1 Kronika 9 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 9:1-44

19.1,2: Es 2.70; Ne 7.73; 11.3.Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.

Àwọn ènìyàn tí ó wà ní Jerusalẹmu

2Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.

39.3-17: Ne 11.4-19.Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:

4Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.

5Àti nínú ará Ṣilo:

Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.

6Ní ti ará Sera:

Jeueli.

Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá (690).

7Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni:

Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;

8Ibinaiah ọmọ Jerohamu;

Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri;

àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.

9Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì (956). Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.

10Ní ti àwọn àlùfáà:

Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;

11Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;

12Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah;

àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.

13Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì (1,760). Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.

14Ní ti àwọn ará Lefi:

Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;

15Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;

16Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni;

àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.

17Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà:

Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn, 18ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.

19Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.

20Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.

21Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.

22Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá (212). A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn.

Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn. 23Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́. 24Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù. 25Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje. 26Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run. 27Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.

28Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde. 29Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn. 30Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀. 31Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín. 32Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.

33Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.

34Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.

Ìdílé àti Ìrandíran Saulu

35Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni.

Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka, 36pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu. 37Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti. 38Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.

39Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.

40Ọmọ Jonatani:

Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.

41Àwọn ọmọ Mika:

Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.

42Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa. 43Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.

44Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn:

Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

1 Летопись 9:1-44

1Весь Исроил был внесён в родословия, записанные в «Книге царей Исроила».

Жители Иерусалима после Вавилонского пленения

(Неем. 11:3-19)

Народ Иудеи был уведён в плен в Вавилон за свою неверность. 2Первыми, кто вернулся к своим владениям в своих городах, были простые исроильтяне, священнослужители, левиты и служители при храме.

3Вот те из родов Иуды, Вениамина, Ефраима и Манассы, кто жил в Иерусалиме:

4Утай, сын Аммихуда, сына Омри, сына Имри, сына Бани, потомка Фареца, сына Иуды.

5Из шилонитян:

первенец Асая и его сыновья.

6Из потомков Зераха:

Иеуил.

От Иуды было шестьсот девяносто человек.

7Из потомков Вениамина:

Саллу, сын Мешуллама, внук Годавии, правнук Ассенуа; 8Ивнея, сын Иерохама; Ела, сын Уззия, внук Михри; и Мешуллам, сын Шефатии, внук Рагуила, правнук Ивнии.

9От Вениамина, по их родословиям, было девятьсот пятьдесят шесть человек. Все эти люди были главами своих семейств.

10Из священнослужителей:

Иедая, Иехоярив, Иахин 11и Азария, сын Хилкии, сына Мешуллама, сына Цадока, сына Мерайота, сына Ахитува, главы дома Всевышнего; 12Адая, сын Иерохама, сына Пашхура, сына Малхии; Маасай, сын Адиила, сына Иахзера, сына Мешуллама, сына Мешиллемита, сына Иммера.

13Священнослужителей, которые были главами своих семейств, было тысяча семьсот шестьдесят человек. Они были искусны в деле служения в доме Всевышнего.

14Из левитов:

Шемая, сын Хашува, сына Азрикама, сына Хашавии, потомка Мерари; 15Бакбаккар, Хереш, Галал и Маттания, сын Михи, сына Зихри, сына Ософа; 16Авдий, сын Шемаи, сына Галала, сына Иедутуна, и Берехия, сын Осо, сына Элканы, который жил в селениях нетофитян.

17Привратниками были:

Шаллум, Аккув, Талмон, Ахиман и их родичи. Шаллум был их главой. 18До сих пор его род стоит на страже у Царских ворот, что с восточной стороны. Это привратники, которые были из левитов. 19Шаллуму, сыну Коре, внуку Авиасафа, правнуку Кораха, и привратникам из его родства (корахитам), которые несли службу вместе с ним, было доверено охранять пороги Шатра9:19 То есть храма; также в ст. 21 и 23., как их отцы охраняли вход в святилище Вечного. 20В прежние времена Пинхас, сын Элеазара, был начальником над привратниками, и Вечный был с ним. 21Закария, сын Мешелемии, был привратником у входа в Шатёр Встречи.

22Всего в привратники было избрано двести двенадцать человек. Они были внесены в родословия по своим поселениям. На ответственные места привратников поставили Довуд и провидец Самуил. 23Им самим и их потомкам было доверено охранять ворота дома Вечного (именуемого Шатром). 24Привратники стояли с четырёх сторон – на востоке, на западе, на севере и на юге. 25Их сородичи в поселениях должны были время от времени приходить, чтобы делить с ними обязанности в течение семи дней. 26Но четырём главным привратникам, которые были левитами, были доверены комнаты и сокровища дома Всевышнего. 27Они проводили ночь возле дома Всевышнего, потому что должны были охранять его и каждое утро отпирать двери.

28Некоторым из них были доверены вещи, которыми пользовались при храмовой службе. Левиты пересчитывали их, когда принимали их и когда выдавали. 29Другие были назначены заботиться об утвари и всех прочих вещах святилища, а также о лучшей муке и вине, масле, ароматах и благовониях. 30А некоторые из священнослужителей смешивали благовония. 31Левиту по имени Маттафия, первенцу корахита Шаллума, было доверено печь хлеб для приношений, 32а некоторым из их каафитских сородичей были вверены заботы о священном хлебе на каждую субботу.

33Музыканты, главы левитских семейств, жили в комнатах храма и были свободны от других обязанностей, потому что несли свою службу днём и ночью.

34Все они были главами левитских семейств, вождями по своим родословиям, и жили в Иерусалиме.

Родословие Шаула

(1 Лет. 8:29-38)

35Иеил, отец Гаваона, жил в Гаваоне. Его жену звали Мааха; 36а первенцем его был Авдон, после которого родились Цур, Киш, Баал, Нер, Надав, 37Гедор, Ахио, Закария и Миклот. 38Миклот был отцом Шимеама. Они тоже жили в Иерусалиме рядом со своими сородичами.

39Нер был отцом Киша; Киш – отцом Шаула; Шаул – отцом Ионафана, Малик-Шуа, Авинадава и Иш-Бошета.

40Сын Ионафана:

Мефи-Бошет, который был отцом Михи.

41Сыновья Михи:

Пифон, Малик, Тареа и Ахаз.

42Ахаз был отцом Иадды; Иадда – отцом Алемета, Азмавета и Зимри, а Зимри – отцом Моцы. 43Моца был отцом Бинеа, сыном которого был Рефая, сыном которого был Элеаса, сыном которого был Ацель.

44У Ацеля было шесть сыновей. Вот их имена:

Азрикам, Бохру, Исмоил, Шеария, Авдий и Ханан. Это сыновья Ацеля.