1 Kronika 28 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 28:1-21

Àwọn èrò Dafidi lórí ilé Olúwa

1Dafidi pe gbogbo àwọn oníṣẹ́ ti Israẹli láti péjọ ní Jerusalẹmu. Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà, àwọn alákòóso ìpín nínú iṣẹ́ bí ọba, àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí bíbojútó gbogbo àwọn ẹrù àti ohun ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ààfin àwọn oníṣẹ́ ààfin, àwọn ọkùnrin alágbára àti gbogbo àwọn ògbójú jagunjagun lápapọ̀.

2Ọba Dafidi dìde dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀, o sì wí pé, “Fetísílẹ̀ sí mi, ẹ̀yin ará mi àti ẹ̀yin ènìyàn mi. Èmi ní o ni lọ́kàn mi láti kọ́ ilé gẹ́gẹ́ bí ibi ìsinmi fún àpótí ẹ̀rí tí Olúwa fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run wa, èmi sì gbèrò láti kọ́ ọ. 3Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀ sílẹ̀.’

4“Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Israẹli, títí láé. Ó yan Juda gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Juda, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Israẹli. 5Nínú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Solomoni láti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lórí Israẹli. 6Ó wí fún mi pé, Solomoni ọmọ rẹ ni ẹni tí yóò kọ́ ilé mi àti àwọn ààfin mi, nítorí tí èmi ti yàn án láti ṣe ọmọ mi èmi yóò sì jẹ́ baba a rẹ̀. 7Èmi yóò fi ìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀ títí láé tí kò bá kọ̀ láti gbé àṣẹ àti òfin mi jáde, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe é ní àsìkò yìí.

8“Bẹ́ẹ̀ ni, nísinsin yìí, èmi pàṣẹ fún ọ ní ojú gbogbo Israẹli àti ní ti ìpéjọpọ̀ tí Olúwa, àti ní etí ìgbọ́ Ọlọ́run wa. Ṣọ́ra kó o sì tẹ̀lé gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ kí ìwọ kí ó le jogún ilẹ̀ dáradára yìí, kí o sì mú un lọ síwájú gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ fún àwọn ìran ọmọ rẹ títí láé.

9“Àti ìwọ, ọmọ mi Solomoni, rántí Ọlọ́run baba à rẹ, kí o sì sìn ín pẹ̀lú tọkàntọkàn pẹ̀lú ìfọkànsí pẹ̀lú ọkàn tí ó pé, nítorí Olúwa ṣàwárí gbogbo ọkàn ó sì mọ gbogbo èrò. Tí ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i; ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ títí láé. 10Gbèrò báyìí nítorí tí Olúwa ti yàn ọ́ láti kọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ilé tí a yà sí mímọ́ fún Olúwa. Jẹ́ alágbára kí ó sì ṣe iṣẹ́ náà.”

11Nígbà náà ni Dafidi fi àpẹẹrẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ ti ìloro àti ti ilé Olúwa náà, kíkọ́ ọ rẹ̀, àti ti ibi ìṣúra rẹ̀, àti ti iyàrá òkè rẹ̀, àti ti ìyẹ̀wù rẹ̀ àti ti ibùjókòó àánú. 12Ó fún un ní àwọn ètò gbogbo èyí tí ẹ̀mí ti fi sí ọkàn rẹ̀ fún ti ààfin ilé Olúwa àti gbogbo yàrá tí ó yíká fún ìṣúra ilé Ọlọ́run àti fún ìṣúra fún ohun yíyà sọ́tọ̀. 13Ó fún un ní àwọn ìlànà fún ìpín ti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti fún gbogbo iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa àti fún gbogbo ohun èlò tí wọn ó lò nínú ìsìn rẹ̀. 14Ó yàn ìwọ̀n wúrà fún gbogbo ohun èlò wúrà tí a ó lò níbi oríṣìí ìsìn, àti ìwọ̀n fàdákà fún gbogbo ohun èlò fàdákà tí a ó lò fún oríṣìí ìsìn, 15ìwọ̀n wúrà fún ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn, fún ìwọ̀n fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn; àti ìwọ̀n fàdákà ìdúró fìtílà fàdákà àti àwọn fìtílà rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlò ti gbogbo ìdúró fìtílà. 16Ìwọ̀n ti wúrà fun tábìlì, tábìlì fún àkàrà tí a yà sọ́tọ̀; ìwọ̀n fàdákà fún àwọn tábìlì fàdákà; 17ìwọ̀n kìkì wúrà fún àwọn àmúga ìjẹun, àwọn ìbùwọ́n ọpọ́n àti àwọn ìkòkò ìpọnmi; ìwọ̀n wúrà fún gbogbo àwopọ̀kọ́ fàdákà; 18àti ìwọ̀n ìdá wúrà fún pẹpẹ tùràrí ó fún un ní ètò fún kẹ̀kẹ́, ìyẹn ni pé àwọn ìdúró kérúbù wúrà tí wọ́n tan iye wọn ká, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí Olúwa.

19“Gbogbo èyí,” ni Dafidi wí pé, “Èmi ní kíkọ sílẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa sórí mi, ó sì fún mí ní ìmọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ ètò yìí.”

