Ìfihàn 6 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 6:1-17

Ṣí àwọn èdìdì ìwé náà

1Èmi sì rí i nígbà tí Ọ̀dọ́-àgùntàn náà ṣí ọkàn nínú èdìdì wọ̀nyí, mo sì gbọ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ń wí bí sísán àrá pé, “Wá, wò ó!” 26.2: Sk 1.8; 6.1-3.Mo sì wò ó, kíyèsi i, ẹṣin funfun kan: ẹni tí ó sì jókòó lórí i rẹ̀ ní ọfà kan; a sì fi adé kan fún un: ó sì jáde lọ láti ìṣẹ́gun dé ìṣẹ́gun.

3Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kejì, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè wí pé, “Wá, wò ó!” 4Ẹṣin mìíràn tí ó pupa sì jáde, a sì fi agbára fún ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀, láti gba àlàáfíà kúrò lórí ilẹ̀ ayé, àti pé kí wọn kí ó máa pa ara wọn, a sì fi idà ńlá kan lé e lọ́wọ́.

5Nígbà tí ó sì di èdìdì kẹta, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kẹta wí pé, “Wá wò ó”. Mo sì wò ó, sì kíyèsi i, ẹṣin dúdú kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ní ìwọ̀n aláwẹ́ méjì ní ọwọ́ rẹ̀. 66.6: 2Ọb 6.25.Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn kan ní àárín àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin nì ti ń wí pé, òsùwọ̀n alikama kan fún owó idẹ kan, àti òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́ta fún owó idẹ kan, sì kíyèsi i, kí ó má sì ṣe pa òróró àti ọtí wáìnì lára.

7Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹrin, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kan wí pé, “Wá wò ó!” 86.8: Ho 13.14; El 5.12.Mo sì wò ó, kíyèsi, ẹṣin ràndànràndàn kan, orúkọ ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni ikú, àti ipò òkú sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn. A sì fi agbára fún wọn lórí ìdámẹ́rin ayé, láti fi idà, àti ebi, àti ikú, àti ẹranko lu orí ilẹ̀ ayé pa.

9Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì karùn-ún, mo rí lábẹ́ pẹpẹ, ọkàn àwọn tí a ti pa nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí tí wọ́n dìímú, 106.10: Sk 1.12; Sm 79.5; Gẹ 4.10.Wọ́n kígbe ní ohùn rara, wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa Olódùmarè, ẹni mímọ́ àti olóòtítọ́ ìwọ kì yóò ṣe ìdájọ́ kí o sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wa mọ́ lára àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé?” 11A sì fi aṣọ funfun fún gbogbo wọn; a sì wí fún wọn pé, kí wọn kí ó sinmi fún ìgbà díẹ̀ ná, títí iye àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wọn àti arákùnrin wọn tí a o pa bí wọn, yóò fi dé.

126.12: Jl 2.31; Ap 2.20.Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹfà mo sì rí i, sì kíyèsi i, ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá kan ṣẹ̀; oòrùn sì dúdú bí aṣọ ọ̀fọ̀ onírun, òṣùpá sì dàbí ẹ̀jẹ̀; 136.13: Isa 34.4.àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run sì ṣubú sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ń rẹ̀ àìgbó èso rẹ̀ dànù, nígbà tí ẹ̀fúùfù ńlá bá mì í. 14A sì ká ọ̀run kúrò bí ìwé tí a ká, àti olúkúlùkù òkè àti erékùṣù ní a sì ṣí kúrò ní ipò wọn.

156.15: Isa 2.10.Àwọn ọba ayé àti àwọn ọlọ́lá àti àwọn olórí ogun, àti àwọn ọlọ́rọ̀ àti àwọn alágbára, àti olúkúlùkù ẹrú, àti olúkúlùkù òmìnira, sì fi ara wọn pamọ́ nínú ihò ilẹ̀, àti nínú àpáta orí òkè; 166.16: Ho 10.8.wọ́n sì ń wí fún àwọn òkè àti àwọn àpáta náà pé, “Ẹ wó lù wá, kí ẹ sì fi wá pamọ́ kúrò lójú ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, àti kúrò nínú ìbínú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà. 176.17: Jl 2.11; Ml 3.2.Nítorí ọjọ́ ńlá ìbínú wọn dé; ta ni ó sì le dúró?”

