1 Timotiu 6 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Timotiu 6:1-21

Àwọn ẹrú

1Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí i ṣe ẹrú lábẹ́ ìsìnrú máa ka àwọn olówó tí ó ni wọ́n yẹ sí ọlá gbogbo, kí a má bà á sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Ọlọ́run àti ẹ̀kọ́ rẹ̀. 2Àwọn ti ó ní ọ̀gá onígbàgbọ́, kí wọn má ṣe ṣàìbọ̀wọ̀ fún wọn nítorí tí wọn jẹ́ arákùnrin; ṣùgbọ́n kí wọn túbọ̀ máa sìn wọ́n, nítorí àwọn tí í ṣe alábápín iṣẹ́ rere wọn jẹ́ onígbàgbọ́ àti olùfẹ́.

Ìfẹ́ owó

Nǹkan wọ̀nyí ni kí ó máa kọ́ ni, kí o sì máa fi gbani níyànjú. 3Bí ẹnikẹ́ni bá ń kọ́ni ní ẹ̀kọ́ mìíràn, ti kò sì gba ọ̀rọ̀ ti ó yè kooro, ti Jesu Kristi Olúwa wa, àti ẹ̀kọ́ ti ó bá ìwà-bí-Ọlọ́run mu, 4Ó gbéraga, kò mọ̀ nǹkan kan, bí kò ṣe ìyànjú àti ìjà nípa ọ̀rọ̀ èyí tí ó ń mú ìlara, ìjà, ọ̀rọ̀ búburú wá, 5àti ọ̀rọ̀ àríyànjiyàn àwọn ènìyàn ọlọ́kàn èérí ti kò sí òtítọ́ nínú wọn, tiwọn ṣe bí ọ̀nà sí èrè ni ìwà-bí-Ọlọ́run; yẹra lọ́dọ̀ irú àwọn wọ̀nyí.

6Ṣùgbọ́n ìwà-bí-Ọlọ́run pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn èrè ńlá ni. 7Nítorí a kò mú ohun kan wá sí ayé, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì lè mu ohunkóhun jáde lọ. 8Bí a sì ni oúnjẹ àti aṣọ, ìwọ̀nyí yẹ́ kí ó tẹ́ wa lọ́rùn. 9Ṣùgbọ́n àwọn tí ń fẹ́ di ọlọ́rọ̀ a máa bọ́ sínú ìdánwò àti ìdẹ̀kùn, àti sínú òmùgọ̀ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ púpọ̀ tí í pa ni lára, irú èyí tí ó máa ń ri ènìyàn sínú ìparun àti ègbé. 10Nítorí ìfẹ́ owó ni gbòǹgbò ohun búburú gbogbo; èyí tí àwọn mìíràn ń lépa tí a sì mú wọn ṣìnà kúrò nínú ìgbàgbọ́, wọ́n sì fi ọ̀pọ̀ ìbànújẹ́ gún ara wọn lọ́kọ̀.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú fún Timotiu

11Ṣùgbọ́n ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, sá fún nǹkan wọ̀nyí; kí ó sì máa lépa òdodo, ìwà-bí-Ọlọ́run, ìgbàgbọ́, ìfẹ́ sùúrù, ìwà tútù. 12Máa ja ìjà rere ti ìgbàgbọ́, di ìyè àìnípẹ̀kun mú nínú èyí tí a pè ọ sí, ti ìwọ sì ṣe ìjẹ́wọ́ rere níwájú ẹlẹ́rìí púpọ̀. 136.13: Jh 18.37.Mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, tí ń sọ ohun gbogbo di ààyè, àti níwájú Jesu Kristi, ẹni tí ó jẹ́rìí níwájú Pọntiu Pilatu, 14kí ìwọ pa àṣẹ wọ̀nyí mọ́ ní àìlábàwọ́n, ní àìlẹ́gàn, títí di ìfarahàn Olúwa wa Jesu Kristi. 15Èyí ti yóò fihàn ní ìgbà tirẹ̀, Ẹni tí í ṣe Olùbùkún àti Alágbára kan ṣoṣo náà, ọba àwọn ọba, àti Olúwa àwọn Olúwa. 16Ẹnìkan ṣoṣo tí ó jẹ àìkú, tí ń gbé inú ìmọ́lẹ̀ tí a kò lè súnmọ́, ẹni tí ènìyàn kan kò rí rí, tí a kò sì lè rí: ẹni tí ọlá àti agbára títí láé ń ṣe tirẹ̀. Àmín.

