Ìparí àwọn ọ̀rọ̀ ìyànjú náà
1Kí ìfẹ́ ará kí o wà títí. 213.2: Gẹ 18.1-8; 19.1-3.Ẹ má ṣe gbàgbé láti máa ṣe àlejò; nítorí pé nípa bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlòmíràn ṣe àwọn angẹli ní àlejò láìmọ̀. 3Ẹ máa rántí àwọn òǹdè bí ẹni tí a dè pẹ̀lú wọn, àti àwọn tí a ń pọn lójú bí ẹ̀yin tìkára yín pẹ̀lú tí ń bẹ nínú ara.
4Kí ìgbéyàwó lọ́lá láàrín gbogbo ènìyàn, kí àkéte si jẹ́ aláìléèérí: Nítorí àwọn àgbèrè àti àwọn panṣágà ni Ọlọ́run yóò dá lẹ́jọ́. 513.5: De 31.6,8; Jo 1.5.Kí ọkàn yín má ṣe fà sí ìfẹ́ owó, ki ohun tí ẹ ní tó yin; nítorí òun tìkára rẹ̀ ti wí pé,
“Èmi kò jẹ́ fi ọ́ sílẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni èmi kò jẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
613.6: Sm 118.6.Nítorí náà ni àwa ṣe ń fi ìgboyà wí pé,
“Olúwa ni olùrànlọ́wọ́ mi, èmi kì yóò bẹ̀rù;
kín ni ènìyàn lè ṣe sí mi?”
7Ẹ máa rántí àwọn tiwọn jẹ́ aṣáájú yín, tiwọn ti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín; kí ẹ máa ro òpin ìwà ayé wọn, kí ẹ sì máa ṣe àfarawé ìgbàgbọ́ wọn. 8Jesu Kristi ọ̀kan náà ni lánàá, àti lónìí, àti títí láé.
9Ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi onírúurú àti àjèjì ẹ̀kọ́ gbá yin kiri. Nítorí ó dára kí a mú yin lọ́kàn le nípa oore-ọ̀fẹ́, kì í ṣe nípa oúnjẹ nínú èyí tí àwọn tí ó ti rìn nínú wọn kò ní èrè. 10Àwa ní pẹpẹ kan, níbi èyí tí àwọn ti ń sin àgọ́ kò ni agbára láti máa jẹ.
1113.11,13: Le 16.27.Nítorí nígbà tí olórí àlùfáà bá mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ẹran wá si ibi mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀, òkú àwọn ẹran náà ni a o sun lẹ́yìn ibùdó. 12Nítorí náà Jesu pẹ̀lú, kí ó lè fi ẹ̀jẹ̀ ara rẹ̀ sọ àwọn ènìyàn di mímọ́, ó jìyà lẹ́yìn ibodè. 13Nítorí náà ẹ jẹ́ kí a jáde tọ̀ ọ́ lọ lẹ́yìn ibùdó, kí a máa ru ẹ̀gàn rẹ̀. 14Nítorí pé àwa kò ní ìlú tí o wa títí níhìn-ín, ṣùgbọ́n àwa ń wá èyí tí ń bọ.
1513.15: Le 7.12; Isa 57.19; Ho 14.2.Ǹjẹ́ nípasẹ̀ rẹ̀, ẹ jẹ́ kí a máa rú ẹbọ ìyìn si Ọlọ́run nígbà gbogbo, èyí yìí ni èso ètè wa, tí ń jẹ́wọ́ orúkọ rẹ̀. 16Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe gbàgbé láti máa ṣoore àti láti máa pín fun ni nítorí irú ẹbọ wọ̀nyí ni inú Ọlọ́run dùn sí jọjọ.
17Ẹ máa gbọ́ ti àwọn tí ń ṣe olórí yín, kí ẹ sì máa tẹríba fún wọ́n: Nítorí wọn ń ṣọ́ ẹ̀ṣọ́ nítorí ọkàn yín, bí àwọn ti yóò ṣe ìṣirò, kí wọn lè fi ayọ̀ ṣe èyí, kì í ṣe pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí èyí yìí yóò jẹ àìlérè fún yín.
18Ẹ máa gbàdúrà fún wa: nítorí àwa gbàgbọ́ pé àwa ni ẹ̀rí ọkàn rere, a sì ń fẹ́ láti máa hùwà títọ́ nínú ohun gbogbo. 19Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ̀ yín gidigidi sí i láti máa ṣe èyí, kí a ba lè tètè fi mi fún yín padà.
