1 Ọba 12 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Ọba 12:1-33

Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí Rehoboamu

112.1-19: 2Ki 10.1-19.Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba. 2Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti. 3Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé, 4“Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”

5Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.

6Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”

7Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”

8Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín. 9Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”

10Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ. 11Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”

12Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.” 13Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, 14Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.” 15Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.

16Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé,

“Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi,

ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese?

Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli!

Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!”

Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn. 17Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.

18Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu. 19Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.

20Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.

21Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án (180,000) ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.

2212.22-24: 2Ki 11.1-4.Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé, 23“Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé, 24‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.” ’ ” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.

Ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani

25Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.

26Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi. 27Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”

28Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.” 29Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani. 30Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.

31Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi. 32Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli. 33Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

3 Царств 12:1-33

Мятеж исраильтян против Реховоама

(2 Лет. 10:1-19)

1Реховоам пошёл в Шехем, потому что там собрались все исраильтяне, чтобы сделать его царём. 2Когда об этом услышал Иеровоам, сын Невата (а он всё ещё оставался в Египте, куда бежал от царя Сулеймана), он возвратился из Египта12:2 Или: «был в Египте».. 3За Иеровоамом послали, и вместе со всеми исраильтянами он пришёл к Реховоаму. Они сказали Реховоаму:

4– Твой отец придавил нас тяжкой ношей, но теперь ты облегчи нам непосильный труд и тяжкую ношу, которую он на нас взвалил, и мы будем тебе служить.

5Реховоам ответил:

– Ступайте, а через три дня придите ко мне снова.

И народ ушёл. 6А царь Реховоам стал советоваться со старейшинами, которые служили его отцу Сулейману, пока тот был жив.

– Как вы посоветуете мне ответить этому народу? – спросил он.

7Они ответили:

– Если сегодня ты станешь слугой этому народу, послужишь им и дашь им добрый ответ, они всегда будут твоими рабами.

8Но Реховоам отверг совет, который дали ему старейшины, и стал советоваться с молодыми людьми, со своими сверстниками, которые выросли вместе с ним и служили ему. 9Он спросил их:

– Каков будет ваш совет? Как нам ответить этому народу, который говорит мне: «Облегчи ношу, которую взвалил на нас твой отец»?

10Молодые люди, которые выросли вместе с ним, ответили:

– Этому народу, который говорил тебе: «Твой отец придавил нас тяжкой ношей, но ты облегчи нам её», скажи: «Мой мизинец толще, чем бёдра моего отца. 11Мой отец взвалил на вас тяжкую ношу, а я сделаю её ещё тяжелее. Мой отец наказывал вас плетьми, а я буду наказывать вас шипованным бичом»12:11 Букв.: «скорпионами»; также в ст. 14..

12Три дня спустя Иеровоам и весь народ вернулись к Реховоаму, как царь и велел им, сказав: «Придите ко мне снова через три дня». 13Царь ответил народу сурово. Отвергнув совет, который дали ему старейшины, 14он последовал совету молодых людей и сказал:

– Мой отец придавил вас тяжкой ношей, а я сделаю её ещё тяжелее. Мой отец наказывал вас плетьми, а я буду наказывать шипованным бичом.

15Так царь не послушал народа, потому что это было по воле Вечного, чтобы исполнилось слово, которое Он сказал Иеровоаму, сыну Невата, через Ахию из Шило. 16Исраильтяне увидели, что царь отказывается их слушать, и ответили царю:

– Что общего у нас с Давудом,

что дал нам сын Есея?

По шатрам своим, Исраил!

Пусть дом Давуда правит своим собственным родом!

И исраильтяне разошлись по домам. 17Только теми, кто жил в городах Иудеи, по-прежнему правил Реховоам.

18Царь Реховоам послал Адонирама, надсмотрщика за подневольными рабочими, но исраильтяне забили его камнями до смерти. Однако царю Реховоаму удалось вскочить в колесницу и спастись в Иерусалиме. 19С тех пор и до сегодняшнего дня Исраил не подчиняется дому Давуда.

Воцарение Иеровоама I, первого исраильского царя

(2 Лет. 11:1-4)

20Когда исраильтяне услышали, что Иеровоам возвратился, они послали за ним, позвали его в собрание и сделали царём всего Исраила. Лишь род Иуды сохранил верность дому Давуда.

21Когда Реховоам прибыл в Иерусалим, он собрал весь род Иуды и род Вениамина – сто восемьдесят тысяч лучших воинов, – чтобы воевать с Исраилом и вернуть себе царство. 22Но пророку Шемае было от Аллаха такое слово:

23– Скажи Реховоаму, сыну Сулеймана, царю Иудеи, всему народу Иуды и Вениамина и остальному народу: 24Так говорит Вечный: «Не ходите воевать со своими братьями исраильтянами. Ступайте по домам, потому что это произошло по Моей воле».

Они послушались слова Вечного и, по Его слову, вернулись домой.

Идолопоклонство Иеровоама

25Иеровоам укрепил Шехем в нагорьях Ефраима и жил там. Выйдя оттуда, он отстроил Пениил.

26Иеровоам думал: «Царство может вернуться к дому Давуда. 27Если народ будет ходить приносить жертвы в храм Вечного в Иерусалим, то сердца их обратятся к господину своему, Реховоаму, царю Иудеи. Они убьют меня и вернутся к царю Реховоаму». 28И, посоветовавшись, царь сделал двух золотых тельцов и сказал народу:

– Хватит вам ходить в Иерусалим. Вот твои боги, Исраил, которые вывели тебя из Египта.

29Одного он поставил в городе Вефиле на юге, а другого в городе Дане на севере. 30Это привело к греху, потому что народ стал ходить к одному из них даже до самого Дана.

31Иеровоам построил капища на возвышенностях и поставил священнослужителей из народа, которые не были левитами. 32Он установил праздник, соответствующий празднику Шалашей, что справляли в Иудее12:32 Иеровоам постановил отмечать праздник Шалашей, который справляли в пятнадцатый день седьмого месяца (см. сноску на 8:2), ровно на один месяц позже., на пятнадцатый день восьмого месяца (в середине осени) и приносил жертвы на жертвеннике в Вефиле – жертвы тельцам, которых он сделал. Там же он назначил жрецов для капищ на возвышенностях, которые он сделал.

Пророк из Иудеи

33В пятнадцатый день восьмого месяца – месяца, который Иеровоам выбрал самовольно, установив праздник для исраильтян, он подошёл к жертвеннику, построенному им в Вефиле, чтобы возжечь благовония.