17Kìlọ̀ fún àwọn tí ó lọ́rọ̀ ní ayé ìsinsin yìí kí wọn ma ṣe gbéraga, bẹ́ẹ̀ ni kí wọn má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ àìdánilójú, bí kò ṣe lé Ọlọ́run alààyè, tí ń fi ohun gbogbo fún wa lọ́pọ̀lọ́pọ̀ láti lò; 18kí wọn máa ṣoore, kí wọn máa pọ̀ ní iṣẹ́ rere, kí wọn múra láti pín fún ni, kí wọn ni ẹ̀mí ìbá kẹ́dùn; 19kí wọn máa to ìṣúra ìpìlẹ̀ rere jọ fún ara wọn dé ìgbà tí ń bọ̀, kí wọn lè di ìyè tòótọ́ mú.

20Timotiu, máa ṣọ ohun tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ, yà kúrò nínú ọ̀rọ̀ asán àti ìjiyàn ohun tí a ń fi èké pè ni ìmọ̀; 21èyí tí àwọn ẹlòmíràn jẹ́wọ́ rẹ̀ tí wọ́n sì ṣìnà ìgbàgbọ́.

Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú rẹ.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

1 Тиметею 6:1-21

1Те, кто находится под игом рабства, пусть относятся со всем уважением к своим хозяевам, чтобы ни имя Аллаха, ни наше учение не были опорочены. 2Рабы, у которых хозяева из последователей Исы аль-Масиха, не должны оказывать им меньше уважения на том основании, что они братья. Наоборот, они должны служить им ещё лучше, потому что те, кому они служат, – верные и любимые братья. Этому ты должен учить людей и к этому их призывать.

Ложное учение и истинное богатство

3Кто учит чему-то другому и не согласен со здравыми наставлениями нашего Повелителя Исы аль-Масиха и с учением, соответствующим истинному почитанию Аллаха, 4тот заносчив, но не имеет знания. У него есть лишь нездоровое желание спорить и вести праздные дебаты, что лишь рождает зависть, распри, злоречие, недобрые подозрения 5и постоянные разногласия между людьми с развращённым умом, далёкими от истины: для них благочестие стало лишь способом наживы.

6Великое приобретение быть благочестивым и довольным. 7Ведь мы ничего не принесли с собой в этот мир и ничего не можем взять с собой из него. 8Мы должны быть довольны, если у нас есть пропитание и одежда. 9Те же, кто стремится разбогатеть, впадают в искушение и попадают в ловушку множества глупых и опасных желаний, которые погружают людей в пучину несчастья и гибели. 10Любовь к деньгам – это корень всех зол. Есть много людей, которых любовь к деньгам увела от веры и принесла им много страданий.

Наказ Тиметею

11Ты же, человек Всевышнего, беги от всего этого. Стремись к праведности, благочестию, вере, любви, терпению, кротости. 12Доблестно сражайся за веру, держись вечной жизни, к которой ты призван, ведь ты достойно и открыто говорил о своей вере перед многими свидетелями. 13Я требую от тебя перед Аллахом, дающим всему жизнь, и перед Исой аль-Масихом, Который достойно говорил о той же вере перед Понтием Пилатом: 14верно и безукоризненно исполняй то, что я тебе повелел, вплоть до возвращения нашего Повелителя Исы аль-Масиха. 15В своё время Его явит Аллах, благословенный и единый Властитель, Царь царей и Владыка владык6:15 См. Втор. 10:17; Заб. 135:3., 16единственный Бессмертный, обитающий в неприступном свете, Которого никто из людей не видел и не может видеть. Ему принадлежит честь и могущество навсегда! Аминь.

17Тех, кто в этой земной жизни богат, предупреждай, чтобы не гордились и не надеялись на своё богатство: оно ненадёжно. Пусть лучше надеются на Аллаха, щедро дающего всё необходимое, чтобы мы могли наслаждаться жизнью. 18Требуй от них делать добро и обогащаться добрыми делами, быть щедрыми и охотно делиться с другими своим богатством. 19Таким образом они соберут себе сокровища, которые станут добрым основанием их будущего, и получат подлинную жизнь.

20Тиметей, храни то, что тебе вверено. Не занимайся безбожным пустословием и спорами о том, что ложно называют знанием. 21Увлёкшись этим, некоторые ушли в сторону от веры.

Пусть благодать будет с вами.