Esra 10 – YCB & NRT

Yoruba Contemporary Bible

Esra 10:1-44

Ìjẹ́wọ́ ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn

1Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò. 2Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli 3Ní ṣinṣin yìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin. 4Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.

5Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra. 6Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.

7Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu. 8Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnrarẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.

9Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀. 10Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli. 11Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”

12Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé: ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí. 13Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí. 14Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa. 15Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.

16Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà, 17Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.

Àwọn tó jẹ̀bi ẹ̀sùn ìgbéyàwó pẹ̀lú àjèjì

18Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì:

Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ:

Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah. 19Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.

20Nínú ìran Immeri:

Hanani àti Sebadiah.

21Nínú ìran Harimu:

Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.

22Nínú ìran Paṣuri:

Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.

23Lára àwọn ọmọ Lefi:

Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.

24Nínú àwọn akọrin:

Eliaṣibu.

Nínú àwọn aṣọ́nà:

Ṣallumu, Telemu àti Uri.

25Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù:

Nínú ìran Paroṣi:

Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.

26Nínú ìran Elamu:

Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.

27Nínú àwọn ìran Sattu:

Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.

28Nínú àwọn ìran Bebai:

Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.

29Nínú àwọn ìran Bani:

Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.

30Nínú àwọn Pahati-Moabu:

Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.

31Nínú àwọn ìran Harimu:

Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni, 32Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.

33Nínú àwọn ìran Haṣumu:

Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.

34Nínú àwọn ìran Bani:

Maadai, Amramu, Ueli, 35Benaiah, Bediah, Keluhi 36Faniah, Meremoti, Eliaṣibu, 37Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.

38Àti Bani, àti Binnui:

Ṣimei, 39Ṣelemiah, Natani, Adaiah, 40Maknadebai, Sasai, Ṣarai, 41Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah, 42Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.

43Nínú àwọn ìran Nebo:

Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joeli àti Benaiah.

44Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

New Russian Translation

Ездра 10:1-44

Покаяние народа и расторжение смешанных браков

1Пока Ездра молился и открыто признавался в грехах, плача и повергаясь перед Божьим домом, вокруг него собралась большая толпа израильтян: мужчин, женщин и детей. Они тоже горько плакали. 2Шекания, сын Иехиила, один из потомков Елама, обратился к Ездре, сказав:

— Мы нарушили верность нашему Богу, женившись на чужеземках из народов, что вокруг нас. Но даже теперь у Израиля еще есть надежда. 3Итак, давайте заключим с нашим Богом завет, чтобы удалить от себя всех этих женщин и их детей, по совету моего господина и тех, кто благоговеет перед повелениями нашего Бога. Пусть всё будет по Закону. 4Поднимись, это дело в твоих руках. Мы поддержим тебя, соберись с духом и действуй.

5Ездра поднялся и заставил главных священников, левитов и весь Израиль поклясться сделать так, как было предложено. И они поклялись. 6Ездра удалился от Божьего дома и пошел в комнату Иоханана, сына Элиашива. Пока он был там, он не ел хлеба и не пил воды, потому что скорбел о неверности переселенцев.

7И в Иудее, и в Иерусалиме объявили, что все переселенцы должны собраться в Иерусалиме, 8а если кто-нибудь не придет в течение трех дней, у того — по решению вождей и старейшин — будет отобрано10:8 См. Исх. 22:20 и сноску к нему. всё его имущество, а сам он будет изгнан из общины переселенцев.

9В течение трех дней все мужчины Иуды и Вениамина собрались в Иерусалиме. На двадцатый день девятого месяца10:9 19 декабря 458 г. до н. э. весь народ сидел на площади перед Божьим домом, дрожа из-за этого дела и из-за ливня. 10Священник Ездра встал и сказал им:

— Вы совершили предательство: вы женились на чужеземках, увеличив вину Израиля. 11Итак, открыто признайтесь Господу, Богу ваших отцов, в своих грехах и исполните Его волю. Отделитесь от народов, что вокруг вас, и от ваших иноплеменных жен.

