Hagai 1 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hagai 1:1-15

Ìpè láti tún ilé Olúwa kọ́

1Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.

2Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’ ”

3Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé, 4“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”

5Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 6Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”

7Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 8Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí. 9“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀. 10Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde. 11Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”

12Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.

13Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí. 14Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn, 15ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.

New Serbian Translation

Књига пророка Агеја 1:1-15

Позив на изградњу Господњег Дома

1Друге године цара Дарија, у шестом месецу првог дана тога месеца, реч Господња је дошла преко пророка Агеја Зоровавељу, Салатиловом сину који је био управитељ Јуде, и Првосвештенику Исусу, Јоседековом сину. Поручила је:

2„Овако каже Господ над војскама: ’Овај народ говори: „Није време, још није дошло време да се обнови Дом Господњи!“’“

3И онда је дошла реч Господња преко пророка Агеја и поручила: 4„А вама је време да живите у својим сређеним кућама, а овај је Дом порушен?!“

5И зато овако каже Господ над војскама: „Размислите о својим путевима! 6Сејете много, али мало жањете. Једете, али нисте сити. Пијете, али се нисте напили. Облачите се, али вам није топло; а онај који је зарадио надницу, зарадио је за пробушену кесу.“

7Овако каже Господ над војскама: „Размислите о својим путевима! 8На гору се попните и грађу донесите! Обновите Дом да уживам у њему, да прослављен будем – каже Господ. 9Много сте очекивали, а ено, мало сте добили! Ја одувам то што у кућу унесете. А зашто? – говори Господ над војскама. Зато што је мој Дом порушен, а сваки од вас своју кућу кући! 10Зато су се над вама затворила небеса, нема росе, а земља је ускратила свој род. 11Призвао сам сушу на земљу, на горе, на усеве, на ново вино, на уље, на све чиме земља рађа, на људе, на стоку и на сав труд руку.“

12Зоровавељ, Салатилов син и Првосвештеник Исус, Јоседеков син, и сав преостали народ су послушали глас Господа, Бога свога, и све речи пророка Агеја јер га послао Господ Бог њихов. Народ је тада показао страхопоштовање пред Господом.

13А Агеј, гласник Господњи, је пренео народу поруку од Господа и рекао им: „Ја сам са вама – говори Господ.“ 14Господ је покренуо дух у Зоровавељу, Салатиловом сину, управитељу Јуде и дух у Првосвештенику Исусу, Јоседековом сину, као и дух у свем преосталом народу. Наиме, дошли су у Дом Господа над војскама, Бога свога, и прионули на посао. 15А то је било двадесет четвртог дана, шестог месеца друге године цара Дарија.