1 Samuẹli 15 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 15:1-35

Olúwa kọ Saulu ní ọba

1Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́. 2Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti. 3Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’ ”

4Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ (200,000) àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) àwọn ọkùnrin Juda. 5Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan. 6Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.

7Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti. 8Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀. 9Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.

10Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé, 11“Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.

12Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”

13Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”

14Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”

15Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”

16Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.”

Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”

17Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli. 18Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’ 19Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”

20Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá. 21Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”

2215.22: Mk 12.33.Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé,

Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ

ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́?

Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ,

ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.

23Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ,

àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà.

Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa,

Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”

24Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́. 25Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”

26Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”

27Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya; 28Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ. 29Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”

30Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.” 31Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.

32Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.”

Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”

33Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé,

“Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ

bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.”

Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.

34Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu. 35Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.

Persian Contemporary Bible

اول سموئيل 15:1-35

خدا شائول را رد می‌كند

1روزی سموئيل به شائول گفت: «خداوند مرا فرستاد كه تو را مسح كنم تا بر قوم او، اسرائيل سلطنت كنی. پس الان به پيغام خداوندِ قادر متعال توجه كن. 2او می‌فرمايد: من مردم عماليق را مجازات خواهم كرد، زيرا وقتی قوم اسرائيل را از مصر بيرون می‌آوردم، آنها نگذاشتند از ميان سرزمينشان عبور كنند. 3حال برو و مردم عماليق را قتل عام كن. بر آنها رحم نكن، بلكه زن و مرد و طفل شيرخواره، گاو و گوسفند، شتر و الاغ، همه را نابود كن.»

4پس شائول لشكر خود را كه شامل دويست هزار سرباز از اسرائيل و ده هزار سرباز از يهودا بود در تلايم سان ديد. 5بعد شائول با لشكر خود به طرف شهر عماليقی‌ها حركت كرد و در دره‌ای كمين نمود. 6او برای قينی‌ها اين پيغام را فرستاد: «از ميان عماليقی‌ها خارج شويد و گرنه شما نيز با آنها هلاک خواهيد شد. شما نسبت به قوم اسرائيل، هنگامی كه از مصر بيرون آمدند، مهربان بوديد و ما نمی‌خواهيم به شما آزاری برسد.» پس قينی‌ها آنجا را ترک گفتند.

7آنگاه شائول، عماليقی‌ها را شكست داده، آنها را از حويله تا شور كه در سمت شرقی مصر است، تار و مار كرد. 8او اجاج پادشاه عماليق را زنده دستگير كرد، ولی تمام قومش را از دم شمشير گذراند.

9اما شائول و سپاهيانش برخلاف دستور خداوند، اجاج پادشاه و بهترين گاوها و گوسفندها و چاقترين بره‌ها را زنده نگاه داشتند. آنها هر چه را كه ارزش داشت نابود نكردند، ولی هر چه را كه بی‌ارزش بود از بين بردند.

10‏-11به همين سبب خداوند به سموئيل فرمود: «متأسفم كه شائول را به پادشاهی برگزيدم، چون از من برگشته و از فرمان من سرپيچی نموده است.» سموئيل چون اين را شنيد بسيار متأثر شد و تمام شب در حضور خدا ناله كرد.

12سموئيل صبح زود برخاست و روانه شد تا شائول را پيدا كند. به او گفتند كه شائول به كوه كرمل رفت و در آنجا ستونی به يادبود خود بر پا نمود و از آنجا هم به جلجال رفته است.

13وقتی سموئيل شائول را پيدا كرد، شائول پس از سلام و احوالپرسی به او گفت: «دستور خداوند را انجام دادم.»

14سموئيل پرسيد: «پس اين بع‌بع گوسفندان و صدای گاوان كه می‌شنوم چيست؟»

15شائول جواب داد: «افراد من، گوسفندها و گاوهای خوب و چاق را كه از عماليقی‌ها گرفته‌اند، زنده نگاه داشته‌اند تا آنها را برای خداوند، خدايت قربانی كنند؛ آنها بقيه را از بين برده‌اند.»

