Ọbadiah 1 – YCB & KSS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ọbadiah 1:1-21

1Ìran ti Ọbadiah.

1-21: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ml 1.2-5.Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:

A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,

“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

2“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;

ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,

3Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,

ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,

tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,

ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,

‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’

4Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,

bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”

ni Olúwa wí.

5“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,

bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,

Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:

wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?

Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,

wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?

6Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,

tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.

7Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ

ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:

Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;

àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,

ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

8Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,

Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,

àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?

9A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,

gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau

ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.

10Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,

ìtìjú yóò bò ọ,

a ó sì pa ọ run títí láé.

11Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,

ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,

tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ

tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,

ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.

12Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,

ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀

ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,

ní ọjọ́ ìparun wọn

ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀

ní ọjọ́ wàhálà wọn.

13Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,

ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀

nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,

ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

14Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà

láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.

Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú

wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé

lórí gbogbo àwọn kèfèrí.

Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;

ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi

bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí

Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn

wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni

Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́

àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn

18Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná

àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná

ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko

wọn yóò fi iná sí i,

wọn yóò jo run.

Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,

àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni

ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.

Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;

Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.

20Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani

yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;

àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi

yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní

21Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá

láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.

Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

Kurdi Sorani Standard

عۆبەدیا 1:1-21

بینینەکەی عۆبەدیا

1بینینەکەی عۆبەدیا.

یەزدانی باڵادەست سەبارەت بە ئەدۆم ئەمە دەفەرموێت،

هەواڵێکمان لەلایەن یەزدانەوە بیست،

نێردراوێک بۆ نەتەوەکان نێردراوە تاکو پێیان بڵێت:

«هەستن! هەستن بۆ جەنگ.»

2«ئێستا لەنێو گەلاندا بچووکت دەکەمەوە،

تۆ زۆر ڕیسوا دەبیت.

3فیزی دڵت هەڵیخەڵەتاندی،

ئەی نیشتەجێی نێو کەلێنی تاشەبەرد1‏:3 پایتەختی ئەدۆم ناوی سەلەع بوو، کە هەمان وشەی عیبرییە بۆ تاشەبەرد.‏،

ئەوەی نشینگەکەت لە بەرزاییدایە،

ئەوەی لە دڵی خۆتدا دەڵێیت:

”کێ دامدەگرێتە سەر زەوی؟“

4ئەگەر وەک هەڵۆ بەرز بیتەوە و

ئەگەر هێلانەت لەناو ئەستێرەکان دابنێیت،

لەوێوە دەتهێنمە خوارەوە.»

ئەوە فەرمایشتی یەزدانە.

5«ئەگەر دز یان چەتەی شەوانت بۆ بێت،

ئایا تەنها ئەوەی پێویستیان بێت نایدزن؟

ئەگەر ڕەزبڕت1‏:5 ڕەزبڕ: ئەوەی بەرهەمی ڕەزی دەبڕێتەوە.‏ بۆ بێت

ئایا هەندێک ترێ بەجێناهێڵن؟

ئای چۆن بە تەواوی بڕایتەوە!

6ئای عیسۆ چۆن دەپشکێنرێت!

گەنجینە شاردراوەکانی تاڵان دەکرێن!

7هەموو هاوپەیمانەکانت هەتا سنوور ڕاویان نای،

هەڵیانخەڵەتاندی و بەسەرتدا زاڵبوون،

ئەوانەی نمەکی تۆیان کردبوو داوت بۆ دەنێنەوە،

بەڵام تۆ تێناگەیت.»

8یەزدان دەفەرموێت:

«ئایا لەو ڕۆژەدا،

دانایان لە ئەدۆم لەناو نابەم،

تێگەیشتووانیش لە چیای عیسۆ؟

9ئەی تێمان، پاڵەوانەکانت دەتۆقن،

هەموو ئەوانەی لە چیای عیسۆن

بە کوشتن لەناودەچن.

10لەبەر ستەمی تۆ لە یاقوبی برات،

ڕیسوایی داتدەپۆشێت،

بۆ هەتاهەتایە لەناودەچیت.

11ئەو ڕۆژەی تەماشات دەکرد

کاتێک بیانییەکان سامانەکەیان داگیر کرد و

نامۆکان هاتنە ناو دەروازەکانی و

لەسەر ئۆرشەلیم تیروپشکیان کرد،

هەروەها تۆش وەک یەکێک بووی لەوان.

12بەڵام نابێت بە ڕۆژی کارەساتی براکەت دڵخۆش بیت،

یان لە ڕۆژی لەناوچوونی نەوەی یەهودا شادمان بیت،

یان لە ڕۆژی تەنگانەیاندا شانازی بکەیت.

13نابێت بچیتە ناو دەروازەی گەلەکەم

لە ڕۆژی کارەساتیان،

یان بە ناخۆشییەکەیان دڵخۆش بیت

لە ڕۆژی کارەساتیان،

یان دەستت بۆ سامانەکەیان درێژ بکەیت

لە ڕۆژی کارەساتیان.

14نابێت لەسەر دووڕیانەکان بوەستیت

بۆ کوشتنی دەربازبووەکانیان،

نابێت هەڵاتووەکانیان ڕادەست بکەیت

لە ڕۆژی تەنگانەیاندا.

15«ڕۆژی یەزدان1‏:15 ڕۆژی سزادانی گوناهباران و ڕزگارکردنی گەلی خودا.‏ بۆ هەموو گەلان نزیکە.

هەروەک ئەوەی کردت ئاوات پێ دەکرێتەوە،

کردەوەکانت بەسەر خۆت دێتەوە.

16هەروەک لەسەر کێوی پیرۆزم خواردتانەوە،

هەموو گەلان بەردەوام جامی سزا دەخۆنەوە؛

دەخۆنەوە و دەخۆنەوە و

وەک ئەوەیان لێدێت کە هەرگیز نەبووبن.

17بەڵام دەربازبوون لەسەر کێوی سییۆن دەبێت،

پیرۆز دەبێت،

بنەماڵەی یاقوبیش بەشە میراتی خۆیان وەردەگرن.

18بنەماڵەی یاقوب دەبێتە ئاگر و

بنەماڵەی یوسف دەبێتە گڕ؛

بنەماڵەی عیسۆش دەبێتە پووش،

جا گڕیان تێبەردەدەن و دەیانخۆن.

بنەماڵەی عیسۆ کەسیان لێ دەرباز نابێت.»

ئەمە فەرمایشتی یەزدانە.

19خەڵکی نەقەب

چیای عیسۆ داگیر دەکەن،

خەڵکی زوورگەکانیش

خاکی فەلەستییەکان.

دەبنە خاوەنی کێڵگەکانی ئەفرایم و سامیرە،

بنیامینیش دەبێتە خاوەنی گلعاد.

20ئەو کۆمەڵەی ڕاپێچکراوانی ئیسرائیل کە لە کەنعانن

هەتا سەرەفەند دەست بەسەر خاکەکەدا دەگرن؛

ڕاپێچکراوانی ئۆرشەلیمیش کە لە سفارەدن

دەست بەسەر شارۆچکەکانی نەقەبدا دەگرن.

21ڕزگارکەرانی خاکەکەش سەردەکەونە سەر کێوی سییۆن

بۆ فەرمانڕەوایەتی لەسەر چیای عیسۆ.

پاشایەتیش بۆ یەزدان دەبێت.