Isaiah 14 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 14:1-32

1Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu,

yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i

yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn.

Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn,

wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.

2Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n

wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn.

Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè

gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin

ní ilẹ̀ Olúwa.

Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn

wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.

3Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà, 4ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé,

báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin!

Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!

5Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà,

ọ̀pá àwọn aláṣẹ,

6èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀

pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró,

nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè

pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.

7Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà,

wọ́n bú sí orin.

8Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn

igi kedari ti Lebanoni

ń yọ̀ lórí rẹ wí pé,

“Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí,

kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”

9Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè

láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀

ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ

gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé

ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn

gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè.

10Gbogbo wọn yóò dáhùn,

wọn yóò wí fún ọ wí pé,

“Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú

ìwọ náà ti dàbí wa.”

11Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì,

pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ,

àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ

àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá,

ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà!

A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé,

ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!

13Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé,

“Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run;

èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè

ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run,

Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ

ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.

14Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀;

èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”

15Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ

lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.

16Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ,

wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ:

“Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì

tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.

17Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù,

tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run

tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”

18Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀

ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.

19Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì

gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀,

àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀,

àwọn tí idà ti gún,

àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun.

Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,

20a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn,

nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́

o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ.

Ìran àwọn ìkà

ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.

21Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ

nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn,

wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀

kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.

22“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,”

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà,

àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,”

ni Olúwa wí.

23Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí

àti sí irà;

Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a,

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Asiria

24Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra,

“Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí,

àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.

25Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi,

ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀.

Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi,

ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”

26Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé,

èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.

27Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète,

ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò?

Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì àwọn Filistini

28Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.

2914.29-31: Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Am 1.6-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia,

pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá;

láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀

yóò ti hù jáde,

èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.

30Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko,

àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu.

Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun,

yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.

31Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú!

Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia!

Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá,

kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.

32Kí ni ìdáhùn tí a ó fún

agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà?

Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀,

àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí

a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

New Russian Translation

Исаия 14:1-32

1Время его близко,

и дни его не продлятся.

Господь пожалеет Иакова;

Он вновь изберет Израиль

и поселит их на их земле.

Чужеземцы присоединятся к ним

и пристанут к дому Иакова.

2Народы возьмут Израиля

и приведут на их место.

А дом Израиля завладеет народами

как слугами и служанками в Господней земле.

Они возьмут в плен тех, кто пленил их,

и будут править своими притеснителями.

3В тот день, когда Господь даст тебе облегчение от боли, смуты и жестокого рабства, 4ты запоешь о царе Вавилона эту язвительную песню:

Не стало гонителя!

Кончилась его ярость!14:4 Так в некоторых древних рукописях еврейского текста и в некоторых древних переводах; смысл этого слова в нормативном еврейском тексте неясен.

5Сломал Господь жезл нечестивых,

скипетр повелителей,

6который в гневе разил народы

нескончаемыми ударами

и в ярости народами правил

с безжалостным притеснением.

7Все страны в покое и мире,

запевают песни.

8Даже кипарисы и кедры Ливана

торжествуют над тобой, говоря:

«С тех пор, как ты уснул,

никто не приходит нас рубить».

9Пришел в движение мир мертвых14:9 Евр.: «шеол»; также в ст. 11 и 15.,

чтобы встретить тебя на входе.

Он будит духов умерших, чтобы тебя встречать, –

всех, кто был вождем на земле;

поднимает с престолов всех,

кто был у народов царем.

10Все они ответят, скажут тебе:

«Ты стал слаб, как мы; ты нам уподобился».

11Слава твоя сошла в мир мертвых,

вместе с пением твоих арф.

Личинки мух стелются под тобой,

черви – твой покров.

12Как пал ты с небес,

утренняя звезда, сын зари!

Низвергли на землю тебя,

того, кто попирал народы!

13А ты говорил в своем сердце:

«На небеса поднимусь,

вознесу свой престол

выше Божьих звезд,

и воссяду на горе собрания,

на краю севера14:13 Или: «на высотах (горы) Цафон»..

14Поднимусь на облачные высоты;

уподоблюсь Всевышнему».

15Но ты низведен в мир мертвых,

в глубины бездны14:12-15 В этом отрывке образ царя Вавилона сливается с образом сатаны, низверженного с небес (ср. Иез. 28:11-17; Лк. 10:18)..

16Видящие тебя всматриваются

и дивятся твоей судьбе:

«Тот ли это, кто колебал землю

и сотрясал царства,

17кто сделал мир пустыней,

разрушал его города

и не отпускал пленников домой?»

18Все цари народов почили во славе,

каждый лежит в своей гробнице14:18 Гробнице – букв.: «доме»..

19А ты – вне своей могилы,

выброшен, словно ненужная ветка14:19 Или: «мерзкая падаль».;

ты облачен убитыми,

пронзенными мечом,

нисходящими в каменистую пропасть.

Словно труп, попираемый ногами,

20ты не будешь погребен, как другие цари,

потому что ты разорил свою страну,

погубил свой народ.

Да не будут вовеки упоминаемы

потомки нечестивых!

21Готовьте бойню его сыновьям

из-за вины их отцов.

Да не поднимутся они, чтобы завладеть землей,

и не покроют мир своими городами.

22– Я поднимусь против них, –

возвещает Господь Сил, –

и отниму у Вавилона его имя и уцелевших,

его потомство и грядущие поколения, –

возвещает Господь. –

23Я превращу его во владения ежей

и в заболоченные пруды;

вымету его метлой уничтожения, –

возвещает Господь Сил.

Пророчество об Ассирии

24Господь Сил поклялся:

– Как Я задумал, так и будет;

как Я решил, так и случится:

25сокрушу ассирийцев в Моей земле;

на горах Моих растопчу их.

Будет снято их ярмо с Моего народа,

и их бремя с его плеч.

26Вот решение о всей земле;

вот рука, занесенная на все народы.

27Ведь Господь Сил решил,

и кто властен это отменить?

Рука Его занесена,

и кто властен ее удержать?

Пророчество о филистимлянах

28Следующее пророчество было в год смерти царя Ахаза14:28 Царь Ахаз умер приблизительно в 715 г. до н. э..

29Не радуйтесь, филистимляне,

что сломан поражавший вас жезл,

потому что от змеиного корня родится гадюка,

а плодом ее будет змея-стрелка14:29 Жезл и змеи символизируют ассирийских правителей, нападавших на филистимлян..

30Тогда беднейшие найдут пастбище,

и нищие будут покоиться в безопасности.

Но твой корень Я погублю голодом,

и уцелевших твоих Я убью14:30 Так в одной из древних рукописей еврейского текста и в одном из древних переводов; в нормативном еврейском тексте: «он убьет»..

31Плачьте, ворота! Вой, город!

Замирайте от страха все вы, филистимляне!

Потому что облако пыли движется с севера –

это приближается войско,

и нет в его рядах отстающего.

32Что же ответить вестникам этого народа?

Что Господь утвердил Сион,

и в нем найдут убежище бедные из Его народа.