Òwe 31 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 31:1-31

Àwọn ọ̀rọ̀ ọba Lemueli

1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,

2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!

Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.

3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,

okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli,

kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì,

kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,

5kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí,

kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.

6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé

wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.

7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn

kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn

fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.

9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè

jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

Ìkádìí: Aya oníwà rere

10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?

Ó níye lórí ju iyùn lọ.

11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀

kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀

Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;

ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.

15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;

ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀

àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.

16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;

nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.

17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára

apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.

18Ó rí i pé òwò òun pé

fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.

19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.

20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀

nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;

ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.

23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú

níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.

24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n

ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.

25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ

ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n

ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀

kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.

28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún

ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.

29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá

ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”

30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán

nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.

31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i

kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

La Bible du Semeur

Proverbes 31:1-31

Paroles du roi Lemouel

1Paroles du roi Lemouel31.1 Lemouel: roi inconnu. Paroles du roi Lemouel, maximes que sa mère… pourrait se traduire : Paroles de Lemouel, roi de Massa, que sa mère… Dans ce cas, Lemouel serait un roi ismaélite (voir 30.1 et note)., maximes que sa mère31.1 Tout ce chapitre souligne le rôle de la femme sage. La reine mère avait une grande influence dans les cours orientales (1 R 1.11-13 ; 15.13). lui a enseignées :

2Que te dirai-je, mon fils ?

Que te conseillerai-je, ô mon fils bien-aimé ?

Que te dirai-je, fils appelé de mes vœux ?

3Ne gaspille pas tes forces avec les femmes31.3 Allusion aux nombreuses femmes du harem royal qui pouvaient détourner le souverain de ses devoirs (voir 5.9-11 ; 1 R 11.1 ; Né 13.26).,

ne te laisse pas mener par celles qui perdent les rois.

4Il ne convient pas aux rois, Lemouel,

non, il ne convient pas aux rois de boire du vin,

ni à ceux qui gouvernent d’aimer les boissons enivrantes31.4 Pour les v. 4-5 et 8-9, voir Ps 72.1-4 ; Pr 16.10, 12 ; Ec 10.16-17.,

5car, en buvant, ils pourraient oublier les lois édictées

et rendre des jugements qui lèsent le droit des pauvres.

6Que l’on donne plutôt les boissons enivrantes à celui qui va périr,

et du vin à qui a le cœur amer.

7Qu’il boive et qu’il oublie sa misère,

qu’il ne se souvienne plus de son tourment !

8Ouvre la bouche pour défendre ceux qui ne peuvent parler,

pour défendre les droits de tous ceux qui sont délaissés.

9Oui, parle pour prononcer de justes verdicts.

Défends les droits des pauvres et des défavorisés !

Poème de la femme de valeur

10Qui se trouvera une femme de valeur ?

elle a bien plus de prix ╵que des coraux.

11Son mari a confiance en elle,

il ne manquera pas ╵de biens dans sa maison.

12Tous les jours de sa vie, ╵elle lui fait du bien,

et non du mal.

13Elle cherche avec soin ╵du lin et de la laine

et les travaille de ses mains ╵avec plaisir.

14Comme un vaisseau marchand,

elle apporte de loin ╵en son logis des vivres.

15Elle se lève ╵quand il fait nuit encore,

pourvoit en nourriture ╵sa maisonnée,

elle donne ses instructions ╵à ses servantes.

16Elle pense à un champ, ╵alors elle l’achète.

Du fruit de son travail, ╵elle plante une vigne.

17Avec plein d’énergie, ╵elle se met à l’œuvre

de ses bras affermis.

18Elle constate ╵que ses affaires marchent bien.

Jusque tard dans la nuit, ╵sa lampe est allumée.

19Ses mains filent la laine

et ses doigts tissent ╵des vêtements.

20Elle ouvre largement ╵la main à l’indigent

et tend les bras au pauvre.

21Pour elle et tous les siens, ╵peu importe la neige,

car toute sa famille ╵est revêtue ╵de doubles vêtements31.21 Selon certaines versions anciennes. Texte hébreu traditionnel : d’écarlate, autrement dit de vêtements luxueux..

22Elle se fait des couvertures,

elle a des vêtements ╵de fin lin et de pourpre31.22 Tissus de grand prix, marque de noblesse (7.16 ; Gn 41.42)..

23Son mari est connu ╵aux portes31.23 Lieu de réunion des dirigeants de la cité. de la ville.

Car il y siège ╵avec les responsables du pays.

24Elle confectionne elle-même ╵des habits et les vend,

ainsi que des ceintures ╵qu’elle cède aux marchands.

25La force et une grande dignité ╵lui servent de parure.

C’est avec le sourire ╵qu’elle envisage l’avenir.

26Ses paroles sont sages,

elle dispense avec bonté ╵l’enseignement.

27Elle veille à la bonne marche ╵de sa maison

et ne se nourrit pas ╵du pain de la paresse.

28Ses fils se lèvent, ╵la disent bienheureuse,

et son mari aussi ╵fait son éloge :

29« Il y a bien des filles ╵qui montrent leur valeur,

mais toi, tu les surpasses toutes. »

30Or le charme est trompeur ╵et la beauté fugace ;

la femme qui craint l’Eternel ╵est digne de louanges.

31Donnez-lui donc ╵le fruit de son travail !

Qu’on dise ses louanges ╵aux portes de la ville ╵pour tout ce qu’elle fait !