Ìbí Isaaki
1Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí. 221.2: Hb 11.11.Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un. 3Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki. 421.4: Gẹ 17.12; Ap 7.8.Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un. 5Ẹni ọgọ́rùn-ún (100) ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
6Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.” 7Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
A lé Hagari àti Iṣmaeli jáde
8Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá. 9Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà, 1021.10: Ga 4.30.ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
11Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe. 1221.12: Ro 9.7; Hb 11.18.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀. 13Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
14Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
15Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó. 16Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
17Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí. 18Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
19Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
20Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà. 21Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Májẹ̀mú ní Beerṣeba
2221.22: Gẹ 26.26.Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe. 23Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
24Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
25Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀. 26Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
27Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú. 28Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀. 29Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30Ó dalóhùn pé “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
3121.31: Gẹ 26.33.Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini. 33Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé. 34Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Isak föds
1Sedan var Herren god mot Sara och gjorde vad han lovat. 2Sara blev med barn och födde en son åt den åldrige Abraham precis vid den tid som Gud hade sagt. 3Abraham gav sonen Sara födde åt honom namnet Isak21:3 Se not till 17:19.. 4Åtta dagar efter födelsen omskar Abraham honom, som Gud hade befallt. 5Abraham var 100 år gammal när hans son Isak föddes.
6Sara sa: ”Gud har fått mig att skratta! Alla som hör detta kommer att skratta med mig. 7Vem kunde ha talat om för Abraham att Sara skulle komma att amma barn? Ändå har jag fött en son åt honom på hans ålderdom.”
Hagar och Ismael drivs ut i öknen
8Barnet växte och blev avvant. Detta firade Abraham med en fest. 9Men när Sara såg att Ismael, Abrahams son med den egyptiska flickan Hagar, hånskrattade21:9 Se Gal 4:29. Eller: Hagar, lekte., 10sa hon till Abraham: ”Driv bort denna slavinna och hennes son! Slavinnans son ska inte få dela arvet tillsammans med min son Isak.”
11Detta gjorde Abraham mycket upprörd, för Ismael var ju också hans son. 12Men Gud sa till Abraham: ”Var inte så bekymrad över detta med Ismael och slavkvinnan. Gör som Sara säger, för det är bara Isaks efterkommande som ska räknas som dina ättlingar. 13Men av slavkvinnans son ska jag också göra ett folk, eftersom även han är din.”
14Abraham gick därför upp tidigt följande morgon. Han gjorde i ordning mat och en lädersäck med vatten som han lyfte upp på Hagars axlar och skickade bort henne med sin son. Utan mål vandrade hon så ut i Beer Shevas öken. 15När vattnet tog slut, lämnade hon barnet under en buske 16och gick bort och satte sig en bit därifrån, på ett pilskotts avstånd. ”Jag kan inte se honom dö”, sa hon och brast ut i våldsam gråt21:16 Både den aktuella satsen och framför allt sammanhanget (se v. 17) tillåter också översättningen att det var pojken som brast i gråt. Situationen talar för att båda två grät..
17Då hörde Gud pojkens gråt, och Guds ängel ropade från himlen till Hagar: ”Hagar, hur är det med dig? Var inte rädd, för Gud har hört pojkens rop där han ligger. 18Gå, hjälp upp pojken och ta väl hand om honom, för jag ska göra honom till ett stort folk.”
19Sedan öppnade Gud hennes ögon och hon såg en brunn. Där fyllde hon vatten i säcken och gav den till pojken så att han fick dricka. 20Och Gud var med pojken, som växte upp i öknen och blev tränad i bågskytte. 21Han levde i Paranöknen. Där skaffade hans mor honom också en hustru från Egypten.
En viktig källa
22Vid den tiden kom kung Avimelek och befälhavaren för hans här, en man som hette Pikol, och sa till Abraham: ”Gud är med dig i allt vad du gör. 23Svär vid Gud att du inte ska bedra mig eller min son eller mina efterkommande, och att du ska vara vänligt inställd mot mig och landet där du bor, på samma sätt som jag har varit mot dig!” 24Abraham svarade: ”Det svär jag på.” 25Sedan klagade Abraham för kungen över en brunn, som kungens tjänare tagit över. 26”Jag har ingen aning om vem som är ansvarig. Varför talade du inte om detta för mig förut?” sa kungen. ”Detta är första gången jag hör talas om detta.”
27Då gav Abraham kungen får och oxar, och de ingick förbund med varandra. 28Men när Abraham tog sju lamm och ställde dem åt sidan, 29frågade Avimelek Abraham: ”Varför gör du så, ställer sju lamm åt sidan?” 30Abraham svarade: ”Dessa sju lamm ska du ta emot av mig som en bekräftelse på att denna brunn är grävd av mig.” 31Från den tiden kallas brunnen Beer Sheva21:31 Namnet är en anspelning på de hebreiska orden för ed och sju; beer betyder brunn. eftersom det var där de svor en ed. 32Så slöt de ett förbund i Beer Sheva. Sedan reste kung Avimelek och Pikol, befälhavaren för hans här, hem till filistéernas land igen. 33Abraham planterade ett tamariskträd i Beer Sheva och åkallade där Herren, den evige Guden. 34Därefter bodde Abraham i filistéernas land under en lång tid.