1 Kronika 21 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 21:1-30

Dafidi ṣe ètò ìkànìyàn

1Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli. 2Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”

3Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”

4Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu. 5Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn (1,100,000) tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún (470,000) ọkùnrin tí ń kọ́ idà.

6Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un. 7Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.

8Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.

9Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé. 10“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’ ”

11Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ. 12Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”

13Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”

14Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin (70,000) ènìyàn. 15Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.

16Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.

17Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”

18Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi. 19Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.

20Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́. 21Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.

22Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”

23Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”

24Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”

25Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta (600) ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà. 26Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.

27Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀. 28Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀. 29Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà. 30Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.

Bibelen på hverdagsdansk

1. Krønikebog 21:1-30

Davids mønstring af hæren

2.Sam. 24,1-25

1Satan ønskede at bringe Israels folk i ulykke, så han gav David den tanke at foretage en optælling af Israels samlede hærstyrke.

2David sagde derfor til Joab og de øvrige officerer: „Rejs rundt blandt alle Israels stammer fra Dan i nord til Be’ersheba i syd og optæl alle de våbenføre mænd. Kom så tilbage og fortæl mig, hvor mange jeg råder over.”

3Men Joab svarede: „Gud give, at din hær må vokse til 100 gange af, hvad den er nu. Min herre og konge, er de ikke alle loyale over for dig? Hvorfor vil du begå denne synd? Hvorfor bringe ulykke over Israels folk?”

4Imidlertid sejrede kongens ord over Joabs protester, så Joab rejste landet rundt for at foretage optællingen. Da han vendte tilbage til Jerusalem, 5meddelte han David det samlede tal på landets våbenføre mænd: I hele Israel var der 1.100.000 mand, heraf 470.000 i Juda. 6Joab havde dog undladt at foretage optælling i Levis og Benjamins stammeområde, for han var meget ilde til mode over kongens befaling. 7Gud var også vred over optællingen. Derfor ville han straffe Israel.

8Da sagde David til Gud: „Jeg har begået en stor synd! Det var tåbeligt af mig at gøre sådan noget. Tilgiv mig!”

9Så sagde Herren til profeten Gad, som var i Davids tjeneste: 10„Gå hen og sig til David: Jeg, Herren, giver dig tre muligheder for straf, og du må selv vælge, hvilken en af dem det skal være.” 11Gad gik derefter hen til David og forelagde ham de tre muligheder: 12„Vælger du tre år med hungersnød? Eller tre måneder på flugt for dine fjender? Eller tre dage, hvor Herrens engel sender pest over hele Israels land? Sig mig, hvad jeg skal svare Herren, som har sendt mig!”

13„Det er et frygteligt valg,” sukkede David. „Men det er bedre at være prisgivet Herren, for hans nåde er stor. Lad mig ikke være prisgivet mennesker.”

14Da sendte Herren pest over hele Israel, og 70.000 mænd døde. 15Da dødsenglen skulle til at ramme Jerusalem, blev Herren bedrøvet over den store ulykke, der var ved at ske. „Stop!” sagde han til englen. „Nu kan det være nok!” Englen stod da ved jebusitten Ornans tærskeplads. 16Da David så Herrens engel stå stille i luften med sit sværd rettet mod Jerusalem, kastede han og hans ledere sig på knæ med ansigtet mod jorden. De var alle klædt i sæk og aske.

17„Det er mig, der har syndet ved at mønstre min hær,” sagde han. „Alle disse mennesker er som uskyldige får. Herre, min Gud, lad dog straffen ramme mig og min familie. Du må ikke tilintetgøre dit folk.”

18Derpå sagde Herrens engel til Gad: „Sig til David, at han skal bygge et alter for Herren på jebusitten Ornans tærskeplads.” 19-20David var lydig mod Herrens befaling og opsøgte Ornan, der var i færd med at tærske hvede. Da Ornan vendte sig om, fik han øje på englen, og hans fire sønner løb i skjul, mens han selv fortsatte med at tærske. 21Kort efter opdagede Ornan kongen, der nærmede sig. Straks forlod han tærskepladsen, løb kong David i møde og kastede sig på knæ med ansigtet mod jorden foran ham.

22David sagde til Ornan: „Lad mig købe tærskepladsen af dig til dens fulde pris, så jeg kan bygge Herren et alter og få pesten til at standse.”

23„Tag den bare, min herre og konge, og gør med den, hvad du vil,” svarede Ornan. „Her, jeg giver dig mine okser til brændofferet, tærskeslæderne til offerbrænde og brug min hvede til afgrødeofferet. Jeg giver dig det hele!”

24„Nej,” svarede kong David, „jeg vil betale dig den fulde pris. Jeg kan ikke tage, hvad der tilhører en anden, og ofre det til Herren. Jeg vil ikke bringe ofre, der ikke har kostet mig noget!”

25Så betalte David Ornan 600 guldstykker for hele området, 26hvorefter han byggede et alter for Herren og ofrede brændofre og takofre. Han bad Herren om nåde, og Herren svarede ved at sende ild fra himlen, som fortærede ofrene på alteret. 27Herren befalede derefter englen at stikke sværdet i skeden.

28David fortsatte nu med at ofre til Herren på jebusitten Ornans tærskeplads, fordi Herren dér havde svaret på hans bøn. 29Herrens telt og brændofferalteret, som Moses havde lavet i ørkenen, stod stadig på højen ved Gibeon. 30Men David turde ikke tage derhen for at søge Herren, for han var bange for Herrens engels sværd.