1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,
nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!
Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
tí ó wà ní ipò opó,
Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú
ni ó padà di ẹrú.
2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò
pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀
kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀
wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,
Juda lọ sí àjò
Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.
Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́
ibi tí kò ti le sá àsálà.
4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,
nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,
àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,
àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,
òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,
nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,
Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,
ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé
kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.
Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín
tí kò rí ewé tútù jẹ;
nínú àárẹ̀ wọ́n sáré
níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni
Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀
tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,
kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó
wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀
ó sì ti di aláìmọ́.
Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,
nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;
ó kérora fúnrarẹ̀,
ó sì lọ kúrò.
9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,
Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;
olùtùnú kò sì ṣí fún un.
“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,
nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé
gbogbo ìní rẹ;
o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè
tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—
àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀
láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora
bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;
wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ
láti mú wọn wà láààyè.
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,
nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?
Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,
Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà
tí a fi fún mi, ti
Olúwa mú wá fún mi
ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
13“Ó rán iná láti òkè
sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.
Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,
ó sì yí mi padà.
Ó ti pa mí lára
mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;
ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.
Wọ́n ti yí ọrùn mi ká
Olúwa sì ti dín agbára mi kù.
Ó sì ti fi mí lé
àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
15“Olúwa kọ
àwọn akọni mi sílẹ̀,
ó rán àwọn ológun lòdì sí mi
kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.
Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́
àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún
tí omijé sì ń dà lójú mi,
Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,
kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.
Àwọn ọmọ mi di aláìní
nítorí ọ̀tá ti borí.”
17Sioni na ọwọ́ jáde,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.
Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu
pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un
Jerusalẹmu ti di
ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,
ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;
ẹ wò mí wò ìyà mi.
Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi
ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.
Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi
ṣègbé sínú ìlú
nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ
tí yóò mú wọn wà láààyè.
20“Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!
Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,
ìdààmú dé bá ọkàn mi
nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.
Ní gbangba ni idà ń parun;
ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.
Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;
wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.
Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,
kí wọ́n le dàbí tèmi.
22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;
jẹ wọ́n ní yà
bí o ṣe jẹ mí ní yà
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ìrora mi pọ̀
ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
Несрећни град
1Како седи престоница усамљена!
А некад је пуна људи била.
Град постаде као удовица,
а некад је свет га поштовао.
Та царица међу градовима
робиња је сада потлачена.
2Грозним плачем сву ноћ плаче,
низ образе сузе рони.
Никог нема да је теши сада,
а некада сви јој пријатељи беху.
Савезници сви је издадоше,
постали су њени непријатељи.
3Народ Јудин, робље беспомоћно,
у невољи, у тешком прогонству,
по туђинским сад живе земљама.
Нема места где би да почину.
Одасвуд их окружују гонитељи,
из теснаца никуд да побегну.
4Тужни су путеви ка сионском Дому,
на празнике не долази нико.
Сва су врата разваљена,
свештеници уздишу једнако,
уплакане су девојке које су некад певале.
Сион је у горком ропцу.
5Над њим сада господаре тлачитељи,
због победе ликују непријатељи.
Многобројни су греси сионски,
зато га је Господ изложио патњама.
Насилници заробише децу са Сиона
и одведоше их у изгнанство.
6Повукла се од ћерке сионске,
повукла се сва слава његова.
Кнезови му постадоше као срне
исцрпене од глади,
у бежању изгубише снагу
испред ловаца који их гоне.
7Јерусалим, рушевина усамљена,
свог се сјаја опомиње,
а кад паде непријатељима у руке,
никог нема да му помоћ пружи.
Гледају га тлачитељи,
смеју му се зато што је пао.
Тешки греси и страдања тешка
8Тешки ли су овог града греси!
Гадан ли је, нечист ли је!
Ценише га, а сад га презиру:
Град без части, го је у срамоти.
Само јечи, лице крије,
осврће се, иза себе гледа.
9Види му се да је нечист јако,
али он не мари што га ово снађе.
Ужасно је како он пропада,
а никога нема да га теши.
Погледај, Господе, његову невољу,
јер непријатељи ликују ли, ликују.
10Непријатељ граби, пљачка,
све ризнице овог града.
Јерусалим гледа како странци
проваљују Дому у Светилиште,
а њима си, Господе, забранио
да ступају где ти збор ступа.
11Цвили народ, како да не тугује!
Траже хлеба, трампе драгоцености своје за храну,
не би ли живнули некако.
„Смилуј ми се – плачу – о, Господе!
Смилуј ми се,
јер падох у беду.“
Јерусалим у тузи
12Погледајте ме, сви што пролазите
– град довикује тужно –
Има ли бола сличног овом болу
што погоди мене?
Како ме је Господ ударио
у дан кад се на ме разгневио.
13Послао је огањ са висине,
разгоре га по мојим костима.
Разапео мрежу испред мојих ногу
и на земљу оборио.
Уцвилио ме је и ожалостио
у мукама за сва времена.
14Све моје грехе на мене навалио,
руком их својом у бреме свезао,
на мој га је врат натоварио.
Ослабих од овог терета.
Господ ме је предао мојим душманима,
ја им се пак не могу супротставити.
15Свим мојим јунацима
Господ се наругао.
Дигао је ратнике против мене,
да побије моје узданице младе.
Као грожђе у муљари
изгазио је Господ лепу земљу Јудину.
16Зато из мојих очију као поток лију сузе.
Утешити не може ме нико;
охрабрити не може ме нико.
Синови су моји побеђени,
непријатељ ништа народу не остави.
17Сион руке своје пружа,
али помоћ нико му не пружа.
Господ поста противник народу Јаковљеву,
са свих страна наваљују тлачитељи;
с Јерусалимом поступају
као да је гадост међу њима.
Реч о праведном Богу
18Господ ме је праведно казнио,
јер његову реч нисам послушао.
О, чујте ме, одасвуд народи,
јаде моје гледајте, видите;
девојке моје, младиће моје,
у прогонство отераше.
19Позвах своје савезнике,
а они ми помоћ ускратише.
Свештеници моји и старешине
по градским улицама помреше,
а само су храну тражили
не би ли у животу остали.
20На мој ропац погледај, Господе,
на измученост душе моје.
У грудима срце ми се грчи,
жалостан сам због свога пркоса.
По улицама синове моје убијају,
а унутра, по кућама, смрт коси.
21Како цвилим, чуј ме.
Нема никог да ме утеши.
За моју несрећу душмани су чули,
те ликују зато што си ми је ти послао.
Дај да и мени сване!
Нека слично мени и душмани пате.
22Прокуни њихове опачине све,
рачунај им зло за зло;
мене си већ за грехе казнио,
и њих казни тако.
Само јечим ја у јаду сада,
у мом је срцу туга.