Amosi 1 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 1:1-15

1Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.

21.2: Jl 3.16.Ó wí pé,

Olúwa yóò bú jáde láti Sioni,

ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;

ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,

orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”

Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli

31.3-5: Isa 17.1-3; Jr 49.23-27; Sk 9.1.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.

Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,

4Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli,

èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.

5Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;

Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run

àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.

Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”

ni Olúwa wí.

61.6-8: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,

àní nítorí mẹ́rin,

Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,

ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.

Ó sì tà wọ́n fún Edomu,

7Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa

tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.

8Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,

ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.

Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni

títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

91.9-10: Isa 23; El 26.1–28.19; Jl 3.4-8; Sk 9.3-4.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu.

Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,

10Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire,

tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”

111.11-12: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Od 1-9; Ml 1.2-5.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,

àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,

Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù,

ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí,

ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,

12Èmi yóò rán iná sí orí Temani,

tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”

131.13-15: Jr 49.1-6; El 21.28-32; 25.1-7; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni,

àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi

kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.

14Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba

èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run

pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,

pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.

15Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn,

òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”

ni Olúwa wí.

Hoffnung für Alle

Amos 1:1-15

Amos kündigt Juda, Israel und den Nachbarvölkern Gottes Gericht an

(Kapitel 1–6)

Gott spricht sein Urteil über Israels Nachbarvölker

1In diesem Buch sind die Worte von Amos aufgeschrieben, einem Schafzüchter aus dem Dorf Tekoa. Zwei Jahre vor dem großen Erdbeben offenbarte ihm Gott, was er mit dem Nordreich Israel vorhatte. Damals regierte in Juda König Usija, und in Israel herrschte Jerobeam, der Sohn von Joasch.

2Amos verkündete dem Volk:

»Mächtig wie das Brüllen eines Löwen ertönt die Stimme des Herrn vom Berg Zion in Jerusalem. Da vertrocknen die saftigen Weiden der Hirten, und die Wälder auf dem Gipfel des Karmel verdorren.

3So spricht der Herr: Die Leute von Damaskus begehen ein abscheuliches Verbrechen nach dem anderen. Sie haben die Bewohner von Gilead wie mit einem eisernen Dreschschlitten niedergewalzt und zermalmt. Das werde ich nicht ungestraft lassen! 4Ich brenne die Paläste nieder, die König Hasaël und König Ben-Hadad errichtet haben. 5Ich zerschmettere die Riegel an den Stadttoren von Damaskus und töte die Herrscher von Bikat-Awen (›Unrechtstal‹) und Bet-Eden (›Freudenhaus‹). Die Bevölkerung von Syrien wird nach Kir verschleppt. Darauf gebe ich, der Herr, mein Wort!

6So spricht der Herr: Die Leute von der Philisterstadt Gaza begehen ein abscheuliches Verbrechen nach dem anderen. Sie haben die Einwohner ganzer Dörfer gefangen genommen und an die Edomiter verkauft. Das werde ich nicht ungestraft lassen! 7Ich brenne die Stadtmauern von Gaza nieder, seine Paläste werden ein Raub der Flammen. 8Die Herrscher von Aschdod und Aschkelon bringe ich um, und auch die Stadt Ekron bekommt meine Macht zu spüren. Die Philister, die dann noch übrig geblieben sind, finden den Tod. Darauf gebe ich, Gott, der Herr, mein Wort!

9So spricht der Herr: Die Leute von Tyrus begehen ein abscheuliches Verbrechen nach dem anderen. Sie haben ihren Freundschaftsbund mit Israel gebrochen und die Einwohner ganzer Dörfer an die Edomiter verkauft. Das werde ich nicht ungestraft lassen! 10Ich brenne die Stadtmauern von Tyrus nieder, seine Paläste werden ein Raub der Flammen.

11So spricht der Herr: Die Leute von Edom begehen ein abscheuliches Verbrechen nach dem anderen. Sie haben die Israeliten, ihr Brudervolk, erbarmungslos bekämpft und unschuldiges Blut vergossen. Ihr Hass kennt keine Grenzen, ständig führen sie Krieg gegen mein Volk. Das werde ich nicht ungestraft lassen! 12Ich brenne Teman nieder, und auch die Paläste der Hauptstadt Bozra werden ein Raub der Flammen.

13So spricht der Herr: Die Leute von Ammon begehen ein abscheuliches Verbrechen nach dem anderen. Sie führten Krieg, um ihre Herrschaft auszudehnen, sie ließen sogar schwangeren Frauen im Gebiet von Gilead den Bauch aufschlitzen. Das werde ich nicht ungestraft lassen! 14Die Mauern ihrer Hauptstadt Rabba lege ich in Schutt und Asche, ihre Paläste werden ein Raub der Flammen. Dann ertönt überall das Kriegsgeschrei, und die Schlacht tobt wie ein verheerender Sturm. 15Der König der Ammoniter und alle führenden Männer werden in die Verbannung geschickt. Darauf gebe ich, der Herr, mein Wort!