Ìbí Isaaki
1Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí. 221.2: Hb 11.11.Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un. 3Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki. 421.4: Gẹ 17.12; Ap 7.8.Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un. 5Ẹni ọgọ́rùn-ún (100) ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
6Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.” 7Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
A lé Hagari àti Iṣmaeli jáde
8Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá. 9Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà, 1021.10: Ga 4.30.ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
11Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe. 1221.12: Ro 9.7; Hb 11.18.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀. 13Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
14Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
15Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó. 16Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
17Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí. 18Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
19Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
20Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà. 21Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Májẹ̀mú ní Beerṣeba
2221.22: Gẹ 26.26.Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe. 23Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
24Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
25Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀. 26Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
27Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú. 28Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀. 29Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30Ó dalóhùn pé “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
3121.31: Gẹ 26.33.Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini. 33Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé. 34Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
Isaac Is Born
1The Lord was gracious to Sarah, just as he had said he would be. The Lord did for Sarah what he had promised to do. 2Sarah became pregnant. She had a son by Abraham when he was old. The child was born at the exact time God had promised. 3Abraham gave the name Isaac to the son Sarah had by him. 4When his son Isaac was eight days old, Abraham circumcised him. He did it exactly as God had commanded him. 5Abraham was 100 years old when his son Isaac was born to him.
6Sarah said, “God has given laughter to me. Everyone who hears about this will laugh with me.” 7She also said, “Who would have said to Abraham that Sarah would breast-feed children? But I’ve had a son by him when he is old.”
Abraham Sends Hagar and Ishmael Away
8Isaac grew. The time came for his mother to stop breast-feeding him. On that day Abraham prepared a big celebration. 9But Sarah saw Ishmael making fun of Isaac. Ishmael was the son Hagar had by Abraham. Hagar was Sarah’s Egyptian slave. 10Sarah said to Abraham, “Get rid of that slave woman! Get rid of her son! That woman’s son will never have a share of the family’s property. All of it belongs to my son Isaac.”
11What Sarah said upset Abraham very much. After all, Ishmael was his son. 12But God said to Abraham, “Do not be so upset about the boy and your slave Hagar. Listen to what Sarah tells you, because your family line will continue through Isaac. 13I will also make the son of your slave into a nation. I will do it because he is your child.”
14Early the next morning Abraham got some food and a bottle of water. The bottle was made out of animal skin. He gave the food and water to Hagar, placing them on her shoulders. Then he sent her away with the boy. She went on her way and wandered in the Desert of Beersheba.
15When the water in the bottle was gone, she put the boy under a bush. 16Then she sat down about as far away as a person can shoot an arrow. She thought, “I can’t stand to watch the boy die.” As she sat there, she began to sob.
17God heard the boy crying. Then the angel of God called out to Hagar from heaven. He said to her, “What is the matter, Hagar? Do not be afraid. God has heard the boy crying as he lies there. 18Lift up the boy and take him by the hand. I will make him into a great nation.”
19Then God opened Hagar’s eyes, and she saw a well of water. So she went and filled the bottle with water and gave the boy a drink.
20God was with the boy as he grew up. He lived in the desert and learned to shoot a bow and arrow. 21While he was living in the Desert of Paran, his mother got a wife for him from Egypt.
The Agreement at Beersheba
22At that time Abimelek and his army commander, Phicol, spoke to Abraham. They said to Abraham, “God is with you in everything you do. 23Now make a promise to me here while God is watching. Give me your word that you will treat me fairly. Promise that you will treat my children and their children the same way. I’ve been kind to you. Now you be kind to me and the country where you are living as an outsider.”
24Abraham said, “I give you my word that I’ll do it.”
25Then Abraham complained to Abimelek that his servants had taken over a well of water. 26But Abimelek said, “I don’t know who has done this. You didn’t tell me. And today is the first time I heard about it.”
27So Abraham gave Abimelek sheep and cattle. The two men came to an agreement. 28Then Abraham picked out seven female lambs from his flock. 29Abimelek asked Abraham, “What’s the meaning of these seven female lambs? Why have you picked them out and set them apart?”
30Abraham replied, “Accept the seven lambs from me. They will be a witness that I dug this well.”
31So that place was named Beersheba. That’s because there the two men came to an agreement.
32After the agreement had been made at Beersheba, Abimelek went back to the land of the Philistines. His army commander, Phicol, went with him. 33Abraham planted a tamarisk tree in Beersheba. There he called on the name of the Lord, the God who lives forever. 34Abraham stayed in the land of the Philistines for a long time.