Ìgbàgbọ́ nínú ọmọ Ọlọ́run
15.1: Jh 8.42.Olúkúlùkù ẹni tí ó bá gbàgbọ́ pé Jesu ni Kristi, a bí i nípa ti Ọlọ́run: àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn. Ẹni tí ó bi nì, ó fẹ́ràn ẹni tí a bí nípasẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú. 2Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa fẹ́ràn àwọn ọmọ Ọlọ́run, nígbà tí a bá fẹ́ràn Ọlọ́run, tí a sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́. 35.3: Jh 14.15; 1Jh 2.5; 2Jh 6.Nítorí èyí ni ìfẹ́ Ọlọ́run, pé kí àwa pa òfin rẹ̀ mọ́: òfin rẹ̀ kò sì nira, 45.4: Jh 16.33.nítorí olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run, ó ṣẹ́gun ayé. Èyí sì ni ìṣẹ́gun tí ó ṣẹ́gun ayé, àní ìgbàgbọ́ wa. 5Ta ni ẹni tí ó ṣẹ́gun ayé, bí kò ṣe ẹni tí ó gbàgbọ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni Jesu jẹ́?
65.6-8: Jh 19.34; 4.23; 15.26.Èyí ni ẹni tí ó wá nípa omi àti ẹ̀jẹ̀, Jesu Kristi, kì í ṣe nípa omi nìkan, bí kò ṣe nípa omi àti ẹ̀jẹ̀. Àti pé Ẹ̀mí ni ó sì ń jẹ́rìí, nítorí pé òtítọ́ ni Ẹ̀mí. 7Nítorí pé àwọn mẹ́ta ni ó ń jẹ́rìí. 8Ẹ̀mí, omi, àti ẹ̀jẹ̀: àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì wà ni ìṣọ̀kan. 95.9: Jh 5.32,36; 8.18.Bí àwa ba ń gba ẹ̀rí ènìyàn, ẹ̀rí Ọlọ́run tóbi jù: nítorí ẹ̀rí Ọlọ́run ni èyí pé, Ó tí jẹ́rìí ní ti Ọmọ rẹ̀. 105.10: 1Jh 1.10.Ẹni tí ó bá gba Ọmọ Ọlọ́run gbọ́, ó ni ẹ̀rí nínú ara rẹ̀; ẹni tí kò bá gba Ọlọ́run gbọ́, ó ti mú un ni èké; nítorí kò gba ẹ̀rí náà gbọ́ tí Ọlọ́run jẹ́ ní ti Ọmọ rẹ̀. 11Ẹ̀rí náà sì ni èyí pé Ọlọ́run fún wa ní ìyè àìnípẹ̀kun, ìyè yìí sì ń bẹ nínú Ọmọ rẹ̀. 125.12: Jh 3.36.Ẹni tí ó bá ni Ọmọ, ó ni ìyè; ẹni tí kò bá sì ni Ọmọ Ọlọ́run, kò ní ìyè.
Àwọn àfiyèsí ìparí
135.13: Jh 20.31.Nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ̀wé rẹ̀ sí yín, àní sí ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́; kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé ẹ̀yin ní ìyè àìnípẹ̀kun, àní fún ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́. 145.14: Mt 7.7; 1Jh 3.21.Èyí sì ni ìgboyà tí àwa ní níwájú rẹ̀, pé bí àwa bá béèrè ohunkóhun gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, ó ń gbọ́ tí wa; 15Bí àwa bá sì mọ̀ pé ó ń gbọ́ tí wa, ohunkóhun tí àwa bá béèrè, àwa mọ̀ pé àwa rí ìbéèrè tí àwa ti béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ gbà.
16Bí ẹnikẹ́ni bá rí arákùnrin rẹ̀ tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú, òun yóò béèrè, Ọlọ́run yóò sì fún un ni ìyè, àní, fún àwọn tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú. Ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ sì ikú: èmi kò wí pé ki òun gbàdúrà fún èyí. 17Gbogbo àìṣòdodo ni ẹ̀ṣẹ̀: ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ tí kì í ṣe sí ikú.
