Hagai 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hagai 1:1-15

Ìpè láti tún ilé Olúwa kọ́

1Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.

2Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’ ”

3Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé, 4“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”

5Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 6Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”

7Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 8Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí. 9“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀. 10Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde. 11Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”

12Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.

13Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí. 14Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn, 15ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.

Nouă Traducere În Limba Română

Hagai 1:1-15

Porunca de a reconstrui Templul

1În al doilea an al împăratului Darius, în prima zi a lunii a șasea1 29 august 520 î.Cr., Cuvântul Domnului le‑a vorbit prin profetul Hagai lui Zerub-Babel, fiul lui Șealtiel, guvernatorul lui Iuda, și lui Iosua, fiul lui Iehoțadak, marele preot, zicând:

2„Așa vorbește Domnul Oștirilor2 Ebr.: YHWH Țebaot. Termenul ebraic pentru oștiri se poate referi: (1) la oștirile lui Israel (Ex. 7:4; Ps. 44:9); (2) la corpurile cerești (Gen. 2:1; Deut. 4:19; Is. 40:26); (3) la îngeri (Ios. 5:14; 1 Regi 22:19; Ps. 148:2). Acest titlu face referire, probabil, la suveranitatea lui Dumnezeu peste orice putere din univers [peste tot în carte].: «Poporul acesta zice: ‘N‑a venit încă vremea pentru rezidirea Casei Domnului.’»“

3Apoi Cuvântul Domnului le‑a vorbit prin profetul Hagai, zicând: 4„Dar pentru voi a venit oare vremea să locuiți în case căptușite cu lemn, în timp ce Casa aceasta este în ruine?“

5Acum, așa vorbește Domnul Oștirilor: „Uitați‑vă cu atenție la căile voastre! 6Ați semănat mult, dar ați adunat puțin! Mâncați, dar tot nu vă săturați! Beți, dar tot nu vă potoliți setea! Vă îmbrăcați, dar tot nu vă este cald, iar plata pe care o câștigați o puneți într‑o pungă spartă!“

7Așa vorbește Domnul Oștirilor: „Uitați‑vă cu atenție la căile voastre! 8Urcați‑vă pe munte, aduceți lemne și rezidiți Casa, ca astfel Eu să‑Mi găsesc plăcerea în ea și să fiu onorat, zice Domnul. 9V‑ați așteptat la mult, dar iată că ați adunat puțin, iar când ați adus recolta acasă, am spulberat‑o. De ce? zice Domnul Oștirilor. Deoarece Casa Mea zace în ruine, în timp ce fiecare dintre voi aleargă pentru casa lui! 10De aceea cerurile nu v‑au mai dat roua, iar pământul nu și‑a mai dat recolta! 11Am chemat seceta peste țară, peste munți și peste grâne, peste must, peste ulei și peste ceea ce rodește pământul, peste oameni, peste animale și peste toată truda mâinilor voastre!“

Răspunsul poporului

12Atunci Zerub-Babel, fiul lui Șealtiel, Iosua, fiul lui Iehoțadak, marele preot, și întreaga rămășiță a poporului au ascultat de glasul Domnului, Dumnezeul lor, și de cuvintele profetului Hagai, pentru că Domnul, Dumnezeul lor, îl trimisese. Și poporul s‑a temut de Domnul.

13Apoi Hagai, mesagerul Domnului, a spus poporului mesajul Domnului: „Eu sunt cu voi“, zice Domnul. 14Astfel Domnul a trezit duhul lui Zerub-Babel, fiul lui Șealtiel, guvernatorul lui Iuda, duhul lui Iosua, fiul lui Iehoțadak, marele preot, și duhul întregii rămășițe a poporului. Ei au venit și au lucrat la Casa Domnului Oștirilor, Dumnezeul lor, 15în a douăzeci și patra zi a lunii a șasea, în al doilea an15 21 septembrie 520 î.Cr. al împăratului Darius.