Isaiah 1 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 1:1-31

1Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.

Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan

2Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:

“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,

Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

3Màlúù mọ olówó rẹ̀,

kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,

ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,

òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”

4Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,

àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,

Ìran àwọn aṣebi,

àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!

Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀

wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,

wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.

5Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?

Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?

Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,

gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.

6Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín

kò sí àlàáfíà rárá,

àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa

àti ojú egbò,

tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.

7Orílẹ̀-èdè yín dahoro,

a dáná sun àwọn ìlú yín,

oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run

lójú ara yín náà,

ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí

àwọn àjèjì borí rẹ̀.

8Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀

gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,

gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,

àti bí ìlú tí a dó tì.

9Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun

bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,

a ò bá ti rí bí Sodomu,

a ò bá sì ti dàbí Gomorra.

10Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,

tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,

ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!

11“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín

kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.

“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun

ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,

Èmi kò ní inú dídùn

nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn

àti ti òbúkọ.

12Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,

ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,

Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!

Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,

oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,

Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.

14Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,

ni ọkàn mi kórìíra.

Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,

Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.

15Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,

Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,

kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,

Èmi kò ni tẹ́tí sí i.

“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.

16“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.

Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!

Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,

17kọ́ láti ṣe rere!

Wá ìdájọ́ òtítọ́,

tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.

Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

gbà ẹjọ́ opó rò.

18“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”

ni Olúwa wí.

“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,

wọn ó sì funfun bí i yìnyín,

bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,

wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.

19Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,

ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.

20Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,

idà ni a ó fi pa yín run.”

Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.

21Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!

Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,

òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,

ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!

22Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,

ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.

23Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,

akẹgbẹ́ àwọn olè,

gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀

wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.

Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.

24Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:

“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi

n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.

25Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,

èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,

n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.

26Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,

àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.

Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”

27A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,

àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.

28Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.

Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.

29“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́

èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,

a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí

tí ẹ ti yàn fúnrayín.

30Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,

bí ọgbà tí kò ní omi.

31Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,

iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,

àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,

láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

La Bible du Semeur

Esaïe 1:1-31

1Révélations reçues par Esaïe, fils d’Amots, au sujet de Juda et de Jérusalem, sous les règnes d’Ozias, de Yotam, d’Ahaz et d’Ezéchias, rois de Juda1.1 Ozias: 2 R 15.1-7 ; 2 Ch 26.1-23 ; Yotam: 2 R 15.32-38 ; 2 Ch 27.1-9 ; Ahaz: 2 R 16.1-20 ; 2 Ch 28.1-27 ; Ezéchias: 2 R 18.1-20 ; 2 Ch 29.1-32. Ces rois ont régné en Juda de 792 à 698 (ou 686) av. J.-C. Esaïe a exercé son ministère de 740 jusqu’au début du viie siècle av. J.-C..

Prophéties sur Juda et sur Israël

Juda est bien malade

2Vous, les cieux, écoutez,

toi, terre, tends l’oreille,

c’est l’Eternel qui parle :

J’ai élevé des enfants, et j’ai pris soin d’eux,

mais ils se sont révoltés contre moi.

3Le bœuf sait bien ╵à qui il appartient,

et l’âne connaît la mangeoire ╵où le nourrit son maître.

Israël ne veut rien savoir,

et mon peuple ne comprend pas.

4Malheur à toi, nation coupable,

peuple chargé de fautes,

race adonnée au mal

et enfants corrompus !

Vous avez abandonné l’Eternel,

méprisé le Saint d’Israël,

vous lui avez tourné le dos.

51.5 Autre traduction : Pourquoi ? vous frapper encore,

puisque vous persistez ╵dans votre rébellion ?

Car, déjà, votre tête ╵tout entière est malade,

votre cœur est tout affligé.

6De la plante des pieds ╵jusqu’à la tête,

rien n’est en bon état,

ce ne sont que blessures, ╵contusions et plaies vives

que l’on n’a pas pansées ╵ni bandées, ni soignées

avec de l’huile.

7Le pays que vous habitez ╵est dévasté1.7 Allusion à l’invasion assyrienne de 701, sous Sennachérib (Es 36 à 37 ; 2 R 18.13), ou à l’invasion des Syriens et des Israélites du Nord, vers 734 (Es 7 ; 2 Ch 28.5-8, 17-18).,

vos villes sont détruites par le feu,

vos campagnes sont ravagées ╵sous vos yeux par des étrangers.

Oui, tout est dévasté, ╵détruit par des envahisseurs1.7 En modifiant légèrement le texte hébreu traditionnel, on obtient : comme à la catastrophe de Sodome (voir Gn 19.23-25)..

8Et Sion est restée

comme une hutte ╵au milieu d’une vigne,

comme un abri ╵dans un champ de concombres,

comme une ville ╵entourée d’armées ennemies.

9Si l’Eternel, ╵le Seigneur des armées célestes,

ne nous avait laissé ╵un faible reste,

nous ressemblerions à Sodome

et nous serions comme Gomorrhe1.9 Cité en Rm 9.29..