185.18: Jh 17.15; 1Jh 3.9.Àwa mọ̀ pé ẹnikẹ́ni tí a bí nípa ti Ọlọ́run kì í dẹ́ṣẹ̀: ṣùgbọ́n ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run a pa ara rẹ̀ mọ́, ẹni búburú kò ní lè fọwọ́ kàn án. 19Àwa mọ̀ pé tí Ọlọ́run ni wá, àti gbogbo ayé ni ó wà lábẹ́ agbára ẹni búburú náà. 205.20-21: Jh 17.3; If 3.7.Àwa sì mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run dé, ó sì tí fi òye fún wa, kí àwa lè mọ ẹni tí í ṣe òtítọ́, àwa sì ń bẹ nínú ẹni tí í ṣe òtítọ́, àní, nínú Ọmọ rẹ̀, Jesu Kristi. Èyí ni Ọlọ́run òtítọ́, àti ìyè àìnípẹ̀kun.
21Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú òrìṣà.
Победа верующих над миром
1Кто верит в то, что Иса – обещанный Масих, тот рождён от Всевышнего, а кто любит Небесного Отца, тот любит и всех рождённых от Него. 2А то, что мы любим детей Всевышнего, узнаём из того, что любим Всевышнего и исполняем Его повеления. 3Любовь к Аллаху проявляется в исполнении Его повелений. Повеления Его необременительны, 4потому что тот, кто рождён от Всевышнего, побеждает мир, и эта победа одержана благодаря нашей с вами вере. 5Кто же побеждает мир, как не тот, кто верит, что Иса – (вечный) Сын Всевышнего?
Свидетельство о (вечном) Сыне Всевышнего
6Иса аль-Масих пришёл через воду и кровь5:6 Вода и кровь – возможные варианты истолкования: вода и кровь указывают 1) на обряд погружения в воду и смерть аль-Масиха; 2) только на смерть аль-Масиха (Ин. 19:34); 3) на Его физическое рождение.. Он пришёл не только через воду, но через воду и кровь. И свидетель этому – Дух, потому что Дух есть истина. 7Итак, есть три свидетеля: 8Дух, вода и кровь – и все они свидетельствуют об одном. 9Если мы верим свидетельству людей, то свидетельство Всевышнего намного сильнее, потому что это свидетельство Бога: Он засвидетельствовал о Своём (вечном) Сыне. 10Кто верит в Сына Всевышнего, у того это свидетельство в нём самом, а кто не верит Аллаху, тот представляет Всевышнего лжецом, потому что он не верит тому, что Всевышний говорит о Своём Сыне. 11Вот это свидетельство: Всевышний дал нам вечную жизнь, и жизнь эта – в Его Сыне. 12У кого есть Сын Всевышнего – у того есть жизнь, а у кого нет Сына – у того нет и жизни.
Молитва за грешников
13Я написал это вам, верящим в (вечного) Сына Всевышнего, чтобы вы знали, что у вас есть вечная жизнь. 14Мы приходим к Аллаху с полной уверенностью в том, что если просим Его о чём-либо в согласии с Его волей, то Он нас слышит. 15И если мы знаем, что Он слышит нас, о чём бы мы ни просили, то знаем, что имеем то, что просим у Него.
16Когда вы видите своего брата согрешающим, и если этот грех не ведёт к смерти, то молитесь об этом брате, и Аллах даст ему жизнь. Я говорю здесь о таких грехах, которые не ведут к смерти5:16 Грех к смерти – имеется в виду грех, который ведёт к физической смерти (см. Деян. 5:1-11; 1 Кор. 11:30), или непростительный грех, ведущий к вечной духовной смерти (см. Мк. 3:28-30; Евр. 6:4-6; 10:26).. Есть грех, последствием которого может быть только смерть, и я не говорю вам молиться о грешнике, виновном в таком грехе. 17Всякий неправедный поступок – грех, но не все грехи влекут за собой смерть.
Заключение
18Мы знаем, что всякий рождённый от Всевышнего не любит грешить. Рождённый от Всевышнего хранит себя5:18 Или: «Рождённый от Всевышнего (Иса аль-Масих) хранит его»; или: «Рождённого от Всевышнего (верующего) хранит Аллах»., и Иблис не прикасается к такому человеку. 19Мы знаем, что мы от Аллаха, а весь мир лежит во власти Иблиса5:19 Или: «зла».. 20Мы знаем и то, что (вечный) Сын Всевышнего пришёл и открыл нам разум, чтобы мы познали Того, Кто истинен. И мы живём в единении с Тем, Кто истинен, будучи в единении с Исой аль-Масихом, Сыном Всевышнего. Он – истинный Бог и вечная жизнь!
21Дети, храните себя от идолов.