Òwe 29 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 29:1-27

1Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí

yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀

nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.

3Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀

ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.

4Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,

ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.

5Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀

ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.

6Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀

ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.

7Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.

8Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,

ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.

9Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n

aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.

10Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin

wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.

11Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú

ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.

12Bí olórí bá fetí sí irọ́,

gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.

13Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí,

Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.

14Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́

ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.

15Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n

ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.

16Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀

ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.

17Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà

yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.

18Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà,

ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.

19A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́

bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.

20Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀?

Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.

21Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré

yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.

22Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè,

onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.

23Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀

ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.

24Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀,

ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.

25Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn

ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.

26Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso,

ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.

27Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́:

ènìyàn búburú kórìíra olódodo.

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 29:1-27

1ከብዙ ተግሣጽ በኋላ ዐንገቱን የሚያደነድን ሰው፣

በድንገት ይጠፋል፤ መዳኛም የለውም።

2ጻድቃን ሥልጣን ሲይዙ ሕዝብ ሐሤት ያደርጋል፤

ክፉዎች ሲገዙ ግን ሕዝብ ያቃስታል።

3ጥበብን የሚወድድ ሰው አባቱን ደስ ያሰኛል፤

የአመንዝራዎች ወዳጅ ግን ሀብቱን ያባክናል።

4ፍትሕን በማስፈን ንጉሥ አገርን ያረጋጋል፤

ጕቦ ለማግኘት የሚጐመጅ ግን ያፈራርሳታል።

5ባልንጀራውን የሚሸነግል፣

ለገዛ እግሩ መረብ ይዘረጋል።

6ክፉ ሰው በራሱ ኀጢአት ይጠመዳል፤

ጻድቅ ግን ይዘምራል፤ ደስም ይለዋል።

7ጻድቅ ለድኾች ፍትሕ ይጨነቃል፤

ክፉ ሰው ግን ደንታ የለውም።

8ተሳዳቢዎች ከተማን ያውካሉ፤

ጠቢባን ግን ቍጣን ያበርዳሉ።

9ጠቢብ ሰው ከተላላ ጋር ወደ ሸንጎ ቢሄድ፣

ተላላ ይቈጣል፤ ያፌዛል፤ ሰላምም አይኖርም።

10ደም የተጠሙ ሰዎች ሐቀኛን ሰው ይጠላሉ፤

ቅን የሆነውንም ለመግደል ይሻሉ።

11ተላላ ሰው ቍጣውን ያለ ገደብ ይለቅቀዋል፤

ጠቢብ ሰው ግን ራሱን ይቈጣጠራል።

12ገዥ የሐሰት ወሬ የሚሰማ ከሆነ፣

ሹማምቱ ሁሉ ክፉዎች ይሆናሉ።

13ድኻውና ጨቋኙ የጋራ ነገር አላቸው፤

እግዚአብሔር ለሁለቱም የዐይን ብርሃንን ሰጥቷቸዋል።

14ንጉሥ ለድኻ ትክክለኛ ፍርድ ቢሰጥ፣

ዙፋኑ ዘላለም ጸንቶ ይኖራል።

15የተግሣጽ በትር ጥበብን ታጐናጽፋለች፤

መረን የተለቀቀ ልጅ ግን እናቱን ያሳፍራል።

16ክፉዎች ሥልጣን ሲይዙ ኀጢአት ይበዛል፤

ጻድቃን ግን የእነርሱን ውድቀት ያያሉ።

17ልጅህን ቅጣው፤ ሰላም ይሰጥሃል፤

ነፍስህንም ደስ ያሰኛታል።

18ራእይ በሌለበት ሕዝብ መረን ይሆናል፤

ሕግን የሚጠብቅ ግን የተባረከ ነው።

19አገልጋይ በቃል ብቻ ሊታረም አይችልም፤

ቢያስተውለውም እንኳ በጀ አይልም።

20በችኰላ የሚናገርን ሰው ታያለህን?

ከእርሱ ይልቅ ተላላ ተስፋ አለው።

21ሰው አገልጋዩን ከልጅነቱ ጀምሮ ቢያቀማጥል፣

የኋላ ኋላ ሐዘን29፥21 በዕብራይስጡ የዚህ ቃል ትርጓሜ በርግጠኝነት አይታወቅም። ያገኘዋል።

22ቍጡ ሰው ጠብን ይጭራል፤

ግልፍተኛም ብዙ ኀጢአት ይሠራል።

23ሰውን ትዕቢቱ ያዋርደዋል፤

ትሑት መንፈስ ያለው ግን ክብርን ይጐናጸፋል።

24የሌባ ግብረ አበር የገዛ ራሱ ጠላት ነው፤

የመሐላውን ርግማን እየሰማ ጭጭ ይላል።

25ሰውን መፍራት ወጥመድ ነው፤

በእግዚአብሔር የሚታመን ግን በሰላም ይኖራል።

26ብዙዎች በገዥ ፊት ተደማጭነት ማግኘት ይሻሉ፤

ሰው ፍትሕ የሚያገኘው ግን ከእግዚአብሔር ዘንድ ነው።

27ጻድቃን አታላዮችን ይጸየፋሉ፤

ክፉዎችም ቅኖችን ይጠላሉ።