Mikaiah sọtẹ́lẹ̀ nípa Ahabu
122.1-35: 2Ki 18.1-34.Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli. 2Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli. 3Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
4Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?”
Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.” 5Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
6Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irínwó (400) ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?”
Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
7Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
8Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.”
Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
9Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
10Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn. 11Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’ ”
12Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
13Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
14Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
15Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?”
Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
16Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
17Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’ ”
18Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
19Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa: Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀. 20Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’
“Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn. 21Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
22“Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’
“Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’
“Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
23“Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
24Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
25Mikaiah sì wí pé, “Ìwọ yóò rí i ní ọjọ́ náà, nígbà tí ìwọ yóò lọ láti inú ìyẹ̀wù dé ìyẹ̀wù láti fi ara rẹ pamọ́.”
26Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba 27kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’ ”
28Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
A pa Ahabu ní Ramoti Gileadi
29Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi. 30Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
31Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.” 32Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè, 33àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
34Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.” 35Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́. 36A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
37Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria. 38Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
39Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli? 40Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Jehoṣafati ọba Juda
41Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli. 42Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùn-dínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi. 43Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀. 44Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
45Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? 46Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà. 47Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
4822.48,49: 2Ki 20.35-37.Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ: nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi. 49Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
5022.50: 2Ki 21.1.Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Ahasiah ọba Israẹli
51Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtà-dínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli. 52Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀. 53Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Пророчество Михея против Ахава
(2 Пар. 18:1–27)
1Три года между Арамом и Израилем не было войны. 2Но на третий год Иосафат, царь Иудеи, отправился к царю Израиля. 3Царь Израиля сказал своим приближенным:
— Разве вы не знаете, что Рамот Галаадский принадлежит нам, а мы и не пытаемся забрать его у царя Арама?
4Он спросил Иосафата:
— Пойдешь ли ты со мной воевать за Рамот Галаадский?
Иосафат ответил царю Израиля:
— Как ты, так и я, мой народ — твой народ, мои кони — твои кони.
5Но еще Иосафат сказал царю Израиля:
— Спроси сперва совета у Господа.
6Царь Израиля собрал пророков — около четырехсот человек — и спросил их:
— Идти ли мне войной на Рамот Галаадский или нет?
— Иди, — ответили они. — Владыка отдаст его в руки царя.
7Но Иосафат спросил:
— Разве нет здесь еще пророка Господа, которого мы могли бы спросить?
8Царь Израиля ответил Иосафату:
— Есть еще один человек, через которого мы можем вопросить Господа, но я ненавижу его, потому что он никогда не пророчествует обо мне ничего доброго, а только плохое. Это Михей, сын Имлы.
— Царю не следует так говорить, — сказал Иосафат.
9Тогда царь Израиля позвал одного из военачальников и сказал:
— Немедленно приведи Михея, сына Имлы!
10Облаченные в царские одеяния царь Израиля и Иосафат, царь Иудеи, сидели на своих тронах на гумне у ворот Самарии, а все пророки пророчествовали перед ними. 11Так Цедекия, сын Хенааны, сделал себе железные рога и сказал:
— Так говорит Господь: «Ими ты будешь бодать арамеев, пока они не будут истреблены».
12Все остальные пророки пророчествовали о том же, говоря:
— Иди на Рамот Галаадский и будь победителем; Господь отдаст его в руки царя.
13Посланник, который ходил, чтобы позвать Михея, сказал ему:
— Слушай, все остальные пророки, как один, предсказывают царю успех. Пусть твое слово будет согласно с их словами, и говори благоприятно.
14Но Михей сказал:
— Верно, как и то, что жив Господь, я скажу ему лишь то, что скажет мне Господь.
15Когда он пришел, царь спросил его:
— Михей! Идти ли нам воевать с Рамотом Галаадским или нет?
— Иди конечно и будь победителем, — ответил он. — Господь обязательно отдаст его в руки царя.
16Но царь сказал ему:
— Сколько раз мне заставить тебя поклясться, чтобы ты не говорил мне ничего, кроме истины во имя Господа?
17Тогда Михей ответил:
— Я видел весь Израиль рассеянным по горам, как овцы без пастуха, и Господь сказал: «У них нет господина. Пусть каждый возвращается с миром домой».
18Царь Израиля сказал Иосафату:
— Разве я не говорил тебе, что он никогда не пророчествует обо мне ничего хорошего, одно лишь плохое?
19Михей сказал:
— Итак, выслушай слово Господа. Я видел Господа сидящим на Своем престоле, со всем небесным воинством, стоявшим справа и слева от Него. 20Господь сказал: «Кто выманит Ахава, чтобы он пошел и пал при Рамоте Галаадском?».
