Òwe 21 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 21:1-31

1Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;

a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.

2Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀,

ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

3Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà

ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

4Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,

ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

5Ètè àwọn olóye jásí èrè

bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

6Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́

jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.

7Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,

nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

8Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀

ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

9Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé

ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.

10Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi

aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.

11Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,

òpè a máa kọ́gbọ́n,

nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.

12Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú

ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n

13Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,

òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;

ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:

àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,

dẹ́kun ìbínú líle.

15Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:

ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

16Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,

yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.

17Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:

ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.

18Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,

àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.

19Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú

oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.

20Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;

ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.

21Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,

òdodo, àti ọlá.

22Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,

ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.

23Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,

ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.

24Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,

àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.

25Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;

nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.

26Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:

ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.

27Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:

mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?

28Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:

ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.

29Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:

ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.

30Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,

tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.

31A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:

ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.

New International Version

Proverbs 21:1-31

1In the Lord’s hand the king’s heart is a stream of water

that he channels toward all who please him.

2A person may think their own ways are right,

but the Lord weighs the heart.

3To do what is right and just

is more acceptable to the Lord than sacrifice.

4Haughty eyes and a proud heart—

the unplowed field of the wicked—produce sin.

5The plans of the diligent lead to profit

as surely as haste leads to poverty.

6A fortune made by a lying tongue

is a fleeting vapor and a deadly snare.21:6 Some Hebrew manuscripts, Septuagint and Vulgate; most Hebrew manuscripts vapor for those who seek death

7The violence of the wicked will drag them away,

for they refuse to do what is right.

8The way of the guilty is devious,

but the conduct of the innocent is upright.

9Better to live on a corner of the roof

than share a house with a quarrelsome wife.

10The wicked crave evil;

their neighbors get no mercy from them.

11When a mocker is punished, the simple gain wisdom;

by paying attention to the wise they get knowledge.

12The Righteous One21:12 Or The righteous person takes note of the house of the wicked

and brings the wicked to ruin.

13Whoever shuts their ears to the cry of the poor

will also cry out and not be answered.

14A gift given in secret soothes anger,

and a bribe concealed in the cloak pacifies great wrath.

15When justice is done, it brings joy to the righteous

but terror to evildoers.

16Whoever strays from the path of prudence

comes to rest in the company of the dead.

17Whoever loves pleasure will become poor;

whoever loves wine and olive oil will never be rich.

18The wicked become a ransom for the righteous,

and the unfaithful for the upright.

19Better to live in a desert

than with a quarrelsome and nagging wife.

20The wise store up choice food and olive oil,

but fools gulp theirs down.

21Whoever pursues righteousness and love

finds life, prosperity21:21 Or righteousness and honor.

22One who is wise can go up against the city of the mighty

and pull down the stronghold in which they trust.

23Those who guard their mouths and their tongues

keep themselves from calamity.

24The proud and arrogant person—“Mocker” is his name—

behaves with insolent fury.

25The craving of a sluggard will be the death of him,

because his hands refuse to work.

26All day long he craves for more,

but the righteous give without sparing.

27The sacrifice of the wicked is detestable—

how much more so when brought with evil intent!

28A false witness will perish,

but a careful listener will testify successfully.

29The wicked put up a bold front,

but the upright give thought to their ways.

30There is no wisdom, no insight, no plan

that can succeed against the Lord.

31The horse is made ready for the day of battle,

but victory rests with the Lord.