20Dafidi tún sọ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára kí o sì gbóyà, kí o sì ṣe iṣẹ́ náà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí dààmú, nítorí Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run mi, wà pẹ̀lú rẹ. Òun kì yóò sì já ọ kule tàbí kọ ọ sílẹ̀ títí gbogbo iṣẹ́ fún ìsìn ní ti ilé Olúwa yóò fi parí. 21Ìpín àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ṣetán fún gbogbo iṣẹ́ ilé Olúwa. Gbogbo ọkùnrin tí ó ní ìfẹ́ sí i tí ó sì ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ náà. Àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn yóò gbọ́rọ̀ sí gbogbo àṣẹ rẹ.”

Slovo na cestu

1 Letopisu 28:1-21

1Shromáždil pak David všecka knížata Izraelská, knížata jednoho každého pokolení, a knížata houfů sloužících králi, i hejtmany a setníky, i úředníky nade vším statkem a jměním královým i synů jeho s komorníky, i se všemi vzácnými a udatnými lidmi, do Jeruzaléma. 2A povstav David král na nohy své, řekl: Slyšte mne, bratří moji a lide můj. Já jsem uložil v srdci svém vystavěti dům k odpočinutí truhle úmluvy Hospodinovy, a ku podnoži noh Boha našeho, a připravil jsem byl potřeby k stavení. 3Ale Bůh mi řekl: Nebudeš stavěti domu jménu mému, proto že jsi muž válkami zaměstknaný a krev jsi vyléval. 4Vyvolil pak Hospodin Bůh Izraelský mne ze vší čeledi otce mého, abych byl králem nad Izraelem na věky; nebo z Judy vybral vývodu a z domu Judova čeled otce mého, a z synů otce mého mne ráčil za krále ustanoviti nade vším Izraelem. 5Tolikéž ze všech synů mých, (nebo mnoho synů dal mi Hospodin), vybral Šalomouna syna mého, aby seděl na stolici království Hospodinova nad Izraelem, 6A řekl mi: Šalomoun syn tvůj, ten mi vzdělá dům můj a síně mé; nebo jsem jej sobě zvolil za syna, a já budu jemu za otce. 7I utvrdím království jeho až na věky, bude-li stálý v ostříhání přikázaní mých a soudů mých, jako i nynějšího času. 8Nyní tedy při přítomnosti všeho Izraele, shromáždění Hospodinova, an slyší Bůh náš, napomínám vás: Zachovávejte a dotazujte se na všecka přikázaní Hospodina Boha svého, abyste vládli zemí dobrou, a v dědictví její uvedli i syny své po sobě až na věky. 9Ty také, Šalomoune, synu můj, znej Boha otce svého, a služ jemu celým srdcem a myslí ochotnou. Nebo všecka srdce zpytuje Hospodin a všeliká mysli tanutí zná. Budeš-li ho hledati, nalezneš jej; pakli ho opustíš, zavrže tě na věky. 10A tak viziž, že tě Hospodin zvolil, abys vystavěl dům svatyně; posilniž se a dělej. 11Dal pak David Šalomounovi synu svému formu síňce i pokojů jejích, a sklepů i paláců a komor jejích vnitřních, i domu pro slitovnici, 12A formu všeho toho, což byl složil v mysli své o síních domu Hospodinova, i o všech komorách vůkol chrámu pro poklady domu Božího, i pro poklady věcí posvátných, 13I pro houfy kněží a Levítů, a pro všecko dílo služby domu Hospodinova, a pro všecko nádobí k přisluhování v domě Hospodinově. 14Dal též zlata v jisté váze na nádobí zlaté, na všelijaké nádobí k jedné každé službě, též stříbra na všecky nádoby stříbrné v jisté váze na všelijaké nádobí k jedné každé službě, 15Totiž váhu na svícny zlaté, a lampy jejich zlaté podlé váhy jednoho každého svícnu i lamp jeho, na svícny pak stříbrné podlé váhy svícnu každého a lamp jeho, jakž potřebí bylo každému svícnu. 16Zlata též váhu na stoly předložení na jeden každý stůl, i stříbra na stoly stříbrné, 17I na vidličky a na kotlíky, i na přikryvadla zlata ryzího, a na medenice zlaté váhu na jednu každou medenici, tolikéž na medenice stříbrné jistou váhu na jednu každou medenici. 18Také na oltář k kadění zlata ryzího váhu, zlata i k udělání vozů cherubínů, kteříž by roztaženými křídly zastírali truhlu úmluvy Hospodinovy. 19Všecko to skrze vypsání z ruky Hospodinovy mne došlo, kterýž mi to dal, abych vyrozuměl všemu dílu formy té. 20A tak řekl David Šalomounovi synu svému: Posilniž se a zmocni a dělej; neboj se, ani lekej. Nebo Hospodin Bůh, Bůh můj s tebou bude, nenecháť tebe samého, aniž tě opustí, až i dokonáno bude všecko dílo služby domu Hospodinova. 21Hle, i houfové kněží a Levítů ke všeliké službě domu Božího s tebou také budou při všelikém díle, jsouce všickni ochotní a prozřetelní v moudrosti při všeliké práci, knížata také i všecken lid ke všechněm slovům tvým.