1 Kronika 29 – YCB & NRT

Yoruba Contemporary Bible

1 Kronika 29:1-30

Ẹ̀bùn fún kíkọ́ ilé Olúwa

1Nígbà náà, ọba Dafidi sọ fún gbogbo àpéjọ pé: “Ọmọ mi Solomoni, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, sì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run. 2Pẹ̀lú gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, idẹ fún ti idẹ, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ rẹ̀, òkúta lóríṣìíríṣìí, àwọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkúta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀. 3Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkára mi ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi. Jù gbogbo rẹ̀ lọ, èmi ti pèsè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí: 4Ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) tálẹ́ǹtì wúrà, ti wúrà ofiri àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin (7,000) tálẹ́ǹtì fàdákà dídára, fún bíbo àwọn ògiri ilé náà. 5Fún iṣẹ́ wúrà àti fàdákà náà, àti fún oríṣìí iṣẹ́ ti ó yẹ ní ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn tí ó ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Nísinsin yìí, ta ni ó ní ìfẹ́ sí yíya ará rẹ̀ sọ́tọ̀ lónìí sí Olúwa?”

6Nígbà náà àwọn aṣáájú àwọn ìdílé, àwọn ìjòyè àwọn ẹ̀yà Israẹli, àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀wàá àti alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí iṣẹ́ ọba ní ìfẹ́ sí i. 7Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún tálẹ́ǹtì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà, ẹgbẹ̀rin méjì-dínlógún tálẹ́ǹtì idẹ àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì irin. 8Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Ọlọ́run ní abẹ́ ìtọ́jú Jehieli ará Gerṣoni. 9Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dafidi ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.

Àdúrà Dafidi

10Dafidi yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé,

“Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa,

Ọlọ́run baba a wa Israẹli,

láé àti láéláé.

11Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìn

àti ọláńlá àti dídán,

nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ.

Tìrẹ Olúwa ni ìjọba;

a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.

12Ọlá àti ọ̀wọ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Rẹ;

ìwọ ni alákòóso gbogbo nǹkan.

Ní ọwọ́ rẹ ni ipá àti agbára wà láti gbéga àti

láti fi agbára fún ohun gbogbo.

13Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ,

a sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ̀ tí ó lógo.

14“Ṣùgbọ́n ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè ṣe ìrànlọ́wọ́ tinútinú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ti wá, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ. 15Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí. 16Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo púpọ̀ yìí tí àwa ti pèsè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀. 17Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsin yìí èmi ti rí i pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́. 18Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Abrahamu, Isaaki àti Israẹli pa ìfẹ́ yìí mọ́ nínú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtítọ́ sí ọ. 19Àti fún ọmọ mi Solomoni ní ìfọkànsìn tòótọ́ láti pa àṣẹ rẹ mọ́ àwọn ohun tí ó nílò àti òfin àti láti ṣe ohun gbogbo láti kọ́ ààfin bí ti ọba fún èyí tí mo ti pèsè.”

20Dafidi sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn pé, Nísinsin yìí, ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín. Gbogbo ènìyàn sì fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì tẹ orí wọn ba, wọ́n wólẹ̀ fún Olúwa àti ọba.

A yan Solomoni gẹ́gẹ́ bí ọba

21Ni ọjọ́ kejì, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì rú ẹbọ sísun sí i: ẹgbẹ̀rún kan akọ màlúù, ẹgbẹ̀rin kan àgbò, àti ẹgbẹ̀rin kan akọ ọ̀dọ́-àgùntàn. Lápapọ̀ pẹ̀lú ọrẹ mímu àti àwọn ẹbọ mìíràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún gbogbo Israẹli. 22Wọ́n jẹ wọ́n sì mu pẹ̀lú ayọ̀ kíkún ní iwájú Olúwa ní ọjọ́ náà.

Nígbà náà wọ́n yan Solomoni ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́ẹ̀kejì wọ́n fi ààmì òróró yàn án níwájú Olúwa láti ṣe olórí àti Sadoku láti ṣe àlùfáà. 2329.23: 1Ọb 2.12.Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò baba a rẹ̀ Dafidi. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Israẹli sì gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu. 24Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dafidi tẹrí ara wọn ba fún ọba Solomoni.

25Olúwa gbé Solomoni ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Israẹli, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọláńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú rẹ̀ tí ó jẹ lórí Israẹli.

Ikú Dafidi

26Dafidi ọmọ Jese jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. 27Ó jẹ ọba lórí Israẹli fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jẹ ọba ní Hebroni, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. 28Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

29Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dafidi, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Samuẹli aríran, ìwé ìrántí ti Natani wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gadi aríran, 30lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí rẹ̀, àti lórí Israẹli, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.

