Deuteronomi 19 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Deuteronomi 19:1-21

Ìlú ààbò

119.1-13: Ek 21.12-14; Nu 35.Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá ti pa àwọn orílẹ̀-èdè tí yóò fi ilẹ̀ wọn fún ọ run, àti nígbà tí ìwọ bá ti lé wọn jáde tí o sì dó sí àwọn ilẹ̀ àti ilé wọn gbogbo. 2Ìwọ yóò ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara à rẹ láàrín ilẹ̀ rẹ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ láti ni. 3Ṣe àwọn ọ̀nà sí wọn àti kí o pín ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún sí ọ̀nà mẹ́ta nítorí kí apànìyàn lè sá níbẹ̀.

4Èyí ni òfin nípa apànìyàn, tí ó sì sá síbẹ̀ láti pa ẹ̀mí rẹ̀ mọ́. Ẹni tí ó pa aládùúgbò láìmọ̀ọ́mọ̀ṣeé láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́. 5Bí àpẹẹrẹ, ọkùnrin kan lè lọ sínú igbó pẹ̀lú aládùúgbò rẹ̀ láti gé igi, bí ó sì ti gbé àáké e rẹ̀ láti gé igi náà lulẹ̀, bí àáké náà bá yọ tí ó sì bà aládùúgbò rẹ̀, tí òun sì kú. Ọkùnrin yìí lè sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú yìí láti gba ẹ̀mí rẹ̀ là. 6Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lè máa lépa rẹ̀ nínú ìbínú, kí ó sì lé e bá nítorí pé ọ̀nà jì, kí ó sì pa á bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò yẹ sí ikú, nígbà tí ó ṣe é sí aládùúgbò rẹ̀ láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́. 7Ìdí nìyìí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara rẹ.

8Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì fẹ́ agbègbè rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba ńlá a yín, tí ó sì fún ọ ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ti ṣe ìlérí fún wọn, 9nítorí tí ìwọ fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ tẹ̀lé gbogbo òfin yìí tí mo pàṣẹ fún ọ lónìí yìí, kí o fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì rìn ní ọ̀nà an rẹ̀ ní gbogbo ìgbà náà, kí o ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀. 10Ṣe èyí kí a má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ni ilẹ̀ rẹ, èyí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, kí ìwọ kí ó má bá a jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ títa.

11Ṣùgbọ́n tí ọkùnrin kan bá kórìíra arákùnrin rẹ̀, tí ó sì lúgọ dè é, tí ó mú u tí o lù ú pa, tí ọkùnrin náà sì sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, 12àwọn àgbàgbà ìlú rẹ yóò sì ránṣẹ́ pè é ìwọ, yóò sì mú un padà láti ìlú náà, wọn yóò sì fi í lé àwọn agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lọ́wọ́ kí ó lè kú. 13Má ṣe ṣàánú fún un. O ní láti fọ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò ni Israẹli, kí ó bá à lè dára fún ọ.

14Má ṣe pa òkúta ààlà aládùúgbò rẹ dà tí aṣíwájú rẹ fi lélẹ̀ nínú ogún tí ó gbà nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ni ní ìní.

Ẹlẹ́rìí

1519.15: Nu 35.30; De 17.6; Mt 18.16; 2Kọ 13.1; 1Tm 5.19; Hb 10.28.Ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo kò tó láti dájọ́ ọkùnrin kan tí o fi ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yóò wù kí ó lè ṣẹ̀ lẹ́bi. A ó fi ìdí ọ̀rọ̀ múlẹ̀ láti orí ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta.