12Всё собрание ответило громким криком:

— Ты прав! Мы должны сделать, как ты сказал. 13Но здесь много людей, и сейчас время дождей, так что мы не можем стоять на улице. Да и дело это не на день и не на два, потому что мы в этом сильно согрешили. 14Пусть наши вожди представляют всё собрание. И пусть все в наших городах, кто женился на чужеземках, приходят в установленное время вместе со старейшинами и судьями каждого города, пока от нас не отвратится пылающий гнев нашего Бога за это дело.

15Только Ионафан, сын Асаила, и Иахзея, сын Тиквы, а с ними Мешуллам и левит Шавтай, воспротивились этому.

16Переселенцы сделали, как было предложено. Священник Ездра выбрал людей, которые были главами семейств,10:16 Так в одном из древн. переводов; в нормативном евр. тексте: «И были избраны священник Ездра и главы семейств…» по одному из каждого семейства; все они были названы поименно. В первый день десятого месяца10:16 29 декабря 458 г. до н. э. они сели, чтобы разбирать это дело, 17и к первому дню первого месяца10:17 27 марта 457 г. до н. э. закончили расследование относительно всех, кто женился на чужеземках.

Список женатых на чужеземках

18Вот женатые на чужеземках среди потомков священников.

Из потомков Иисуса, сына Иоседека, и его братьев: Маасея, Элиезер, Иарив и Гедалия. 19(Они обещали развестись со своими женами, и за свою вину каждый принес барана из своей отары в жертву повинности.)

20Из потомков Иммера: Ханани и Зевадия.

21Из потомков Харима: Маасея, Илия, Шемая, Иехиил и Уззия.

22Из потомков Пашхура: Элиоэнай, Маасея, Исмаил, Нафанаил, Иозавад и Эласа.

23Из левитов: Иозавад, Шимей, Келаия (он же Клита), Петахия, Иуда и Элиезер.

24Из певцов: Элиашив.

Из привратников: Шаллум, Телем и Ури.

25Вот женатые на чужеземках среди прочих израильтян.

Из потомков Пароша: Рамия, Иззия, Малхия, Миямин, Элеазар, Малхия10:25 В одном из древних текстов: Хашавия. и Бенаи.

26Из потомков Елама: Маттания, Захария, Иехиил, Авдий, Иеримот и Илия.

27Из потомков Затту: Элиоэнай, Элиашив, Маттания, Иеримот, Завад и Азиза.

28Из потомков Бевая: Иоханан, Ханания, Заббай и Атлай.

29Из потомков Бани: Мешуллам, Маллух, Адая, Иашув, Шеал и Иеримот.

30Из потомков Пахат-Моава: Адна, Хелал, Бенаи, Маасея, Маттания, Веселеил, Биннуй и Манассия.

31Из потомков Харима: Элиезер, Ишшия, Малхия, Шемая, Симеон, 32Вениамин, Маллух и Шемария.

33Из потомков Хашума: Матнай, Маттфа, Завад, Элифелет, Иеремай, Манассия и Шимей.

34Из потомков Бани: Маадай, Амрам, Уел, 35Бенаи, Бидья, Келуги, 36Ваная, Меремоф, Элиашив, 37Маттания, Матнай и Иаасай.

38Из потомков Биннуя:10:37–38 Так в одном из древних текстов, приводящих этот же именной список, и в одном из древн. переводов; в нормативном евр. тексте: Иаасу, 38 и Бани, и Биннуй. Шимей, 39Шелемия, Нафан, Адая, 40Махнадбай, Шашай, Шарай, 41Азариил, Шелемия, Шемария, 42Шаллум, Амария и Иосиф.

43Из потомков Нево: Иеил, Маттифия, Завад, Зевина, Иаддай, Иоиль и Бенаи.

44Все они женились на чужеземках, и некоторые из их жен родили им детей.10:44 Или: «И все они отослали своих жен вместе с их детьми».