Один предлагал одно, другой другое, 21пока, наконец, не вышел некий дух и встал перед Господом и сказал: «Я его выманю». — «Как?» — спросил Господь. 22«Я пойду и стану лживым духом в устах всех его пророков», — сказал он. «Да, ты преуспеешь в этом и выманишь его, — сказал Господь. — Иди и сделай так». 23И вот теперь Господь вложил в уста всех этих твоих пророков лживый дух, а тебе Господь определил беду.
24Тогда Цедекия, сын Хенааны, подошел и ударил Михея по щеке.
— Как это Дух Господа перешел от меня к тебе, чтобы говорить с тобой? — спросил он.
25Михей ответил:
— Ты узнаешь это в тот день, когда будешь прятаться во внутренней комнате.
26Тогда царь Израиля приказал:
— Возьмите Михея и отправьте его обратно к Амону, правителю города, и к Иоашу, сыну царя, 27и скажите: «Так говорит царь: Посадите этого человека в темницу и держите его впроголодь на хлебе и воде, пока я не вернусь благополучно».
28Михей сказал:
— Если ты благополучно вернешься, значит, Господь не говорил через меня.
И еще он сказал:
— Пусть все услышат это!
Гибель Ахава при Рамоте Галаадском
(2 Пар. 18:28–34)
29Царь Израиля пошел на Рамот Галаадский с Иосафатом, царем Иудеи. 30Царь Израиля сказал Иосафату:
— Я вступлю в сражение переодетым, но ты носи свои царские одежды. — Царь Израиля переоделся и вступил в сражение.
31А царь Арама приказал тридцати двум начальникам над своими колесницами:
— Не сражайтесь ни с кем, ни с малым, ни с великим, кроме царя Израиля.
32Когда начальники над колесницами увидели Иосафата, они подумали: «Конечно, это и есть царь Израиля».
И они повернули, чтобы напасть на него, но когда Иосафат закричал, 33начальники над колесницами увидели, что он не царь Израиля и перестали его преследовать.
34Но кто-то натянул лук и случайно ранил царя Израиля, так что стрела попала в щель между доспехами. Царь сказал своему колесничему:
— Разворачивайся и вывези меня из боя! Я ранен.
35Но битва кипела весь день, и царь вынужден был стоять в своей колеснице перед арамеями. Кровь из раны текла на пол колесницы, и вечером он умер. 36Когда садилось солнце, по войску прокатился клич:
— Пусть каждый человек возвращается в свой город, каждый — в свою землю!
37Царь умер и был привезен в Самарию, где его и похоронили. 38А колесницу вымыли в одном из прудов Самарии, где мылись блудницы,22:38 Или: в Самарии, и омыли его оружие. и псы лизали его кровь — по слову Господа, которое Он изрек22:38 См. 21:19..
39Что же до прочих событий правления Ахава и того, что он сделал, включая дворец, построенный им и выложенный слоновой костью, и города, которые он укрепил, то разве не записано об этом в «Книге летописей царей Израиля»? 40Ахав упокоился со своими предками. Охозия, его сын, стал царем вместо него.
Иосафат — царь Иудеи
(2 Пар. 20:31‒21:1)
41Иосафат, сын Асы, стал царем Иудеи на четвертом году правления Ахава, царя Израиля. 42Иосафату было тридцать пять лет, когда он стал царем, и правил он в Иерусалиме двадцать пять лет. Его мать звали Азува, дочь Шилхи. 43Он во всем ходил путями своего отца Асы и не уклонялся от них, делая то, что было правильным в глазах Господа. Но святилища на возвышенностях не были убраны, и народ продолжал приносить там жертвы и возжигать благовония. 44Еще Иосафат заключил мир с царем Израиля.
45Что же до прочих событий правления Иосафата, того, чего он достиг, и его воинских подвигов, то разве не записаны они в «Книге летописей царей Иудеи»? 46Остаток храмовых блудников, которые еще были в стране в дни его отца Асы, он искоренил. 47В Эдоме не было царя, правил наместник.
48Иосафат построил флотилию таршишских кораблей, чтобы плавать в Офир за золотом, но они так и не отплыли, потому что разбились в родном порту Эцион-Гевер. 49В то время Охозия, сын Ахава, сказал Иосафату:
— Пусть мои люди плавают вместе с твоими.
Но Иосафат не захотел.
50Иосафат упокоился со своими предками и был похоронен с ними в Городе Давида, своего предка. Иорам, его сын, стал царем вместо него.
Охозия — царь Израиля
51Охозия, сын Ахава, стал царем Израиля в Самарии на семнадцатом году правления Иосафата, царя Иудеи, и правил Израилем два года. 52Он делал зло в глазах Господа, потому что ходил путями отца и матери, и путями Иеровоама, сына Навата, который склонил Израиль к греху. 53Он служил Баалу, поклонялся ему и вызывал гнев Господа, Бога Израиля, как и его отец.