1Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
21.2: Jl 3.16.Ó wí pé:
“Olúwa yóò bú jáde láti Sioni
ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;
Ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,
orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli
31.3-5: Isa 17.1-3; Jr 49.23-27; Sk 9.1.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.
Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú
4Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli
Èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;
Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní Àfonífojì Afeni run
àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.
Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”
ni Olúwa wí.
61.6-8: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Sf 2.4-7; Sk 9.5-7.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,
àní nítorí mẹ́rin,
Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,
ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.
Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa
tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run
8Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,
ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.
Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni
títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”
ni Olúwa Olódùmarè wí.
91.9-10: Isa 23; El 26.1–28.19; Jl 3.4-8; Sk 9.3-4.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu
Wọn kò sì nání májẹ̀mú ọbàkan,
10Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire
Tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
111.11-12: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Ọd; Ml 1.2-5.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,
àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,
Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù
ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí
ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́
12Èmi yóò rán iná sí orí Temani
Tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
131.13-15: Jr 49.1-6; El 21.28-32; 25.1-7; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
ni Olúwa wí.
1Amos, Tekoa nguanhwɛfo no mu baako nsɛm ni. Onyaa saa anisoadehu yi a ɛfa Israel ho mfe abien ansa na asase wosowee, bere a Usia di hene wɔ Yuda na Yoas babarima Yeroboam nso di hene wɔ Israel no.
2Ɔkae se,
“Awurade bobɔ mu fi Sion bepɔw so
na ɔde aprannaa nnyigyei nso fi Yerusalem;
nguanhwɛfo mmoa adidibea rehyew
na Karmel atifi nso kisa.”
Atemmu A Ɛfa Amanamanmufo Ahorow Ho
3Nea Awurade se ni:
“Damasko ayɛ bɔne bebree ama no atra so
ɛno nti, merennan mʼabufuw.
Efisɛ ɔde awiporowbea ade a ɛwɔ dade se
dwerɛw Gilead.
4Mede ogya bɛto Hasael fi
na ahyew Ben-Hadad aban no.
5Mebubu Damasko apon,
na mɛsɛe ɔhene a ɔwɔ Awen bon no mu no
ne nea okura ahempema wɔ Bet Eden no.
Na Aramfo bɛkɔ nnommum mu wɔ Kir,”
sɛnea Awurade se ni.
6Nea Awurade se ni:
“Gasa ayɛ bɔne bebree ama no atra so,
ɛno nti, merennan mʼabufuw no.
Ɔfaa ɔman mu no nyinaa nnommum
na ɔtɔn wɔn maa Edomfo.
7Mede ogya bɛto Gasa afasu mu,
na ahyew nʼaban no.
8Mɛsɛe Asdod hene no
ne nea okura ahempema wɔ Askelon no.
Mɛdan me nsa atia Ekron,
kosi sɛ Filistini a otwa to no bewu,”
sɛnea Asafo Awurade se ni.
9Nea Awurade se ni:
“Tiro ayɛ bɔne bebree ama no atra so,
ɛno nti, merennan mʼabufuw.
Ɔfaa ɔmanmu no nnommum
na ɔtɔn wɔn maa Edomfo,
a wankae onuadɔ apam.
10Mede ogya bɛto Tiro afasu no mu,
na ahyew nʼaban.”
11Nea Awurade se ni:
“Edom ayɛ bɔne bebree ama no atra so,
ɛno nti, merennan mʼabufuw.
Ɔde afoa taataa ne nua,
a wannya ayamhyehye biara.
Efisɛ ne bo kɔɔ so fuwii,
na obiara antumi annwudwo nʼabufuw no ano.
12Mede ogya bɛto Teman mu,
na ahyew Bosra aban.”
13Sɛnea Awurade se ni:
“Amon ayɛ bɔne bebree ama no atra so,
ɛno nti, merennan mʼabufuw.
Ɔde afoa paapaee Gilead apemfo yafunu mu
de trɛw nʼahye mu.
14Mede ogya bɛto Raba afasu mu
na ahyew nʼaban
wɔ ɔko da mu nteɛteɛmu
ne ahum da mfɛtɛ mu.
15Na ne hene ne mmapɔmma
bɛbɔ mu akɔ nnommum mu,”
sɛnea Awurade se ni.