New Russian Translation

1-я книга Паралипоменон 29:1-30

Пожертвования на строительство храма

1Царь Давид сказал всему собранию: «Мой сын Соломон, единственный, кого избрал Бог, молод и неопытен. Работа велика, ведь этот храм не для человека, а для Господа Бога. 2Я всё приготовил для дома моего Бога, что только смог — золото, серебро, бронзу, железо и дерево, а кроме того, много оникса и камней в оправы, бирюзы29:2 Смысл этого слова в евр. тексте неясен., разноцветных камней, всех видов драгоценных камней и мрамора. 3Кроме того, из любви к моему Богу я отдаю собственное золото и серебро на дом моего Бога сверх всего того, что я заготовил для этого святого дома. Я отдаю: 43 000 талантов29:4 Около 100 т. золота из Офира и 7 000 талантов29:4 Около 235 т. очищенного серебра для покрытия стен зданий, 5для всех золотых и серебряных вещей и для всякой работы ремесленников. Кто еще готов сделать добровольные пожертвования, посвящая себя сегодня Господу?»

6Тогда главы семейств, вожди родов Израиля, тысячники и сотники, и сановники, надзирающие за царским добром, стали делать добровольные пожертвования. 7Они пожертвовали на работу по строительству Божьего дома 5 000 талантов29:7 Около 170 т. и 10 000 дариков29:7 Около 84 кг. золота, 10 000 талантов29:7 Около 340 т. серебра, 18 000 талантов29:7 Около 610 т. бронзы и 100 000 талантов29:7 Около 3 400 т. железа. 8Всякий, у кого были драгоценные камни, отдавал их в сокровищницу дома Господа в руки гершонита Иехиила. 9Народ радовался добровольному участию своих вождей, потому что они жертвовали Господу от всего сердца. Очень радовался и царь Давид.

Молитва Давида

10Давид благословил Господа перед всем собранием, говоря:

«Благословен будь, Господи,

Бог отца нашего Израиля,

во веки и веки!

11Твои, Господи, величие и мощь,

великолепие, победа и слава,

ведь в небесах и на земле — всё Твое.

Твое, Господи, царство.

Ты над всем вознесен как Глава.

12От Тебя богатство и слава,

Ты — властитель всего.

В руках Твоих — сила и власть

вознести и упрочить всё.

13И сейчас, Бог наш, мы благодарим Тебя

и хвалим Твое славное имя.

14Но кто я и кто мой народ, чтобы нам делать это добровольное пожертвование? Всё происходит от Тебя, и мы даем Тебе лишь то, что получили из Твоей руки. 15Мы странники и чужеземцы в Твоих глазах, какими были и наши предки. Наши дни на земле — как тень, и нет надежды. 16Господи, наш Боже, всё это изобилие, что мы приготовили для строительства дома для Твоего святого имени, мы получили из Твоей руки, оно целиком принадлежит Тебе. 17Я знаю, мой Бог, что Ты испытываешь сердца и Тебе угодно чистосердечие. Я от чистого сердца добровольно отдал всё это и теперь с радостью вижу, что и Твой народ, который находится здесь, добровольно жертвует Тебе. 18Господи, Бог наших отцов Авраама, Исаака и Израиля, сохрани это желание в сердцах Твоего народа навсегда и сбереги их сердца верными Тебе. 19Дай моему сыну Соломону от всего сердца соблюдать Твои повеления, предписания и установления и сделать всё, чтобы построить дом, для которого я всё это приготовил».

20Затем Давид сказал всему собранию: «Славьте Господа, вашего Бога!» И все они восхвалили Господа, Бога их отцов. Они низко поклонились и простерлись ниц перед Господом и перед царем.

Признание Соломона царем

21На следующий день народ принес жертвы Господу и вознес Ему всесожжения: тысячу быков, тысячу баранов и тысячу ягнят вместе с положенными жертвенными возлияниями и многими другими жертвами за весь Израиль. 22Люди ели и пили в тот день перед Господом с великой радостью.

Затем они признали Соломона, сына Давида, царем во второй раз, помазав его пред Господом в правители, а Цадока в священники. 23И Соломон сел на престол Господа как царь вместо своего отца Давида. Он преуспевал, и весь Израиль повиновался ему. 24Все вожди и могучие воины, а также все сыновья царя Давида признали над собой власть царя Соломона.

25Господь высоко вознес Соломона в глазах всего Израиля и даровал ему такое царское великолепие, какого не было прежде ни у кого из израильских царей.

Смерть Давида

(3 Цар. 2:10–12)

26Давид, сын Иессея, был царем всего Израиля. 27Он правил Израилем сорок лет: семь лет в Хевроне и тридцать три года в Иерусалиме. 28Он умер в глубокой старости, насытившись жизнью, богатством и славой. И царем вместо него стал его сын Соломон.

29Что же до событий правления царя Давида, от первых до последних, то они описаны провидцем Самуилом, пророком Нафаном и прозорливцем Гадом. 30Эти записи повествуют о деяниях Давида во время его царствования, о его власти и событиях, которые выпали на его долю, о том, что случилось с Израилем и всеми царствами земли.