1Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan
2Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!
Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:
“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,
Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
3Màlúù mọ olówó rẹ̀,
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,
ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,
òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
4Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,
àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,
Ìran àwọn aṣebi,
àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!
Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀
wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,
wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
5Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?
Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?
Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,
gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
6Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín
kò sí àlàáfíà rárá,
àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa
àti ojú egbò,
tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
7Orílẹ̀-èdè yín dahoro,
a dáná sun àwọn ìlú yín,
oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run
lójú ara yín náà,
ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí
àwọn àjèjì borí rẹ̀.
8Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀
gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,
gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,
àti bí ìlú tí a dó tì.
9Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun
bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,
a ò bá ti rí bí Sodomu,
a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
10Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,
tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,
ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
11“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín
kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.
“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun
ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,
Èmi kò ní inú dídùn
nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn
àti ti òbúkọ.
12Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,
ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,
Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
13Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!
Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,
oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,
Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
14Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,
ni ọkàn mi kórìíra.
Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,
Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
15Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,
Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,
kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,
Èmi kò ni tẹ́tí sí i.
“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
16“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.
Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!
Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
17kọ́ láti ṣe rere!
Wá ìdájọ́ òtítọ́,
tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.
Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,
gbà ẹjọ́ opó rò.
18“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”
ni Olúwa wí.
“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,
wọn ó sì funfun bí i yìnyín,
bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,
wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
19Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,
ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
20Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,
idà ni a ó fi pa yín run.”
Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
21Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!
Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,
òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,
ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
22Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,
ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
23Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,
akẹgbẹ́ àwọn olè,
gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀
wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.
Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,
ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
24Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:
“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi
n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
25Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,
èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,
n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
26Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,
àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.
Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
27A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,
àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
28Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.
Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
29“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́
èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,
a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí
tí ẹ ti yàn fúnrayín.
30Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,
bí ọgbà tí kò ní omi.
31Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,
iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,
àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,
láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
1اين كتاب شامل پيامهايی است كه خدا در دوران سلطنت عزيا و يوتام و آحاز و حزقيا، پادشاهان سرزمين يهودا، در عالم رؤيا به اشعيا پسر آموص داد. اين پيامها دربارهٔ يهودا و پايتخت آن اورشليم است.
ياغيگری قوم اسرائيل
2ای آسمان و زمين، به آنچه خداوند میفرمايد گوش كنيد: «فرزندانی كه بزرگ كردهام بر ضد من برخاستهاند. 3گاو مالک خود را و الاغ صاحب خويش را میشناسد، اما قوم اسرائيل شعور ندارد و خدای خود را نمیشناسد.»
4وای بر شما قوم گناهكار كه پشتتان زير بار گناهانتان خم شده است. وای بر شما مردم شرور و فاسد كه از خداوند مقدس بنیاسرائيل روگردانده و او را ترک گفتهايد. 5چرا از گناهان خود دست برنمیداريد؟ آيا به اندازهٔ كافی مجازات نشدهايد؟ ای اسرائيل، فكر و دلت تمام بيمار است. 6از سر تا پا مجروح و مضروب هستی؛ جای سالم در بدنت نمانده است. زخمهايت باز مانده و عفونی شده، كسی آنها را بخيه نزده و مرهم نماليده است.
7ای قوم اسرائيل، سرزمينتان ويران گشته و شهرهايتان به آتش كشيده شده است. بيگانگان هر چه را كه میبينند، در برابر چشمانتان به غارت میبرند و نابود میكنند. 8اورشليم همچون كلبهای در مزرعه و مانند سايبانی در جاليز، بیدفاع و تنها مانده است.
9اگر خداوند قادر متعال به داد قوم ما نمیرسيد اين عدهٔ كم نيز از ما باقی نمیماند و اورشليم مثل شهرهای سدوم و عموره به کلی از بين میرفت.
10ای حاكمان و ای مردم اورشليم كه چون اهالی سدوم و عموره فاسد هستيد، به كلام خداوند گوش دهيد. 11او میفرمايد: «از قربانیهای شما بيزارم. ديگر آنها را به حضور من نياوريد. قوچهای فربهٔ شما را نمیخواهم. ديگر مايل نيستم خون گاوها و برهها و بزغالهها را ببينم. 12چه كسی از شما خواسته كه وقتی به حضور من میآييد اين قربانیها را با خود بياوريد؟ چه كسی به شما اجازه داده كه اينچنين آستان خانهٔ مرا پايمال كنيد؟ 13ديگر اين هدايای باطل را نياوريد. من از بخوری كه میسوزانيد نفرت دارم و از اجتماعات مذهبی و مراسمی كه در اول ماه و در روز سَبَت بجا میآوريد بيزارم. نمیتوانم اين اجتماعات گناهآلود را تحمل كنم. 14از همهٔ آنها متنفرم و تحمل ديدن هيچكدام را ندارم. 15هرگاه دستهايتان را به سوی آسمان دراز كنيد، روی خود را از شما برخواهم گرداند و چون دعای بسيار كنيد، اجابت نخواهم نمود؛ زيرا دستهای شما به خون آلوده است.
16«خود را بشوييد و طاهر شويد! گناهانی را كه در حضور من مرتكب شدهايد از خود دور كنيد. 17نيكوكاری را بياموزيد و با انصاف باشيد. به مظلومان و يتيمان و بيوهزنان كمک كنيد.»
18خداوند میفرمايد: «بحث و جدل من با شما اين است: اگرچه لكههای گناهانتان به سرخی خون است، اما من آنها را مانند پشم پاک میكنم و شما را همچون برف سفيد میسازم! 19كافی است مرا اطاعت كنيد تا شما را از محصول زمين سير كنم. 20اما اگر به سرپيچی از من ادامه دهيد، به دست دشمن كشته خواهيد شد.» اين كلام خداوند است.
21ای اورشليم، زمانی تو نسبت به خداوند وفادار بودی، اما اينک همچون يک فاحشه به دنبال خدايان ديگر میروی. زمانی شهر عدل و انصاف بودی، اما اكنون شهر جنايتكاران شدهای. 22زمانی چون نقره خالص بودی، ولی اينک فلزی بیمصرف شدهای. زمانی همچون شراب ناب بودی، ولی اكنون همانند آب شدهای. 23رهبرانت ياغی و شريک دزدانند؛ همه رشوهخوارند؛ از يتيمان حمايت نمیكنند و به دادخواهی بيوهزنان گوش نمیدهند. 24بنابراين خداوند، خدای قادر متعال اسرائيل به آنها میگويد: «شما دشمن من هستيد؛ تا از شما انتقام نگيرم آرام نمیشوم. 25به دست خود، شما را مثل فلز در كوره میگدازم تا از كثافت خود پاک شويد.
26«مانند گذشته، رهبران و مشاورانی لايق به شما خواهم بخشيد تا اورشليم را به شهر عدالت و امانت مشهور سازند.»
27خداوند عادل، اورشليم و اهالی توبهكار آن را نجات خواهد داد. 28اما گناهكاران و عصيانگران را به هلاكت خواهد رساند و كسانی را كه او را ترک كنند نابود خواهد كرد.
29شما از بتپرستی خود در زير درختان بلوط باغهايتان پشيمان خواهيد شد، 30و مانند بلوطی خشک و باغی بیآب، از بين خواهيد رفت. 31زورمندانتان با اعمالشان مانند كاه در آتش خواهند سوخت و كسی قادر نخواهد بود آنها را نجات دهد.