Amosi 1 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 1:1-15

1Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.

21.2: Jl 3.16.Ó wí pé,

Olúwa yóò bú jáde láti Sioni,

ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;

ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,

orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”

Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli

31.3-5: Isa 17.1-3; Jr 49.23-27; Sk 9.1.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.

Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,

4Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli,

èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.

5Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;

Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run

àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.

Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”

ni Olúwa wí.

61.6-8: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,

àní nítorí mẹ́rin,

Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,

ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.

Ó sì tà wọ́n fún Edomu,

7Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa

tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.

8Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,

ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.

Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni

títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

91.9-10: Isa 23; El 26.1–28.19; Jl 3.4-8; Sk 9.3-4.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu.

Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,

10Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire,

tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”

111.11-12: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Od 1-9; Ml 1.2-5.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,

Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù,

ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí,

ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,

12Èmi yóò rán iná sí orí Temani,

tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”

131.13-15: Jr 49.1-6; El 21.28-32; 25.1-7; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni,

àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi

kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.

14Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba

èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run

pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,

pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.

15Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn,

òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”

ni Olúwa wí.

Japanese Contemporary Bible

アモス書 1:1-15

1

1アモスはテコアの村に住む羊飼いでした。一日中、丘の中腹にいて、羊が迷い出ないように見張っていたのです。

イスラエルの隣人へのさばき

2ある日、神はアモスに、イスラエルに起ころうとしていることを幻の中で語りました。この幻をアモスが見たのは、ウジヤがユダの王、ヨアシュの子ヤロブアムがイスラエルの王であった時で、地震が起こる二年前のことでした。

アモスは見聞きしたことを、次のように報告しています。

主は、ねぐらからほえるどう猛なライオンのように、

シオンの山にある神殿から、大声で叫びました。

すると突然、カルメル山のみずみずしい牧草地が

しおれて枯れ、羊飼いはみな、声を上げて泣きました。

3主はこう言います。

「ダマスコの民は何度もくり返して罪を犯し、

わたしはそのことを忘れない。

もうこれ以上、処罰を猶予しない。

彼らは穀物を鉄の打穀棒で打つように、

ギルアデでわたしの民を打った。

4だから、ハザエル王の宮殿に火を放ち、

ベン・ハダデの堅固なとりでを破壊する。

5ダマスコの町の門のかんぬきを折り、

アベンの平野に住む者や、

ベテ・エデンで王位についている者を殺す。

シリヤの民は奴隷としてキルに戻る。」

6主はこう言います。

「ガザは何度もくり返して罪を犯し、

わたしはそのことを忘れない。

もうこれ以上、処罰を猶予しない。

ガザはわたしの民を追い出し、

エドムで奴隷として売った。

7だから、ガザの城壁に火を放ち、

とりではすべて破壊される。

8アシュドデの民を殺し、

エクロンと、アシュケロンの王を滅ぼそう。

残ったペリシテ人は滅びる。」

9主はこう言います。

「ツロの民は何度もくり返して罪を犯し、

わたしはそのことを忘れない。

もうこれ以上、処罰を猶予しない。

彼らは兄弟であるイスラエルとの協定を破り、

攻撃をしかけて征服し、奴隷としてエドムに渡した。

10だから、ツロの城壁に火を放ち、

とりでも宮殿も灰にする。」

11主はこう言います。

「エドムは何度もくり返して罪を犯し、

わたしはそのことを忘れない。

もうこれ以上、処罰を猶予しない。

彼らは兄弟であるイスラエルを剣で追いかけ、

怒りにまかせて冷酷にふるまった。

12だから、テマンに火をかけ、

ボツラのとりでをすべて灰にする。」

13主はこう言います。

「アモンの民は何度もくり返して罪を犯し、

わたしはそのことを忘れない。

もうこれ以上、処罰を猶予しない。

彼らはギルアデの戦いで、領土を広げるために

残虐なことを行い、剣で妊婦を切り裂いた。

14だから、ラバの城壁に火を放ち、

とりでと宮殿は灰となる。

嵐の時のつむじ風のように、

戦いのものすごい叫び声が上がる。

15王も君主たちも捕囚として連れ去られる。」