1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,
nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!
Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
tí ó wà ní ipò opó,
Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú
ni ó padà di ẹrú.
2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò
pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀
kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀
wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,
Juda lọ sí àjò
Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.
Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́
ibi tí kò ti le sá àsálà.
4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,
nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,
àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,
àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,
òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,
nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,
Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,
ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé
kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.
Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín
tí kò rí ewé tútù jẹ;
nínú àárẹ̀ wọ́n sáré
níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni
Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀
tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,
kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó
wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀
ó sì ti di aláìmọ́.
Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,
nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;
ó kérora fúnrarẹ̀,
ó sì lọ kúrò.
9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,
Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;
olùtùnú kò sì ṣí fún un.
“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,
nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé
gbogbo ìní rẹ;
o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè
tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—
àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀
láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora
bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;
wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ
láti mú wọn wà láààyè.
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,
nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?
Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,
Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà
tí a fi fún mi, ti
Olúwa mú wá fún mi
ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
13“Ó rán iná láti òkè
sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.
Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,
ó sì yí mi padà.
Ó ti pa mí lára
mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;
ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.
Wọ́n ti yí ọrùn mi ká
Olúwa sì ti dín agbára mi kù.
Ó sì ti fi mí lé
àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
15“Olúwa kọ
àwọn akọni mi sílẹ̀,
ó rán àwọn ológun lòdì sí mi
kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.
Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́
àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún
tí omijé sì ń dà lójú mi,
Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,
kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.
Àwọn ọmọ mi di aláìní
nítorí ọ̀tá ti borí.”
17Sioni na ọwọ́ jáde,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.
Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu
pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un
Jerusalẹmu ti di
ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,
ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;
ẹ wò mí wò ìyà mi.
Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi
ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.
Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi
ṣègbé sínú ìlú
nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ
tí yóò mú wọn wà láààyè.
20“Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!
Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,
ìdààmú dé bá ọkàn mi
nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.
Ní gbangba ni idà ń parun;
ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.
Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;
wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.
Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,
kí wọ́n le dàbí tèmi.
22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;
jẹ wọ́n ní yà
bí o ṣe jẹ mí ní yà
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ìrora mi pọ̀
ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
1Sɛnea kuropɔn no adan amamfo ni,
kuropɔn a anka nnipa ahyɛ no ma!
Adɛn nti na wayɛ okunafobea a
kan no na anka ɔyɛ ɔkɛse wɔ amanaman no mu?
Nea na ɔyɛ ɔhemmea wɔ amantam no mu no
abɛyɛ afenaa nnɛ.
2Osu yayaayaw anadwo,
nusu sensan nʼafono so.
Nʼadɔfo nyinaa mu no,
obiara nni hɔ a ɔkyekyee ne werɛ.
Ne nnamfonom nyinaa ayi no ama
Wɔayɛ nʼatamfo.
3Amanehunu ne adwumaden akyi no,
Yuda kɔ nnommum mu.
Ɔte amanaman no mu
na onni ahomegyebea.
Wɔn a wɔtaa no nyinaa ato no
wɔ nʼahokyere mu.
4Akwan a ɛkɔ Sion no resu,
efisɛ obiara nkɔ nʼafahyɛ ase.
Nʼapon nyinaa adeda mpan,
na nʼasɔfo si apini,
ne mmabaa di yaw,
na ɔwɔ yawdi a mu yɛ den mu.
5Nʼatamfo abɛyɛ ne wuranom;
wɔn a wɔne no ayɛ adɔm ho adwo wɔn.
Awurade ama awerɛhow aba ne so
nʼamumɔyɛ bebrebe nti.
Ne mma kɔ nnommum mu.
Wɔayɛ nneduafo ama ɔtamfo.
6Anuonyam nyinaa atu
afi Ɔbabea Sion so kɔ.
Ne mmapɔmma ayɛ sɛ aforote
a wonnya adidibea;
na wɔde mmerɛwyɛ aguan
wɔ wɔn ataafo anim.
7Nʼamanehunu ne akyinkyinakyinkyin nna mu no,
Yerusalem kae ademude nyinaa
a na ɛwɔ no wɔ nna a atwa mu no mu.
Ne nkurɔfo kɔtɔɔ ɔtamfo no nsa mu no,
na obiara nni hɔ a ɔbɛboa no.
