Òwe 6 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 6:1-35

Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀

1Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,

bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,

2bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,

tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.

3Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ

níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:

lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;

bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.

4Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,

tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.

5Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,

bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.

6Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ;

kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!

7Kò ní olùdarí,

kò sí alábojútó tàbí ọba,

8síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò

yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.

9Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?

Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?

10Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,

ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.

11Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà

àti àìní bí adigunjalè.

12Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,

tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,

13tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,

ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀

ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,

14tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀

ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.

15Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;

yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

16Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,

ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,

17Ojú ìgbéraga,

ahọ́n tó ń parọ́

ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,

18ọkàn tí ń pète ohun búburú,

ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,

19ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu

àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.

Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè

20Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́

má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.

22Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;

nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;

nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.

23Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,

ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,

àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí

ni ọ̀nà sí ìyè.

24Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,

kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.

25Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ

tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.

26Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,

ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.

27Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan

kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?

28Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?

Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?

29Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;

kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.

30Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè

nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.

31Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje

bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.

32Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;

ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.

33Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,

ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.

34Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,

kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.

35Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;

yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.

Persian Contemporary Bible

امثال 6:1-35

هشدارهای گوناگون

1ای پسرم، اگر ضامن كسی شده‌ای و تعهد كرده‌ای كه او قرضش را پس بدهد، 2و اگر با اين تعهد، خود را گرفتار ساخته‌ای، 3تو در واقع اسير او هستی و بايد هر چه زودتر خود را از اين دام رها سازی. پس فروتن شو و نزد او برو و از او خواهش كن تا تو را از قيد اين تعهد آزاد سازد. 4خواب به چشمانت راه نده و آرام ننشين، 5بلكه مانند آهويی كه از چنگ صياد می‌گريزد يا پرنده‌ای كه از دامی كه برايش نهاده‌اند می‌رهد، خود را نجات بده.

6ای آدمهای تنبل، زندگی مورچه‌ها را مشاهده كنيد و درس عبرت بگيريد. 7آنها ارباب و رهبر و رئيسی ندارند، 8ولی با اين همه در طول تابستان زحمت می‌كشند و برای زمستان آذوقه جمع می‌كنند. 9اما ای آدم تنبل، كار تو فقط خوابيدن است. پس كی می‌خواهی بيدار شوی؟ 10می‌گويی: «بگذار كمی بيشتر بخوابم! بگذار استراحت كنم.» 11اما بدان كه فقر و تنگدستی مانند راهزنی مسلح بر تو هجوم خواهد آورد.

12آدم رذل و بدطينت كه دائم دروغ می‌گويد، 13و برای فريب دادن مردم با ايما و اشاره حرف می‌زند، 14و در فكر پليد خود پيوسته نقشه‌های شرورانه می‌كشد و نزاع بر پا می‌كند، 15ناگهان دچار بلای علاج‌ناپذيری می‌گردد كه او را از پای در می‌آورند. 16‏-19هفت چيز است كه خداوند از آنها نفرت دارد:

نگاه متكبرانه،

زبان دروغگو،

دستهايی كه خون بی‌گناه را می‌ريزند،

فكری كه نقشه‌های پليد می‌كشد،

پاهايی كه برای بدی كردن می‌شتابند،

شاهدی كه دروغ می‌گويد،

شخصی كه در ميان دوستان تفرقه می‌اندازد.

هشدار در مورد زنا

20ای پسر من، اوامر پدر خود را به جا آور و تعاليم مادرت را فراموش نكن. 21سخنان ايشان را آويزه گوش خود نما و نصايح آنها را در دل خود جای بده. 22اندرزهای ايشان تو را در راهی كه می‌روی هدايت خواهند كرد و هنگامی كه در خواب هستی از تو مواظبت خواهند نمود و چون بيدار شوی با تو سخن خواهند گفت؛ 23زيرا تعاليم و تأديب‌های ايشان مانند چراغی پر نور راه زندگی تو را روشن می‌سازند. 24نصايح ايشان تو را از زنان بدكاره و سخنان فريبنده‌شان دور نگه می‌دارد.

25دلباخته زيبايی اين گونه زنان نشو. نگذار عشوه‌گری‌های آنها تو را وسوسه نمايد؛ 26زيرا زن فاحشه تو را محتاج نان می‌كند و زن بدكاره زندگی تو را تباه می‌سازد. 27آيا كسی می‌تواند آتش را در بر بگيرد و نسوزد؟ 28آيا می‌تواند روی زغالهای داغ راه برود و پاهايش سوخته نشود؟ 29همچنان است مردی كه با زن ديگری زنا كند. او نمی‌تواند از مجازات اين گناه فرار كند.

30اگر كسی به دليل گرسنگی دست به دزدی بزند مردم او را سرزنش نمی‌كنند، 31با اين حال وقتی به دام بيفتد بايد هفت برابر آنچه كه دزديده است جريمه بدهد، ولو اينكه اين كار به قيمت از دست دادن همهٔ اموالش تمام شود. 32اما كسی كه مرتكب زنا می‌شود احمق است، زيرا جان خود را تباه می‌كند. 33او را خواهند زد و رسوايی تا ابد گريبانگير او خواهد بود؛ 34زيرا آتش خشم و حسادت شوهر آن زن شعله‌ور می‌گردد و با بی‌رحمی انتقام می‌گيرد. 35او تاوانی قبول نخواهد كرد و هيچ هديه‌ای خشم او را فرو نخواهد نشاند.