Gẹnẹsisi 21 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 21:1-34

Ìbí Isaaki

1Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí. 221.2: Hb 11.11.Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un. 3Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki. 421.4: Gẹ 17.12; Ap 7.8.Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un. 5Ẹni ọgọ́rùn-ún (100) ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.

6Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.” 7Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”

A lé Hagari àti Iṣmaeli jáde

8Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá. 9Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà, 1021.10: Ga 4.30.ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”

11Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe. 1221.12: Ro 9.7; Hb 11.18.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀. 13Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”

14Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.

15Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó. 16Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.

17Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí. 18Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”

19Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.

20Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà. 21Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.

Májẹ̀mú ní Beerṣeba

2221.22: Gẹ 26.26.Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe. 23Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”

24Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”

25Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀. 26Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”

27Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú. 28Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀. 29Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”

30Ó dalóhùn pé “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”

3121.31: Gẹ 26.33.Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.

32Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini. 33Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé. 34Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.

Nouă Traducere În Limba Română

Geneza 21:1-34

Nașterea lui Isaac

1Domnul a cercetat‑o pe Sara, după cum a zis; Domnul a făcut pentru Sara ceea ce promisese. 2Sara a rămas însărcinată și i‑a născut lui Avraam un fiu la bătrânețe, la vremea hotărâtă, despre care îi vorbise Dumnezeu. 3Avraam i‑a pus numele Isaac3 Ebr.: Ițhak, care înseamnă el râde. fiului său nou‑născut, pe care i‑l născuse Sara. 4Avraam l‑a circumcis pe fiul său Isaac, la vârsta de opt zile, așa cum i‑a poruncit Dumnezeu. 5Avraam avea o sută de ani când s‑a născut fiul său Isaac. 6Sara a zis: „Dumnezeu mi‑a dat un motiv de râs. Oricine va auzi despre aceasta, va râde împreună cu mine.“ 7Apoi a zis: „Cine i‑ar fi spus lui Avraam că Sara va alăpta copii? Totuși, i‑am născut un fiu la bătrânețe.“

Agar și Ismael sunt alungați în pustie

8Copilul a crescut și a fost înțărcat. În ziua în care Isaac a fost înțărcat, Avraam a dat un ospăț mare. 9Dar Sara l‑a văzut râzând9 Posibil un joc de cuvinte cu ebraicul Ițhak (el râde). pe fiul egiptencei Agar, pe care aceasta i‑l născuse lui Avraam, 10și i‑a zis lui Avraam: „Alung‑o pe această roabă și pe fiul ei, căci fiul acestei roabe nu va moșteni împreună cu fiul meu, cu Isaac!“ 11Lucrul acesta nu i‑a plăcut deloc lui Avraam,11 Lit.: Și cuvântul a fost foarte rău în ochii lui Avraam. deoarece îl avea în vedere pe fiul său. 12Dar Dumnezeu i‑a zis lui Avraam: „Să nu fii tulburat12 Lit.: Să nu fie rău în ochii tăi. din cauza băiatului și a roabei tale. Ascult‑o pe Sara în tot ce îți spune, pentru că prin Isaac își va primi numele sămânța12 Vezi nota de la 12:7. Ideea care se desprinde de aici, este aceea că promisiunea legământului nu se va împlini pe linia lui Ismael, ci pe linia lui Isaac. ta. 13Cât despre fiul roabei tale, îl voi face și pe el un neam, pentru că este sămânța ta.“

14Avraam s‑a sculat dis‑de‑dimineață, a luat niște pâine și un burduf cu apă și i le‑a dat lui Agar, punându‑i‑le pe umăr; i‑a dat și copilul și a trimis‑o. Ea a plecat și a rătăcit în pustia Beer-Șeba. 15Când apa din burduf s‑a terminat, a aruncat copilul sub unul dintre tufișuri 16și apoi s‑a dus și a șezut singură la depărtare, cam până unde zboară o săgeată trasă de arc, căci își zicea: „Să nu văd moartea copilului.“ Și, șezând la depărtare, și‑a ridicat glasul și a plâns. 17Dar Dumnezeu a auzit glasul băiatului. Îngerul lui Dumnezeu a strigat din ceruri către Agar și i‑a zis: „Ce se întâmplă, Agar? Nu te teme, pentru că Dumnezeu a auzit glasul băiatului din locul în care este. 18Scoală‑te, ridică băiatul și ține‑l de mână, pentru că voi face din el un neam mare.“ 19Apoi Dumnezeu i‑a deschis ochii, iar ea a văzut o fântână cu apă. S‑a dus, a umplut burduful cu apă și i‑a dat băiatului să bea. 20Dumnezeu a fost cu băiatul, iar el a crescut, a locuit în pustie și a ajuns arcaș. 21A locuit în pustia Paran, iar mama lui i‑a luat o soție din țara Egiptului.

Legământul dintre Avraam și Abimelek

22În vremea aceea, Abimelek, împreună cu Pihol, comandantul oștirii sale, i‑au vorbit lui Avraam, zicând:

– Dumnezeu este cu tine în tot ceea ce faci. 23Jură‑mi acum pe Dumnezeu că nu mă vei trăda nici pe mine, nici pe copiii mei, nici pe descendenții mei, ci, așa cum eu am arătat îndurare față de tine, tot așa vei arăta și tu față de mine și față de țara în care locuiești ca străin.

24Avraam i‑a răspuns:

– Jur!

25Dar Avraam i s‑a plâns lui Abimelek cu privire la o fântână cu apă, pe care robii acestuia o luaseră cu forța.

26Abimelek i‑a răspuns: „Nu știu cine a făcut acest lucru. Tu nu mi‑ai spus, iar eu nu am auzit despre aceasta decât astăzi.“ 27Atunci Avraam a luat oi și vite și i le‑a dat lui Abimelek. Apoi cei doi au încheiat un legământ. 28Avraam a pus deoparte șapte mielușele din turmă.

29Abimelek l‑a întrebat pe Avraam:

– Ce este cu aceste șapte mielușele pe care le‑ai pus deoparte?

30Avraam i‑a răspuns:

– Primește aceste șapte mielușele ca pe o mărturie din partea mea că eu am săpat această fântână.

31De aceea locul acela a fost numit Beer-Șeba31 Beer-Șeba poate însemna fie fântâna jurământului, fie fântâna celor șapte (v. 28-29)., pentru că amândoi au depus acolo un jurământ. 32După ce au încheiat legământul la Beer-Șeba, Abimelek și Pihol, comandantul oștirii sale, s‑au ridicat și s‑au întors în țara filistenilor. 33Avraam a plantat un tamarisc în Beer-Șeba și a chemat acolo Numele Domnului, Dumnezeul cel Veșnic33 Ebr.: El‑Olam.. 34El a locuit ca străin în țara filistenilor multă vreme.