Esra 3 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esra 3:1-13

Títún pẹpẹ kọ́

1Nígbà tí ó di oṣù keje tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú àwọn ìlú wọn, àwọn ènìyàn péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ní Jerusalẹmu. 23.2: El 27.1.Nígbà náà ni Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ pẹpẹ Ọlọ́run Israẹli láti rú ẹbọ sísun níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a ti kọ sínú ìwé òfin Mose ènìyàn Ọlọ́run. 3Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ẹ̀rù àwọn ènìyàn tí ó yí wọn ká ń bà wọ́n síbẹ̀, wọ́n kọ́ pẹpẹ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, wọ́n sì rú ẹbọ sísun lórí rẹ̀ sí Olúwa, ọrẹ àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́. 4Nígbà náà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ, wọ́n ṣe àjọ àgọ́ ìpàdé pẹ̀lú iye ẹbọ sísun tí a fi lélẹ̀ fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan. 5Lẹ́yìn náà, wọ́n ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àtìgbàdégbà, ẹbọ oṣù tuntun àti gbogbo àwọn ẹbọ fún gbogbo àpèjẹ tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti àwọn tí a mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àtinúwá fún Olúwa. 6Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní rú ẹbọ sísun sí Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ì tí ì fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.

Títún tẹmpili kọ́

7Nígbà náà ni wọ́n fún àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà ní owó, wọ́n sì tún fi oúnjẹ, ohun mímu àti òróró fún àwọn ará Sidoni àti Tire, kí wọ́n ba à le è kó igi kedari gba ti orí omi Òkun láti Lebanoni wá sí Joppa, gẹ́gẹ́ bí Kirusi ọba Persia ti pàṣẹ.

8Ní oṣù kejì ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n ti padà dé sí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn arákùnrin yòókù (àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti gbogbo àwọn tí ó ti ìgbèkùn dé sí Jerusalẹmu) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ náà. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ Lefi tí ó tó ọmọ-ogun ọdún sókè láti máa bojútó kíkọ́ ilé Olúwa. 9Jeṣua àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti Kadmieli àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọmọ Juda (àwọn ìran Hodafiah) àti àwọn ọmọ Henadadi àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn—gbogbo ará Lefi—parapọ̀ láti bojútó àwọn òṣìṣẹ́ náà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ lórí í kíkọ́ ilé Ọlọ́run.

10Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Lefi (àwọn ọmọ Asafu) pẹ̀lú símbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dafidi ọba Israẹli ti fi lélẹ̀. 11Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa:

“Ó dára;

ìfẹ́ rẹ̀ sí Israẹli dúró títí láé.”

Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀. 12Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹmpili Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sọkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀. 13Kò sí ẹni tí ó le mọ ìyàtọ̀ láàrín igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jíjìn réré.

New Russian Translation

Ездра 3:1-13

Восстановление жертвенника

1Когда наступил седьмой месяц и израильтяне уже поселились в своих городах, народ, как один человек, собрался в Иерусалиме. 2Иисус, сын Иоседека, вместе со своими собратьями священниками, Зоровавелем, сыном Шеалтиила, и его собратьями начал строить жертвенник Бога Израиля, чтобы приносить на нем всесожжения, как предписано в Законе Божьего человека Моисея. 3Несмотря на то что3:3 Несмотря на то, что – или: «Так как». они боялись народов, которые были вокруг них, они построили жертвенник на прежнем основании и приносили на нем всесожжения Господу – и утренние, и вечерние жертвы. 4Затем они отпраздновали, как предписано, праздник Шалашей3:4 Праздник Шалашей – иудейский праздник в память о попечении Бога во время скитаний в пустыне (см. Лев. 23:33-43; Чис. 29:12-39; Втор. 16:13-17). с указанным количеством всесожжений, установленных для каждого дня. 5После этого они принесли постоянные всесожжения, жертвы на Новолуние3:5 Праздник появления каждой новой луны, означавшей (в системе времяисчисления, построенной на лунном календаре) начало нового месяца., и жертвы на все праздники, посвященные Господу, и добровольные пожертвования от каждого, кто добровольно жертвовал Господу. 6В первый день седьмого месяца они начали приносить Господу всесожжения, хотя основание Господнего храма еще не было заложено.

Закладка основания для храма

7Они начали давать деньги каменщикам и плотникам и еду, питье и масло жителям Сидона и Тира, чтобы те привозили морем кедровые бревна с Ливана в Яффу с разрешения Кира, царя Персии.

8Во второй месяц второго года после того, как они пришли к Божьему дому в Иерусалиме3:8 В середине весны 536 г. до н. э., Зоровавель, сын Шеалтиила, Иисус, сын Иоседека, и все остальные их соплеменники (священники, левиты и все, кто вернулся в Иерусалим из плена) приступили к работе, назначив левитов от двадцати лет и старше следить за строительством дома Господа. 9Иисус со своими сыновьями и братьями, и Кадмиил со своими сыновьями (потомками Годавии3:9 Букв.: «Иуды». Иуда – вариант имени Годавия (см. 2:40; Неем. 7:43).), и сыновья Хенадада со своими сыновьями и братьями – все левиты – вместе начали следить за строительством Божьего дома.

10Когда строители заложили основание дома Господа, священники в своих облачениях и с трубами и левиты (сыновья Асафа) с тарелками заняли свои места, чтобы восславить Господа по наставлениям Давида, царя Израиля. 11Они пели попеременно, возвеличивая и благодаря Господа:

– Он благ;

милость Его к Израилю – навеки!

А весь народ отвечал громким криком хвалы Господу, потому что основание дома Господа было заложено. 12Но многие из старых священников, левитов и глав семейств, видевших прежний дом, громко плакали, глядя, как закладывается основание этого дома, а многие кричали от радости. 13Крики радости нельзя было отличить от плача – так шумел народ. И шум был слышен далеко.