Nʼatamfo de wɔn ani hwɛɛ no
na wɔserew ne sɛe.
8Yerusalem ayɛ bɔne kɛse
enti ne ho agu fi.
Wɔn a wodi no ni no sopa no,
efisɛ wɔahu nʼadagyaw;
ɔno ankasa gu ahome
na ɔdan nʼani.
9Nʼafideyɛ atu aka ne ntade mu;
wannwene ne daakye ho.
Nʼasehwe yɛ nwonwa;
obiara ankyekye ne werɛ.
“Awurade, hwɛ mʼamanehunu,
efisɛ ɔtamfo adi nkonim.”
10Ɔtamfo no de ne nsa too
nʼademude nyinaa so;
ohuu sɛ amanaman
rehyɛn ne kronkronbea hɔ,
nnipa a woabra sɛ
wɔnnhyɛn wʼasafo mu no.
11Ne nkurɔfo nyinaa si apini
bere a wɔrehwehwɛ aduan;
wɔde wɔn ademude sesa aduan
de nya ahoɔden.
“Awurade, hwɛ na dwene me ho,
efisɛ wobu me animtiaa.”
12“Ɛmfa mo ho ana, mo a mutwa mu wɔ hɔ nyinaa?
Monhwɛ na munhu.
Ɔyaw bi wɔ hɔ a ɛte sɛ me de
a wɔma ɛbaa me so yi,
nea Awurade de baa me so
wɔ nʼabufuwhyew da no ana?
13“Ɔsomaa ogya fii ɔsoro,
ma ɛbaa me nnompe mu.
Osum afiri maa mʼanan
na ɔsan me kɔɔ mʼakyi.
Ɔyɛɛ me pasaa,
metɔɔ beraw da mu nyinaa.
14“Woakyekyere me bɔne ahyɛ konnua mu;
ɔde ne nsa nwen bɔɔ mu.
Wɔde asɛn me kɔn mu
na Awurade atwe mʼahoɔden.
Ɔde me ahyɛ wɔn a
merentumi nnyina wɔn anim no nsa.
15“Awurade apo
akofo a wɔwɔ me ntam nyinaa;
wafrɛ asraafo atia me
sɛ wɔmmɛdwerɛw me mmerante.
Awurade atiatia Ɔbabea Ɔbabun Yuda so
wɔ ne nsakyiamoa mu.
16“Eyinom nti na misu
na nusu aguare me.
Obiara mmɛn a ɔbɛkyekye me werɛ,
nea ɔbɛhyɛ me honhom den nni hɔ.
Me mma agyigya
efisɛ ɔtamfo no adi nkonim.”
17Sion trɛw ne nsa mu
nanso obiara nni hɔ a ɔbɛkyekye ne werɛ.
Awurade ahyɛ ama Yakob se
ne mfɛfo bɛyɛ nʼatamfo;
Yerusalem abɛyɛ
afide wɔ wɔn mu.
18“Awurade yɛ ɔtreneeni,
nanso manni nʼahyɛde so.
Muntie, mo amanaman nyinaa
monhwɛ me yaw.
Me mmerante ne mmabaa
kɔ nnommum mu.
19“Mefrɛɛ mʼadɔfo
nanso woyii me mae.
Mʼasɔfo ne me mpanyimfo
ase tɔree wɔ kuropɔn no mu,
bere a wɔrehwehwɛ aduan adi
na wɔanwuwu.
20“Awurade, hwɛ me mmɔbɔ!
Meredi yaw wɔ me mu,
na me koma mu nso minni ahotɔ,
efisɛ mayɛ otuatewfo kɛse.
Afoa hyɛ me awerɛhow wɔ abɔnten so;
ofie nso yɛ owu nko ara.
21“Nnipa ate mʼapinisi,
nanso obiara nni hɔ a ɔbɛkyekye me werɛ.
Mʼatamfo nyinaa ate mʼamanehunu
wɔn ani gye nea woayɛ no ho.
Ma nna a woahyɛ no mmra
sɛnea wɔbɛyɛ sɛ me.
22“Fa wɔn atirimɔdensɛm nyinaa si wʼanim;
na wo ne wɔn nni
sɛnea wo ne me adi;
esiane mʼamumɔyɛ no nti.
Mʼapinisi dɔɔso
na me koma abotow.”