Gẹnẹsisi 20 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 20:1-18

Abrahamu àti Abimeleki

1Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀. 220.2: Gẹ 12.13; 26.7.Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.

3Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ nnì, aya ẹni kan ní íṣe.”

4Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí? 5Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”

6Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà. 7Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”

8Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi. 9Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.” 10Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”

11Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi. 12Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya. 13Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi: Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.” ’ ”

14Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un. 15Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”

16Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”

17Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ. 18Nítorí Ọlọ́run ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 20:1-18

Abraham och kung Avimelek

1Abraham flyttade söderut till Negev och bosatte sig mellan Kadesh och Shur. Under en tid var han i Gerar, 2och där sa han om sin hustru Sara att hon var hans syster. Då lät Gerars kung Avimelek hämta henne till sig.

3Men om natten kom Gud till Avimelek i en dröm och sa: ”Du ska dö, eftersom den kvinna du har tagit till dig är gift.” 4Men Avimelek hade inte legat med henne, så han sa: ”Herre, vill du döda en oskyldig nation? 5Han påstod ju att hon var hans syster. Och hon själv sa: ’Ja, han är min bror.’ Jag har inte haft den minsta tanke på att göra något ont eller något felaktigt.”

6”Ja, jag vet det”, svarade Gud i en dröm. ”Du har handlat med uppriktigt hjärta. Det är därför som jag har hindrat dig från att synda emot mig, och därför lät jag dig inte röra henne. 7Återlämna henne nu till hennes man. Han ska be för dig så att du får leva, för han är en profet. Men om du inte återlämnar henne till honom, ska både du och hela din familj straffas med döden.”

8Nästa morgon steg kungen upp tidigt och kallade snabbt samman sina män. Han talade om för dem vad som hade hänt och de blev allesammans mycket rädda.

9Sedan kallade kungen på Abraham. ”Vad är det du har gjort mot oss?” frågade han. ”Och vad har jag gjort, för att du ska behandla mig på det här sättet och göra mig och mitt kungarike skyldiga till denna stora synd? Du har gjort något som inte får göras mot mig.” 10Avimelek frågade Abraham: ”Vad har fått dig att handla så?”

11Abraham svarade: ”Jag räknade med att man inte fruktade Gud på denna plats. Jag tänkte att ni kunde döda mig för att få min hustru. 12Dessutom är hon faktiskt min syster, för vi har samma far, men inte samma mor. Därför kunde jag gifta mig med henne. 13När Gud skickade iväg mig på den långa resan från mitt barndomshem, sa jag till henne: ’Visa mig din kärlek genom att säga att jag är din bror, vart vi än kommer.’ ”

14Då tog kung Avimelek får och oxar och slavar, både män och kvinnor, och gav till Abraham samtidigt som han återlämnade hans hustru Sara.

15”Se dig omkring i mitt rike och välj själv var du vill bo”, sa Avimelek till honom. 16Sedan vände han sig till Sara: ”Se här, jag ger din bror 1 000 siklar20:16 1 sikel=12 gram. silver som ersättning åt dig inför de dina. På så sätt blir du upprättad inför alla.”

17Då bad Abraham till Gud att han skulle bota kungen och hans hustru och slavinnor så att de skulle kunna få barn. 18Herren hade nämligen slagit alla kvinnorna med ofruktsamhet för Saras, Abrahams hustrus, skull.