Changez de comportement

10Vous, les chefs de Sodome,

écoutez bien ╵ce que dit l’Eternel,

vous, peuple de Gomorrhe1.10 Sodome, Gomorrhe: voir Gn 18.20 ; 19.,

écoutez bien ╵la Loi de notre Dieu.

11A quoi peuvent bien me servir ╵vos nombreux sacrifices ?

dit l’Eternel,

car je suis rassasié ╵des holocaustes de béliers,

et de la graisse ╵de bêtes à l’engrais.

Je ne prends pas plaisir

aux sacrifices de taureaux, ╵d’agneaux comme de boucs1.11 Pour les v. 11-14, voir Am 5.21-22..

12Quand vous venez ╵pour vous présenter devant moi,

qui vous a demandé ╵de fouler mes parvis ?

13Cessez de m’apporter ╵d’inutiles offrandes :

j’ai l’encens en horreur ;

quant aux nouvelles lunes, ╵aux sabbats et aux assemblées,

je ne veux plus ╵de ces rassemblements de culte ╵de gens qui font le mal.

14Oui, vos nouvelles lunes, ╵toutes vos fêtes, ╵je les déteste,

elles sont un fardeau pour moi ;

je suis las de les supporter.

15Lorsque vous étendez les mains ╵pour me prier,

je me cache les yeux,

vous avez beau multiplier ╵le nombre des prières,

je ne vous entends pas,

car vos mains sont pleines de sang.

16Lavez-vous donc, ╵purifiez-vous,

écartez de ma vue ╵vos mauvaises actions

et cessez de faire le mal.

17Apprenez à faire le bien,

efforcez-vous d’agir avec droiture,

assistez l’opprimé1.17 D’après les versions anciennes. Le texte hébreu traditionnel a : l’oppresseur.,

et défendez le droit ╵de l’orphelin,

plaidez la cause de la veuve !

18Venez et discutons ensemble,

dit l’Eternel :

si vos péchés sont rouges ╵comme de l’écarlate,

ils deviendront

aussi blancs que la neige.

Oui, s’ils sont rouges ╵comme la pourpre,

ils deviendront ╵aussi blancs que la laine.

19Si vous vous décidez à m’obéir,

vous mangerez ╵les meilleurs produits du pays.

20Mais, si vous refusez, ╵si vous êtes rebelles,

c’est l’épée qui vous mangera,

l’Eternel le déclare.

Autrefois, aujourd’hui et demain

21Jérusalem !

Comment se fait-il donc ╵que la cité fidèle

soit devenue ╵une prostituée1.21 L’infidélité d’Israël à l’alliance avec l’Eternel est souvent comparée par les prophètes à la prostitution (Jr 3.2 ; 13.27 ; Ez 16.15 ; 23.11 ; Os 2.4 ; Na 3.4). ?

Toi, jadis pleine de droiture,

où la justice demeurait,

maintenant, tu abrites ╵des assassins.

22Ton argent n’est plus que scories,

et ton vin le meilleur ╵est coupé d’eau.

23Tes chefs sont des rebelles,

complices de voleurs,

tous aiment les pots-de-vin

et sont avides de présents,

ils ne défendent pas ╵les droits de l’orphelin ;

la cause de la veuve ╵jamais ne leur parvient.

24C’est pourquoi l’Eternel,

le Seigneur des armées célestes,

le Puissant d’Israël, ╵vous déclare ceci :

Malheur à vous !

Je tirerai vengeance ╵de vous, mes adversaires,

je vous ferai payer, ╵ô vous, mes ennemis.

25Je tournerai ma main ╵contre toi, ô Jérusalem,

je fondrai tes scories,

comme avec de la soude1.25 Ou de la potasse.,

et je vais supprimer ╵tous tes déchets.

26Je te redonnerai des dirigeants ╵comme ceux d’autrefois,

des conseillers ╵comme au commencement.

Après cela, ╵tu seras appelée

la Ville-de-Justice

et la Cité fidèle.

27Le salut viendra pour Sion ╵selon le droit,

ses habitants ╵qui reviendront à Dieu1.27 Autre traduction : chez elle. ╵seront sauvés : ╵ils obtiendront justice.

28Mais les pécheurs ╵et ceux qui transgressent la Loi

seront brisés ensemble

et ceux qui se détournent ╵de l’Eternel, ╵disparaîtront.

29Et quant aux chênes, ╵ceux que vous aimez tant,

ils tourneront à votre honte,

vous rougirez ╵à cause des jardins sacrés1.29 Voir Es 17.10 ; Os 4.13.

que vous avez choisis.

30Car vous serez vous-mêmes ╵pareils aux chênes

au feuillage flétri,

ou tout comme un jardin ╵qui serait privé d’eau.

31L’homme le plus puissant ╵sera comme l’étoupe,

et ce qu’il a produit ╵servira d’étincelle

pour qu’il soit consumé ╵avec ce qu’il a fait

sans qu’il y ait personne ╵pour éteindre les flammes1.31 Autre traduction : le lin semi-traité deviendra de l’étoupe, et celui qui l’a fait sera une étincelle. Avec son œuvre, il brûlera sans qu’il y ait personne pour éteindre les flammes..