1619.16-20: El 20.16; 23.1; Le 19.16; De 5.20.Tí alárankàn ẹlẹ́rìí èké bá dúró láti fi ẹ̀sùn ẹ̀ṣẹ̀ kan ọkùnrin kan, 17àwọn méjèèjì tí àríyànjiyàn wà láàrín wọn gbọdọ̀ dúró níwájú Olúwa níwájú àwọn àlùfáà àti àwọn adájọ́ tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní ìgbà náà. 18Àwọn adájọ́ gbọdọ̀ ṣe ìwádìí fínní fínní bí ẹ̀rí bá sì jẹ́ irọ́, tí ó fi ẹ̀rí èké sun arákùnrin rẹ̀, 1919.19: 1Kọ 5.13.nígbà náà ni kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ṣe fẹ́ ṣe sí arákùnrin rẹ̀. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ. 20Àwọn ènìyàn tókù yóò gbọ́ nípa èyí, wọn yóò sì bẹ̀rù, kí irú nǹkan búburú bẹ́ẹ̀ máa tún sẹ̀ mọ́ láàrín yín. 2119.21: El 21.23-26; Le 24.20; Mt 5.38.Má ṣe fi àánú hàn, ẹ̀mí fún ẹ̀mí, ojú fún ojú, eyín fún eyín, apá fún apá, ẹsẹ̀ fún ẹsẹ̀.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Второзаконие 19:1-21

Города-убежища

(Чис. 35:6-34; Втор. 4:41-43; Иеш. 20:1-9)

1Исроил, когда Вечный, твой Бог, истребит народы, землю которых Он отдаёт тебе, и когда ты прогонишь их и поселишься в их городах и домах, 2тогда отдели три города, расположенные посередине земли, которую Вечный, твой Бог, отдаёт тебе во владение. 3Проложи к ним дороги и раздели на три части землю, которую Вечный, твой Бог, отдаёт тебе как наследие, чтобы всякий, кто убьёт кого-либо, мог туда убежать.

4Вот правило о человеке, который совершит убийство и убежит туда, чтобы спасти свою жизнь, о всяком, кто убьёт человека неумышленно, не питая к убитому ненависти. 5Например, человек пойдёт в лес с кем-нибудь, чтобы нарубить дров. А когда он замахнётся на дерево топором, топор слетит с топорища, ударит другого и убьёт его. Такой человек может убежать в один из этих городов и спасти свою жизнь. 6Иначе, если расстояние слишком велико, мститель за кровь может погнаться за ним в гневе, настигнуть и убить. Хотя тот и не заслуживает смерти, потому что убил неумышленно, не питая к убитому ненависти. 7Вот почему я повелеваю тебе отделить три города.

8Когда Вечный, твой Бог, расширит твои владения, как Он клялся твоим предкам, и даст тебе всю землю, которую обещал им, 9если ты будешь прилежно следовать всем повелениям, которые я даю тебе сегодня, – любить Вечного, твоего Бога, и всегда ходить Его путями, – то выбери ещё три города. 10Сделай это, чтобы в твоей земле, которую Вечный, твой Бог, даёт тебе в наследие, не проливалась невинная кровь, и чтобы ты не был виновным в кровопролитии.

11Но если человек из ненависти к ближнему, устроит ему засаду, нападёт на него и убьёт, а потом убежит в один из этих городов, 12то старейшины его города должны послать за ним, чтобы вернуть его из города-убежища и передать мстителю за кровь. И пусть он умрёт. 13Не жалей его. Ты должен искоренить в Исроиле грех пролития невинной крови, чтобы в дальнейшем у тебя всё было благополучно.

14Не передвигай межу ближнего твоего, установленную твоими предшественниками в наследии, которое ты получил в земле, которую Вечный, твой Бог, отдаёт тебе во владение.

Свидетели

15Чтобы осудить человека, обвиняемого в каком бы то ни было преступлении или проступке, одного свидетеля недостаточно. Любое обвинение должно подтверждаться показаниями двух или трёх свидетелей.

16Если свидетель встанет, чтобы обвинить человека в преступлении, 17то двое участников тяжбы должны предстать перед Вечным, священнослужителями и судьями, которые будут в те дни. 18Судьи должны тщательно расследовать дело, и если свидетель окажется лгуном, дающим ложное показание против своего брата, 19то вы должны сделать с ним то, что он хотел сделать со своим братом. Вы должны искоренить зло из своей среды. 20Остальной народ услышит об этом и испугается, и впредь такое зло никогда не повторится. 21Не поддавайся жалости: жизнь за жизнь, глаз за глаз, зуб за зуб, рука за руку, нога за ногу.