Esekiẹli 17 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esekiẹli 17:1-24

Ẹyẹ idì méjì àti àjàrà

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé: 2“Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli. 3Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ, 4ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.

5“ ‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò. 6Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.

7“ ‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi. 8Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’

9“Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu. 10Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’ ”

11Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé: 12“Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀. 13Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ. 14Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́. 15Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?

16“ ‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà. 17Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn. 18Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.

19“ ‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀. 20Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi. 21Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”

22“ ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí. 2317.23: El 31.6; Mt 13.32; Mk 4.32; Lk 13.19.Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀. 24Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé.

“ ‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’ ”

New International Reader’s Version

Ezekiel 17:1-24

Two Eagles and a Vine

1A message from the Lord came to me. The Lord said, 2“Son of man, tell the people of Israel a story about their kings. Let them know what will happen to them. 3Tell them, ‘The Lord and King says, “A great eagle came to the city of ‘Lebanon.’ It had powerful wings and a lot of long feathers. The feathers were colorful and beautiful. The eagle landed in the top of a cedar tree. 4It broke off the highest twig. The eagle carried it away to the land of Babylon. There are many traders in that land. The eagle planted the twig in the city of Babylon.

5“ ‘ “Then it took from the land a seed that had just sprouted. It put it in rich soil near plenty of water. It planted the seed like a willow tree. 6The seed grew into a low, spreading vine. Its branches turned toward the eagle. And its roots remained under the eagle. So the seed became a vine. It produced branches and put out leaves.

7“ ‘ “But there was another great eagle. It also had powerful wings and a lot of feathers. The vine now sent out its roots toward that eagle. It sent them out from the place where it was planted. And it reached out its branches to the eagle for water. 8The seed had been planted in good soil near plenty of water. Then it could produce branches and bear fruit. It could become a beautiful vine.” ’

9“Ezekiel, tell the Israelites, ‘The Lord and King asks, “Will the vine grow? Won’t it be pulled up by its roots? Won’t all its fruit be stripped off? Won’t it dry up? All its new growth will dry up. It will not take a strong arm or many people to pull it up. 10It has been planted, but will it grow? No. It will dry up completely when the east wind strikes it. It will dry up in the place where it grew.” ’ ”

11A message from the Lord came to me. The Lord said, 12“These people refuse to obey me. Ask them, ‘Don’t you know what these things mean?’ Tell them, ‘Nebuchadnezzar went to Jerusalem. He was the king of Babylon. He carried off King Jehoiachin and the nobles. He brought them back with him to the city of Babylon. 13Then Nebuchadnezzar made a peace treaty with Zedekiah. He was a member of Jerusalem’s royal family. Nebuchadnezzar made him promise he would keep the treaty. He also took away the leading men of the land as prisoners. 14He did it to bring down their kingdom. It would not rise again. In fact, it would be able to last only by keeping his treaty. 15But Zedekiah turned against him. He sent messengers to Egypt. They went there to get horses and a large army. Will he succeed? Will he who does things like that escape? Can he break the peace treaty and still escape?

16“ ‘Zedekiah will die in Babylon,’ announces the Lord and King. ‘And that is just as sure as I am alive. He will die in the land of King Nebuchadnezzar, who put him on the throne. Zedekiah didn’t keep his promise to Nebuchadnezzar and broke his treaty. 17So Nebuchadnezzar will build ramps against the walls of Jerusalem. He will set up war machines to destroy many lives. Pharaoh will not be able to help Zedekiah during the war. The huge and mighty army of Egypt will not be of any help. 18Zedekiah didn’t keep his promise to Nebuchadnezzar and broke his treaty. Zedekiah had made a firm promise to keep it. But he broke it anyway. So he will not escape.

19“ ‘The Lord and King says, “Zedekiah didn’t keep the promise he made in my name. He broke the treaty. So I will pay him back. And that is just as sure as I am alive. 20I will spread out my net to catch him. He will be caught in my trap. I will bring him to Babylon. I will judge him there because he was not faithful to me. 21All Zedekiah’s best troops will be killed by swords. Those who are left alive will be scattered to the winds. Then you will know that I have spoken. I am the Lord.”

22“ ‘The Lord and King says, “I myself will get a twig from the very top of a cedar tree and plant it. I will break off the highest twig. I will plant it on a very high mountain. 23I will plant it on the high mountains of Israel. It will produce branches and bear fruit. It will become a beautiful cedar tree. All kinds of birds will make their nests in it. They will live in the shade of its branches. 24All the trees in the forest will know that I bring down tall trees. I make short trees grow tall. I dry up green trees. And I make dry trees green.”

“ ‘I have spoken. I will do this. I am the Lord.’ ”