2013.20: Isa 63.11; Sk 9.11; Isa 55.3; El 37.26.Ǹjẹ́ Ọlọ́run àlàáfíà, ẹni tí o tún mu olùṣọ́-àgùntàn ńlá ti àwọn àgùntàn, ti inú òkú wá, nípa ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ayérayé, àní Olúwa wa Jesu. 21Kí ó mú yín pé nínú iṣẹ́ rere gbogbo láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣiṣẹ́ ohun tí i ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú rẹ̀ nínú yín nípasẹ̀ Jesu Kristi; ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín.
22Èmi sì ń bẹ̀ yín ará, ẹ gbà ọ̀rọ̀ ìyànjú mi; nítorí ìwé kúkúrú ni mo kọ sí yín.
23Ẹ mọ pé a sá titu Timotiu arákùnrin wa sílẹ̀; bí ó ba tètè dé, èmí pẹ̀lú rẹ̀ yóò rí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
24Ẹ ki gbogbo àwọn tí ń ṣe olórí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
Àwọn tí o ti Itali wá ki yín.
25Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú gbogbo yín.
Náboženství v běžném životě
1-2Jste bratři. Nepřestávejte se mít rádi. Nezapomínejte na pohostinnost. Byli už takoví, kteří, aniž si toho byli vědomi, přijali za hosty anděly. 3Pamatujte na vězně, jako byste byli spolu s nimi uvězněni, a na trýzněné jako ti, které to může postihnout také. 4Manželství mějte všichni v úctě. Manželé, buďte si věrni. Cizoložné a nestoudné bude soudit Bůh. 5Ať se vás nezmocní láska k penězům. Spokojte se s tím, co máte. Neboť Bůh řekl:
„Nezřeknu se tě,
ani tě neopustím.“
6Proto smíte směle prohlásit:
„Pán je můj pomocník.
Nebojím se ničeho,
co by mi mohl udělat člověk.“
7Nezapomínejte na své vůdce, kteří vám vyřizovali Boží poselství. Sledujte cíl jejich života a důvěřujte Bohu jako oni.
8Ježíš Kristus je týž včera, dnes i na věky. 9Nenechte se proto strhávat různými cizími naukami. Svou duchovní sílu čerpáme pouze jako dar od Boha. Nezískáme ji tím, že budeme dodržovat určité předpisy o požívání potravy. Pouhým dodržováním takových předpisů nikdo nic nezíská.
10Máme nový způsob služby Bohu, na kterém nemají podíl ti, kteří lpí na původních izraelských obřadech. Ve staré obětní praxi je však i pro nás něco poučného. 11Těla zvířat obětovaných za hřích, jejichž krev vnášel velekněz do svatyně, byla spalována za městem. 12To je předobraz Ježíše, který trpěl za branami Jeruzaléma. 13Vykročme tedy za ním, opusťme náš starý způsob života a nebojme se pro něho snášet potupu. Vezměme na sebe jeho potupu. 14Vždyť zde na zemi přece nemáme trvalý domov, ale naším cílem je město, které jistě přijde.
Závěrečná výzva k dobročinnosti a modlitbám
15Přinášejme tedy skrze Ježíše stále oběť chvály Bohu; naše rty nechť vyznávají jeho jméno. 16Nezapomínejme na dobročinnost a štědrost, protože takové oběti se Bohu velice líbí. 17Důvěřujte těm, kteří vás vedou, a podřizujte se jim. Oni nad vámi bdí a budou voláni k odpovědnosti. Dbejte, ať mohou podat zprávu s radostí a ne s lítostí, aby vám to nebylo ke škodě. 18Modlete se za nás. Jsme přesvědčeni o svém čistém svědomí, neboť se chceme ve všem správně zachovat. 19Snažně prosím: Modlete se, abych se zase mohl mezi vás brzy vrátit.
20Bůh je dárce pokoje. Vzkřísil našeho Pána Ježíše z mrtvých. Učinil jej pro jeho oběť naším nejvyšším pastýřem. 21Ať vás Bůh uschopní ke konání všeho dobrého, abyste plnili jeho vůli. Kristovou mocí ať ve vás tvoří všechno, co se mu líbí. Jemu buď navždycky sláva. Amen.
Osobní pozdrav pisatele
22Prosím vás, bratři, přijměte tato napomenutí. 23Sděluji vám, že byl náš bratr Timoteus propuštěn z vězení. Přijde-li brzo, navštívím vás s ním. 24Pozdravte všechny, kteří vás vedou, a všechny, kteří jsou Bohu oddáni. Pozdravují vás všichni italští bratři.
25Milost s vámi se všemi.