Persian Contemporary Bible

مکاشفه 6:1-17

برّه مهرها را باز می‌كند

1همچنانكه محو تماشا بودم، «برّه» نخستين مهر را گشود. ناگاه يكی از آن چهار موجود زنده، با صدايی همچون غرش رعد گفت: «بيا!»

2نگاه كردم و اسبی سفيد ديدم. سوار بر اسب، كسی را ديدم كه كمانی در دست و تاجی بر سر داشت. او اسب را به جلو می‌راند تا در نبردهای بسيار، پيروز شود و فاتح جنگ باشد.

3سپس «برّه» مهر دوم را باز كرد. آنگاه شنيدم كه موجود زندهٔ دوم گفت: «بيا!»

4اين بار، اسبی سرخ پديدار شد. به سوار آن شمشيری داده شده بود تا قادر باشد صلح و سلامتی را از زمين بردارد و به جای آن هرج و مرج ايجاد كند. در نتيجه، جنگ و خونريزی در همه جا آغاز شد.

5چون «برّه» مهر سوم را گشود، شنيدم كه موجود زندهٔ سوم گفت: «بيا!» آنگاه اسب سياهی را ديدم كه سوارش ترازويی در دست داشت. 6سپس از ميان چهار موجود زنده، صدايی به گوش رسيد كه می‌گفت: «يک قرص نان گندم، يا يک كيلو آرد جو، به قيمت مزد روزانهٔ يک كارگر باشد. اما به روغن زيتون و شراب آسيبی نرسان!»

7چون «برّه» مهر چهارم را گشود، صدای موجود زندهٔ چهارم را شنيدم كه گفت: «بيا!» 8ناگاه اسب رنگ پريده‌ای ظاهر شد كه سوارش «مرگ» نام داشت. به دنبال او، اسب ديگری می‌آمد كه نام سوارش «دنيای مردگان» بود. به آن دو، اختيار و قدرت داده شد تا يک چهارم زمين را بوسيلهٔ جنگ، قحطی، بيماری و جانوران وحشی نابود كنند.

9وقتی مهر پنجم را باز كرد، قربانگاهی ظاهر شد. زير قربانگاه، روحهای كسانی را ديدم كه برای موعظهٔ كلام خدا و شهادت راستين خود شهيد شده بودند. 10ايشان با صدايی بلند به خداوند می‌گفتند: «ای خداوند پاک و حق، تا به كی بر ساكنان زمين داوری نمی‌كنی و انتقام خون ما را از آنان نمی‌گيری؟» 11سپس به هر يک از ايشان، ردايی سفيد دادند و گفتند كه كمی ديگر نيز استراحت كنند تا همقطارانشان كه بايد مانند ايشان به خاطر خدمت به عيسی مسيح شهيد گردند، به جمع آنان بپيوندند.

12آنگاه «بره» مهر ششم را گشود. ناگهان زلزلهٔ شديدی رخ داد و خورشيد مانند پارچه‌ای سياه، تيره و تار گشت و ماه به رنگ خون درآمد. 13سپس ديدم كه ستارگان آسمان بر زمين می‌ريزند، درست مانند انجيرهای نارس كه در اثر باد شديد، از درخت كنده شده، بر زمين می‌افتند. 14آسمان نيز مانند يک طومار به هم پيچيد و ناپديد گشت و تمام کوهها و جزيره‌ها تكان خورده، از جای خود منتقل شدند. 15پادشاهان زمين و رهبران جهان، فرمانداران و ثروتمندان، كوچک و بزرگ، برده و آزاد، همه خود را در غارها و زير تخته سنگهای کوهها پنهان كردند. 16ايشان به کوهها و صخره‌ها التماس كرده، می‌گفتند: «ای کوهها و ای صخره‌ها، بر ما بيفتيد و ما را از روی آنكه بر تخت نشسته و از خشم بره پنهان كنيد. 17زيرا روز عظيم خشم آنان فرا رسيده است. پس كيست كه تاب مقاومت داشته باشد؟»