16سموئيل به شائول گفت: «گوش كن تا آنچه را كه خداوند ديشب به من گفت به تو بگويم.»

شائول پرسيد: «خداوند چه گفته است؟»

17سموئيل جواب داد: «وقتی كه تو شخص گمنام و كوچكی بودی، خداوند تو را به پادشاهی اسرائيل برگزيد. 18او تو را فرستاد تا عماليقی‌های گناهكار را ريشه‌كن كنی. 19پس چرا كلام خداوند را اطاعت نكردی و حيوانات آنها را به غنيمت گرفته، مخالف خواست خداوند انجام دادی؟»

20شائول پاسخ داد: «من از خداوند اطاعت كردم و هر آنچه كه به من گفته بود، انجام دادم؛ اجاج، پادشاه عماليقی‌ها را آوردم ولی بقيه را هلاک كردم. 21اما سپاهيان بهترين گوسفندان و گاوان را گرفته، با خود آوردند تا در جلجال برای خداوند، خدايت قربانی كنند.»

22سموئيل در جواب گفت: «آيا خداوند به قربانیها خشنود است يا به اطاعت از كلامش؟ اطاعت بهتر از قربانی است. اگر او را اطاعت می‌كردی، خشنودتر می‌شد تا اينكه برايش گوسفندهای فربه قربانی كنی. 23نااطاعتی مثل گناه جادوگری است و خودسری مانند بت‌پرستی می‌باشد. چون به كلام خداوند توجه نكردی، او هم تو را از مقام پادشاهی بركنار خواهد كرد.»

24سرانجام شائول اعتراف نموده، گفت: «گناه كرده‌ام! از دستور خداوند و از سخن تو سرپيچی نموده‌ام، چون از مردم ترسيدم و تسليم خواست ايشان شدم. 25التماس می‌كنم مرا ببخش و با من بيا تا بروم و خداوند را عبادت كنم.»

26اما سموئيل پاسخ داد: «من با تو نمی‌آيم. چون تو از فرمان خداوند سرپيچی كردی، خداوند نيز تو را از پادشاهی اسرائيل بركنار كرده است.»

27همين كه سموئيل برگشت كه برود، شائول ردای او را گرفت تا او را نگه دارد، پس ردای سموئيل پاره شد. 28سموئيل به او گفت: «امروز خداوند سلطنت اسرائيل را از تو گرفته و همین‌گونه پاره كرده و آن را به كسی كه از تو بهتر است، داده است. 29خدا كه جلال اسرائيل است، دروغ نمی‌گويد و قصدش را عوض نمی‌كند، چون او انسان نيست كه فكرش را تغيير دهد.»

30شائول بار ديگر التماس نموده، گفت: «درست است كه من گناه كرده‌ام، اما خواهش می‌كنم احترام مرا در حضور مشايخ و مردم اسرائيل نگه داری و با من بيايی تا بروم و خداوند، خدای تو را عبادت كنم.»

31سرانجام سموئيل قبول كرد و با او رفت و شائول خداوند را عبادت نمود.

32سموئيل دستور داد اجاج، پادشاه عماليق را نزد او ببرند. اجاج با خوشحالی نزد او آمد، چون فكر می‌كرد خطر مرگ گذشته است. 33اما سموئيل گفت: «چنانكه شمشير تو زنان زيادی را بی‌اولاد گردانيد، همچنان مادر تو بی‌اولاد خواهد شد.» سپس او را در حضور خداوند، در جلجال قطعه‌قطعه كرد. 34بعد سموئيل به رامه رفت و شائول به خانه‌اش در جبعه بازگشت. 35پس از آن سموئيل ديگر شائول را نديد، اما هميشه برايش عزادار بود، و خداوند متأسف بود از اينكه شائول را پادشاه اسرائيل ساخته بود.