Deuteronomi 30 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Deuteronomi 30:1-20

Àlàáfíà lẹ́yìn ìyípadà sí Ọlọ́run

1Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, 2àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí. 3Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí. 430.4: Mt 24.31; Mk 13.27.Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà. 5Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ. 6Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ. 7Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ. 8Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí. 9Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ. 10Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.

Ìfifún ìyè tàbí ikú

11Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ. 1230.12,13: Ro 10.6,7.Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?” 13Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?” 1430.14: Ro 10.8.Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.

15Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun. 16Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.

17Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n, 18èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.

19Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ, 20kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.

La Bible du Semeur

Deutéronome 30:1-20

Les bénédictions d’un retour à l’Eternel

1Ces paroles que je viens de prononcer, les bénédictions et les malédictions entre lesquelles je vous offre le choix, se réaliseront. Si vous les prenez de nouveau à cœur, au milieu de tous les peuples parmi lesquels l’Eternel votre Dieu vous aura dispersés, 2si vous revenez à l’Eternel votre Dieu et si vous l’écoutez en obéissant de tout votre cœur et de tout votre être, vous et vos enfants, à tout ce que je vous ordonne aujourd’hui, 3alors l’Eternel votre Dieu aura compassion de vous : il vous restaurera30.3 On peut peut-être traduire il ramènera ceux d’entre vous qui auront été en captivité. et vous rassemblera pour vous faire revenir de chez tous les peuples parmi lesquels il vous aura dispersés. 4Même si les exilés de votre peuple sont aux confins du monde, l’Eternel votre Dieu ira les chercher là-bas et les rassembler 5pour les ramener au pays que leurs ancêtres auront possédé et ils en retrouveront la possession. Il les y rendra plus heureux et plus nombreux que leurs ancêtres. 6L’Eternel votre Dieu vous circoncira le cœur et celui de vos descendants pour que vous l’aimiez de tout votre cœur et de tout votre être, et qu’ainsi vous viviez. 7Il infligera alors toutes ces malédictions que je vous ai décrites à vos ennemis, à ceux qui vous haïssent et qui vous auront persécutés. 8Quant à vous, vous reviendrez à lui, vous l’écouterez et vous appliquerez tous ses commandements que je vous transmets aujourd’hui. 9L’Eternel votre Dieu vous comblera de bonheur en faisant réussir tout ce que vous entreprendrez ; il vous donnera de nombreux enfants, il multipliera votre bétail et vous accordera d’abondantes récoltes. Car l’Eternel prendra de nouveau plaisir à votre bonheur comme il prenait plaisir à celui de vos ancêtres, 10pourvu que vous l’écoutiez en obéissant à ses commandements et ses ordonnances consignés dans ce livre de la Loi, et que vous reveniez à lui de tout votre cœur et de tout votre être !

La Loi dans le cœur

11Le code de lois que je vous donne aujourd’hui n’est certainement pas trop difficile pour vous, ni hors de votre portée. 12Il n’est pas au ciel pour que l’on dise : « Qui montera au ciel pour aller nous le chercher et nous le faire comprendre afin que nous puissions l’appliquer ? » 13Il n’est pas non plus au-delà de l’océan pour que l’on dise : « Qui traversera pour nous les mers pour aller nous le chercher, et nous le faire comprendre, afin que nous puissions l’appliquer ? » 14Non, la parole est toute proche de vous : elle est dans votre bouche et dans votre cœur, pour que vous l’appliquiez30.14 Les formules de ce verset sont reprises en Rm 10.6-8..

La vie et la mort

15Voyez, je place aujourd’hui devant vous, d’un côté, la vie et le bonheur, de l’autre, la mort et le malheur. 16Ce que je vous commande aujourd’hui, c’est d’aimer l’Eternel votre Dieu, de suivre le chemin qu’il vous trace et d’obéir à ses commandements, ses ordonnances et ses lois. En faisant cela, vous aurez la vie, vous deviendrez nombreux et vous serez bénis par l’Eternel votre Dieu dans le pays où vous vous rendez pour en prendre possession. 17Mais si votre cœur se détourne de lui, si vous refusez de lui obéir et si vous vous laissez entraîner à adorer d’autres dieux et à leur rendre un culte, 18je vous préviens dès aujourd’hui que vous périrez à coup sûr. Vous ne vivrez pas longtemps dans le pays au-delà du Jourdain où vous vous rendez pour en prendre possession.

19Je prends aujourd’hui le ciel et la terre à témoins : je vous offre le choix entre la vie et la mort, entre la bénédiction et la malédiction. Choisissez donc la vie, afin que vous viviez, vous et vos descendants. 20Choisissez d’aimer l’Eternel votre Dieu, de lui obéir et de lui rester attachés, car c’est lui qui vous fait vivre et qui pourra vous accorder de passer de nombreux jours dans le pays que l’Eternel a promis par serment de donner à vos ancêtres Abraham, Isaac et Jacob30.20 Voir Gn 12.7 ; 26.3 ; 28.13..