Esekiẹli 18 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esekiẹli 18:1-32

Ọkàn tí o bá sẹ̀ ni yóò kú

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé: 218.2: Jr 31.29.“Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé:

“ ‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan,

eyín àwọn ọmọ sì kan.’

3“Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli. 418.4: El 18.20.Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.

5“Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà,

tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ

6tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga,

tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli,

ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́

tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.

7Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára,

ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀

gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un,

kò fi ipá jalè

ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ,

tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.

8Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá,

tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù.

Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀,

ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.

9Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi,

tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo.

Ó jẹ́ olódodo,

yóò yè nítòótọ́,

Olúwa Olódùmarè wí.

10“Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀ 11(tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì):

“Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga,

tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.

12Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára,

ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí,

o gbójú sókè sí òrìṣà,

ó sì ń ṣe ohun ìríra.

13Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù.

Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.

14“Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:

15“Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga

tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli,

tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́

16tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára,

tí kò dá ohun ògo dúró

tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè

ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ,

tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.

17Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀,

kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù,

tí ó ń pa òfin mi mọ́,

tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi.

Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè! 18Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.

19“Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè. 20Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.

21“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú. 22A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè. 23Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?

24“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.

25“Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún? 26Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá. 27Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là. 28Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú. 29Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?

30“Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín. 3118.31: El 11.19; 36.26.Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli? 3218.32: El 18.23; 33.11.Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Езекиил 18:1-32

Личная ответственность за грех

1Было ко мне слово Вечного:

2– Что вы имеете в виду, повторяя о земле исроильской поговорку:

«Отцы ели кислый виноград,

а у детей на зубах оскомина»?

3Верно, как и то, что Я живу, – возвещает Владыка Вечный, – вы больше не будете произносить эту поговорку в земле исроильской. 4Знайте, всякая жизнь принадлежит Мне: и отец, и сын – оба Мои. Кто согрешит, тот и умрёт.

5Если кто-то праведен и поступает справедливо и праведно:

6не ест в горных капищах,

не поклоняется идолам исроильтян,

не соблазняет жены другого

и не спит с женщиной во время её месячных,

7никого не притесняет

и возвращает должнику взятое у того в залог,

не грабит,

даёт свой хлеб голодным

и одевает нагих,

8не даёт в рост денег

и не взимает процентов,

удерживает руку от преступления

и справедливо судит между спорящими,

9следует Моим установлениям

и усердно исполняет Мои законы –

тот праведен; он, несомненно, будет жить, – возвещает Владыка Вечный.

10Если у него есть сын, который разбойничает, проливает чужую кровь и делает что-либо из нижеследующего 11(хотя его отец и не делал ничего подобного):

ест в горных капищах,

соблазняет жену другого,

12притесняет нищих и бедняков,

грабит,

не возвращает должнику взятое у того в залог,

поклоняется идолам,

творит мерзости,

13даёт деньги в рост

и взимает проценты, –

будет ли он жить? Нет! За то, что он совершил эти мерзости, он, несомненно, умрёт и сам будет повинен в своей смерти.

14Но если у такого человека есть сын, который видит грехи, совершённые отцом, и, видя, не поступает по его примеру:

15не ест в горных капищах,

не поклоняется идолам исроильтян,

не соблазняет жены другого,

16никого не притесняет,

не требует залога,

не грабит,

даёт свой хлеб голодным

и одевает нагих,

17удерживает руку от преступления,

не даёт денег в рост и не взимает процентов,

исполняет Мои законы и следует Моим установлениям, –

то он не умрёт за грех отца; он, несомненно, будет жить. 18А его отец умрёт за свой грех, потому что он вымогал, грабил брата и творил зло среди своего народа.

19А вы спрашиваете: «Почему же сын не причастен к вине отца?» Раз сын поступал справедливо и праведно и прилежно исполнял Мои установления, он, несомненно, будет жить. 20Кто согрешил, тот и умрёт. Сын не будет причастен к вине отца, и отец не будет причастен к вине сына. Праведность будет засчитана праведнику, и нечестие будет засчитано нечестивому.

21Но если нечестивый оставит грехи, которые творит, станет исполнять Мои установления и делать то, что справедливо и праведно, он, несомненно, будет жить; он не умрёт. 22Ни одно из преступлений, которые он совершил, не припомнится ему. Ради сделанных им праведных дел он будет жить. 23Неужели Мне больше угодна смерть нечестивого, – возвещает Владыка Вечный, – а не то, чтобы он оставил свои поступки и жил?

24Но если праведник оставит праведность, совершит преступление и начнёт совершать те же мерзости, что и нечестивый, то разве он будет жить? Ни одно из сделанных им праведных дел не вспомнится. За вероломство, в котором он повинен, и за совершённые им грехи он умрёт.

25А вы говорите: «Путь Владыки несправедлив». Слушайте, исроильтяне: это Мой-то путь несправедлив? Не ваши ли пути несправедливы? 26Если праведник оставит праведность и совершит преступление, то за это он и умрёт; за сделанное им преступление он умрёт. 27А если нечестивый оставит нечестие, которое творит, и примется делать то, что справедливо и праведно, он спасёт себе жизнь. 28За то, что, признав все преступления, которые он творил, он больше не будет делать зло, он, несомненно, будет жить; он не умрёт. 29А исроильтяне говорят: «Путь Владыки несправедлив». Мои ли пути несправедливы, народ Исроила? Не ваши ли?

30Поэтому, исроильтяне, Я буду судить вас, каждого по его делам, – возвещает Владыка Вечный. – Покайтесь! Оставьте свои преступления, чтобы грех не погубил вас. 31Отвергните преступления, которые вы совершили, и обретите новое сердце и новый дух. Зачем вам умирать, народ Исроила? 32Ничья смерть Мне не угодна, – возвещает Владыка Вечный. – Покайтесь и живите!