Òwe 3 – YCB & HTB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 3:1-35

Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn

1Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.

Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.

2Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,

ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

3Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,

kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.

43.4: Ro 12.17.Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere

ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

5Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ

má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.

6Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ

òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

73.7: Ro 12.16.Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ

bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.

8Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ

àti okun fún àwọn egungun rẹ.

9Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,

pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,

10nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya

àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

113.11,12: Hb 12.5,6.Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa

má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí

bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,

ẹni tí ó tún ní òye sí i,

14nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ

ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.

15Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;

kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.

16Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;

ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.

17Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,

òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.

18Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;

àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.

19Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;

20nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,

àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,

má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.

22Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,

àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.

23Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,

ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.

24Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,

nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.

25Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,

tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.

26Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,

kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.

27Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,

nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.

28Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,

“Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”

nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.

29Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,

ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.

30Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,

nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan

tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

32Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà

ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.

33Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.

343.34: (Gk): Jk 4.6; 1Pt 5.5.Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,

ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.

35Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,

ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.

Het Boek

Spreuken 3:1-35

1Mijn zoon, vergeet mijn onderricht niet, Neem mijn wenken ter harte. 2Ze schenken u lengte van dagen, jaren van leven, En overvloedige welvaart! 3Liefde en trouw mogen u nimmer verlaten, Hang ze om uw hals, schrijf ze op de tafel van uw hart; 4Dan zult ge goed en verstandig zijn, In de ogen van God en de mensen. 5Vertrouw op Jahweh met heel uw hart, Verlaat u niet op uw eigen inzicht; 6Denk aan Hem op al uw wegen, Dan zal Hij uw paden effenen. 7Wees niet wijs in uw eigen ogen, Heb ontzag voor Jahweh en vermijd het kwaad: 8Het zal genezing brengen voor uw lichaam, Verkwikking voor uw gebeente. 9Eer Jahweh met heel uw bezit, Met het beste van al uw inkomsten: 10Dan zullen uw schuren vol koren zijn, Uw kuipen bersten van most. 11Mijn zoon, sla de lessen van Jahweh niet in de wind, Heb geen afkeer van zijn bestraffing; 12Want Jahweh tuchtigt hem, dien Hij liefheeft, Kastijdt het kind, dat Hij mag. 13Gelukkig de mens, die wijsheid verkreeg, De man die inzicht bekwam; 14Want haar voordelen zijn groter dan die van zilver, Wat zij opbrengt is beter dan goud. 15Zij is meer waard dan juwelen; Geen van uw kostbaarheden komt haar nabij! 16Met de rechterhand schenkt ze lengte van dagen, Met de linker rijkdom en aanzien. 17Haar wegen zijn liefelijke wegen, Al haar paden leiden tot vrede; 18Zij is een boom des levens voor wie haar vatten, En wie haar vasthoudt, is zalig te prijzen! 19Met wijsheid heeft Jahweh de aarde gegrond, Met inzicht de hemel gewelfd; 20Naar zijn kennis rollen de zeeën aan, En druppelen de wolken van dauw. 21Mijn zoon, verlies ze dus niet uit het oog, Maar doe alles met beleid en verstand; 22Laat ze het leven zijn voor uw ziel, Een sieraad voor uw hals. 23Dan zult ge veilig uw weg bewandelen, En zult ge uw voeten niet stoten; 24Dan behoeft ge niet te vrezen, als ge u neerlegt, Kunt ge rustig sluimeren, als ge wilt slapen. 25Dan behoeft ge niet te vrezen, voor wat de dommen verschrikt, Of als het onweer komt, dat de bozen overvalt; 26Want Jahweh zal zijn op al uw wegen, Uw voet behoeden voor de strik. 27Weiger het goede niet, aan wien het toekomt, Zolang het in uw macht is, het te doen. 28Zeg niet tot uw naaste: “Ga heen en kom nog eens terug”; Of “Mórgen krijgt ge iets”, terwijl ge het nú hebt! 29Smeed geen kwaad tegen uw naaste, Terwijl hij, niets duchtend, bij u verblijft; 30Zoek geen twist met iemand om niets, Als hij u geen kwaad heeft gedaan. 31Wees niet jaloers op een tyran, Laat geen zijner wegen u gevallen; 32Want Jahweh heeft een afschuw van den zondaar, Maar met de rechtvaardigen gaat Hij vertrouwelijk om. 33De vloek van Jahweh rust op het huis van den boze, Zijn zegen op de woning der rechtvaardigen; 34Met spotters drijft Hij de spot, Maar aan de nederigen schenkt hij genade. 35Wijzen zullen achting verwerven, Dwazen schande verkrijgen!