2 Ọba 3 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Ọba 3:1-27

Ọ̀tẹ̀ Moabu

1Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá. 2Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò. 3Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.

4Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún (100,000) àgbò. 5Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli. 6Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà. 7Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?”

Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”

8“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè.

“Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.

9Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.

10“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”

11Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”

Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”

12Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.

13Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.”

Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”

14Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ. 15Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.”

Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa. 16Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’ 17Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu. 18Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú. 19Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”

20Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.

21Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀. 22Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀. 23“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”

24Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run. 25Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.

26Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin (700) ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege. 27Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

New International Reader’s Version

2 Kings 3:1-27

Moab’s King Refuses to Obey Israel’s King

1Joram became king of Israel in Samaria. It was in the 18th year that Jehoshaphat was king of Judah. Joram ruled for 12 years. He was the son of Ahab. 2Joram did what was evil in the sight of the Lord. But he wasn’t as bad as his father and mother had been. Joram’s father had made a sacred stone used to worship the god named Baal. Joram got rid of it. 3But he kept on committing the sins of Jeroboam, the son of Nebat. Jeroboam had also caused Israel to commit those same sins. Joram didn’t turn away from them.

4Mesha raised sheep. He was king of Moab. He had to pay the king of Israel 100,000 lambs a year. He also had to pay him with the wool of 100,000 rams a year. 5After Ahab died, Moab’s king refused to obey the next king of Israel. 6So at that time King Joram started out from Samaria. He gathered together all of Israel’s troops. 7He also sent a message to Jehoshaphat, the king of Judah. Joram said, “The king of Moab is refusing to obey me. Will you go with me to fight against Moab?”

“Yes. I’ll go with you,” Jehoshaphat replied. “My men will go with you. My horses will also go with you.”

8“What road should we take to attack Moab?” Joram asked.

“The one that goes through the Desert of Edom,” Jehoshaphat answered.

9So the king of Israel marched out. The king of Judah and the king of Edom went with him. Their armies marched around the southern end of the Dead Sea. After seven days they ran out of water. There wasn’t any water for the men or their animals.

10“What should we do now?” exclaimed the king of Israel. “The Lord has called us three kings together. Did he do it only to hand us over to Moab?”

11But Jehoshaphat asked, “Isn’t there a prophet of the Lord here? Can’t we ask the Lord for advice through him?”

An officer of the king of Israel answered, “Elisha is here. He’s the son of Shaphat. Elisha used to serve Elijah.”

12Jehoshaphat said, “The Lord speaks through him.” So the king of Israel went down to see Elisha. Jehoshaphat and the king of Edom also went there.

13Elisha said to the king of Israel, “Why do you want to come to me? Go to your father’s prophets. Go to your mother’s prophets.”

“No,” the king of Israel answered. “The Lord called us three kings together. He did it to hand us over to Moab.”

14Elisha said, “I serve the Lord who rules over all. You can be sure that he lives. And you can be just as sure that I have respect for Jehoshaphat, the king of Judah. If I didn’t, I wouldn’t pay any attention to you. 15But now bring me someone who plays the harp.”

While that person was playing the harp, the Lord’s power came on Elisha. 16Elisha announced, “The Lord says, ‘I will fill this valley with pools of water.’ 17This will happen because the Lord says, ‘You will not see wind or rain. But this valley will be filled with water. Then you, your cattle and your other animals will have water to drink.’ 18This is an easy thing for the Lord to do. He will also hand Moab over to you. 19You will destroy every city that has high walls around it. You will destroy every major town. You will cut down every good tree. You will stop up all the springs of water. And you will cover every good field with stones.”

20The next day, the time came to offer the morning sacrifice. And then it happened! Water was flowing from the direction of Edom! In fact, the land was filled with water!

21Now all the people of Moab had heard that the kings had come to fight against them. So the king of Moab sent for all Moab’s fighting men. It didn’t matter whether they were young or old. He sent for everyone who could carry a weapon. All of them were stationed at the border. 22They got up early in the morning. The sun was already shining on the water. Across the way, the water looked red to the men of Moab. It looked like blood. 23“That’s blood!” they said. “Those kings must have fought and killed each other. Let’s go, Moab! Let’s take everything that has any value.”

24So the men of Moab went to the camp of Israel. Just as they arrived there, the men of Israel got ready to fight. They fought against the men of Moab until those men ran away. The men of Israel marched into the land and attacked it. They killed the people of Moab. 25They destroyed the towns. Each man threw a large stone on every good field. They did that until the fields were covered. They stopped up all the springs of water. And they cut down every good tree. The only town left with any stones in place was Kir Hareseth. But some of the Israelites armed with slings surrounded it. Then they attacked it.

26The king of Moab saw that the battle had gone against him. So he took with him 700 men who had swords. They tried to break through the battle lines to the king of Edom. But they couldn’t do it. 27Then the king of Moab took his oldest son. He was the son who would become the next king of Moab. But the king offered his son as a sacrifice on the city wall. That shocked and terrified the men of Israel. So they pulled back and returned to their own land.