1Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
21.2: Jl 3.16.Ó wí pé:
“Olúwa yóò bú jáde láti Sioni
ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;
Ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,
orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli
31.3-5: Isa 17.1-3; Jr 49.23-27; Sk 9.1.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.
Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú
4Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli
Èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;
Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní Àfonífojì Afeni run
àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.
Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”
ni Olúwa wí.
61.6-8: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,
àní nítorí mẹ́rin,
Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,
ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.
Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa
tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run
8Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,
ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.
Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni
títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”
ni Olúwa Olódùmarè wí.
91.9-10: Isa 23; El 26.1–28.19; Jl 3.4-8; Sk 9.3-4.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu
Wọn kò sì nání májẹ̀mú ọbàkan,
10Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire
Tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
111.11-12: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Ọd; Ml 1.2-5.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,
Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù
ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí
ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́
12Èmi yóò rán iná sí orí Temani
Tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
131.13-15: Jr 49.1-6; El 21.28-32; 25.1-7; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
ni Olúwa wí.
1Estas son las palabras de Amós, uno de los pastores de Tecoa. Es la visión que recibió acerca de Israel dos años antes del terremoto, cuando Uzías era rey de Judá y Jeroboán, hijo de Joás, era rey de Israel.
2Él dijo:
«Ruge el Señor desde Sión;
truena su voz desde Jerusalén.
Los pastizales de los pastores quedan asolados,
y se seca la cumbre del Carmelo».
Juicio contra las naciones vecinas
3Así dice el Señor:
«Por tres pecados de Damasco y por el cuarto,1:3 Por … y por el cuarto. Expresión hebrea que puede traducirse como son tantos los delitos de. Así en 1:6, 9, 11, 13; 2:1, 4 y 6.
no anularé su castigo:
Porque trillaron a Galaad
con trillos de hierro.
4Por eso yo enviaré fuego sobre el palacio de Jazael
que consumirá las fortalezas de Ben Adad.
5Romperé el cerrojo de la puerta de Damasco,
destruiré al rey que está en el valle de Avén1:5 Avén. Alt. maldad.
y al que empuña el cetro en Bet Edén.
Y el pueblo de Aram será desterrado a Quir»,
dice el Señor.
6Así dice el Señor:
«Por tres pecados de Gaza y por el cuarto,
no anularé su castigo,
porque tomaron cautivas poblaciones enteras
para venderlas a Edom.
7Por eso yo enviaré fuego sobre los muros de Gaza
que consumirá sus fortalezas.
8Destruiré al rey de Asdod
y al que empuña el cetro en Ascalón.
Volveré mi mano contra Ecrón,
y perecerá hasta el último de los filisteos»,
dice el Señor y Dios.
9Así dice el Señor:
«Por tres pecados de Tiro y por el cuarto,
no anularé su castigo:
Porque le vendieron a Edom poblaciones enteras de cautivos,
olvidando así una alianza entre hermanos.
10Por eso yo enviaré fuego sobre los muros de Tiro
que consumirá sus fortalezas».
11Así dice el Señor:
«Por tres pecados de Edom y por el cuarto,
no anularé su castigo:
Porque persiguió a espada a su hermano
y mató a las mujeres del país;
porque dio rienda suelta a la ira
y no dejó de alimentar el enojo.
12Por eso yo enviaré fuego sobre Temán
que consumirá las fortalezas de Bosra».
13Así dice el Señor:
«Por tres pecados de Amón y por el cuarto,
no anularé su castigo,
porque abrieron el vientre a las mujeres embarazadas de Galaad
a fin de extender sus fronteras.
14Por eso yo prenderé fuego a los muros de Rabá
que consumirá sus fortalezas
entre gritos de guerra en el día de la batalla,
y en el rugir de la tormenta en un día de tempestad.
15Su rey1:15 Su rey. Alt. Milcón. marchará al destierro,
junto con sus oficiales»,
dice el Señor.