Òwe 21 – YCB & LCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 21:1-31

1Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;

a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.

2Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀,

ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

3Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà

ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

4Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,

ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

5Ètè àwọn olóye jásí èrè

bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

6Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́

jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.

7Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,

nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

8Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀

ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

9Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé

ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.

10Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi

aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.

11Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,

òpè a máa kọ́gbọ́n,

nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.

12Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú

ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n

13Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,

òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;

ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:

àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,

dẹ́kun ìbínú líle.

15Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:

ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

16Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,

yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.

17Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:

ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.

18Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,

àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.

19Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú

oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.

20Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;

ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.

21Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,

òdodo, àti ọlá.

22Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,

ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.

23Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,

ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.

24Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,

àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.

25Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;

nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.

26Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:

ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.

27Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:

mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?

28Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:

ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.

29Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:

ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.

30Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,

tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.

31A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:

ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.

Luganda Contemporary Bible

Engero 21:1-31

1Omutima gwa kabaka guli ng’amazzi agakulukutira mu mukono gwa Mukama,

era agukyusiza gy’ayagala yonna.

2Buli kkubo lya muntu liba ng’ettuufu mu maaso ge,

naye Mukama apima omutima.

3Okukola ebituufu n’eby’amazima

kisanyusa Mukama okusinga ssaddaaka.

4Amaaso ageegulumiza, n’omutima ogw’amalala,

ye ttabaaza y’ababi, era ebyo kwonoona.

5Enteekateeka z’omunyiikivu zivaamu magoba meereere,

naye okwanguyiriza okutalina nteekateeka kuvaamu bwavu.

6Okufuna obugagga n’olulimi olulimba,

mpewo buwewo etwalibwa eruuyi n’eruuyi era mutego gwa kufa.

7Obukambwe bw’ababi bulibamalawo,

kubanga bagaana okukola eby’ensonga.

8Ekkubo ly’abazza emisango liba kyamu,

naye ery’abataliiko musango liba golokofu.

9Okusula ku kasolya k’ennyumba,

kisinga okubeera mu nnyumba n’omukazi omuyombi.

10Emmeeme y’omubi yeegomba okukola ebibi;

talaga muliraanwa we kisa n’akatono.

11Omukudaazi bw’abonerezebwa, atalina magezi agafuna;

n’ow’amagezi bw’ayigirizibwa afuna okutegeera.

12Katonda alaba ebifa mu nnyumba y’omubi,

era abakozi b’ebibi abazikkiririza ddala.

13Oyo aziba amatu ge eri okulaajana kw’omwavu,

naye alikoowoola nga talina amwanukula.

14Ekirabo ekigabire mu kyama kikakkanya obusungu obungi,

n’enguzi ebikiddwa mu munagiro eggyawo ekiruyi ekingi.

15Ensonga bwe zisalibwa mu bwenkanya, lye ssanyu eri abatuukirivu,

naye kiba kyekango eri abakozi b’ebibi.

16Omuntu awaba okuva mu kkubo ly’okutegeera,

agukira mu bafu.

17Aganza eby’amasanyu anaabanga mwavu, n’oyo

ayagala omwenge n’amafuta taligaggawala.

18Abakozi b’ebibi batuukibwako emitawaana egyandigudde ku balungi,

n’ekyandituuse ku b’amazima kituuka ku batali beesigwa.

19Okubeera mu ddungu,

kisinga okubeera n’omukazi omuyombi anyiiganyiiga.

20Mu nnyumba y’omutuukirivu mubaamu eby’obugagga eby’omuwendo,

naye omusirusiru ebibye byonna abyonoona.

21Agoberera obutuukirivu n’ekisa,

alibeera n’obulamu obukulaakulana n’ekitiibwa.

22Omuntu ow’amagezi alumba ekibuga eky’abazira nnamige,

era n’asesebbula enfo yaabwe gye beesiga.

23Afuga akamwa ke n’olulimi lwe,

yeewoonya emitawaana.

24“Mukudaazi,” lye linnya ly’ab’amalala abeeraga,

abeetwalira mu kwemanya okw’ekitalo mwe batambulira.

25Okwetaaga kw’omugayaavu lwe luliba olumbe lwe,

kubanga emikono gye tegyagala kukola.

26Olunaku lwonna aba yeegomba kweyongezaako,

naye omutuukirivu agaba awatali kwebalira.

27Ssaddaaka y’omubi ya muzizo,

na ddala bw’agireeta ng’alina ekigendererwa ekitali kirungi.

28Omujulizi ow’obulimba alizikirira,

naye ekigambo ky’oyo ayogera eby’amazima kiribeerera emirembe gyonna.

29Omuntu omubi yeekazaakaza,

naye omuntu ow’amazima yeegendereza amakubo ge.

30Tewali magezi, newaakubadde okutegeera, wadde ebiteeso

ebiyinza okulemesa Mukama.

31Embalaasi etegekerwa olunaku olw’olutalo,

naye obuwanguzi buva eri Mukama.