Òwe 31:1-31
1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,
ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.
2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!
Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,
okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli
kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì
kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle
5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí
kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n
6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé
wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;
7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn
kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn
fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun
9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè
jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?
Ó níye lórí ju iyùn lọ
11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀
kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi
ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀
Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;
ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn
15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;
ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀
àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;
nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀
17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára
apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́
18Ó rí i pé òwò òun pé
fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru
19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú
20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀
nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;
ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀
23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú
níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú
24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n
ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò
25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ
ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n
ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀
kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́
28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún
ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un
29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá
ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”
30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán
nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn
31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i
kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
Proverbios 31:1-31
Dichos del rey Lemuel
1Los dichos del rey Lemuel. Mensaje mediante el cual31:1 Lemuel. … cual. Alt. Lemuel de Masa, mediante los cuales. su madre lo instruyó:
2«¿Qué pasa, hijo mío?
¿Qué pasa, hijo de mis entrañas?
¿Qué pasa, fruto de mis promesas?31:2 fruto de mis promesas? Alt. respuesta a mis oraciones.
3No gastes tu vigor en las mujeres
ni tu fuerza en las que arruinan a los reyes.
4»No conviene que los reyes, Lemuel,
no conviene que los reyes se den al vino
ni que los gobernantes se entreguen a la cerveza;
5no sea que al beber se olviden de lo que la ley ordena
y priven de sus derechos a todos los oprimidos.
6Dales cerveza a los que están por morir
y vino a los amargados;
7¡que beban y se olviden de su pobreza!
¡que no vuelvan a acordarse de sus penas!
8»¡Levanta la voz por los que no tienen voz!
¡Defiende los derechos de los desposeídos!
9¡Levanta la voz y hazles justicia!
¡Defiende a los pobres y necesitados!».
Epílogo: Acróstico a la mujer ejemplar31:10-31 Los vv. 10-31 son un acróstico, en que cada verso comienza con una de las letras del alfabeto hebreo.
Álef
10Mujer ejemplar,31:10 ejemplar. Alt. fuerte. ¿dónde se hallará?
¡Es más valiosa que las piedras preciosas!
Bet
11Su esposo confía plenamente en ella
y no le faltarán ganancias.
Guímel
12Ella le es fuente de bien, no de mal,
todos los días de su vida.
Dálet
13Anda en busca de lana y de lino,
y gustosa trabaja con sus manos.
He
14Es como los barcos mercantes,
que traen de muy lejos su alimento.
Vav
15Se levanta de madrugada,
da de comer a su familia
y asigna tareas a sus criadas.
Zayin
16Calcula el valor de un campo y lo compra;
con sus ganancias31:16 sus ganancias. Lit. el fruto de sus manos. planta un viñedo.
Jet
17Decidida se ciñe la cintura,31:17 se ciñe la cintura. Lit. se ciñe con fuerza sus lomos.
pues sus brazos están fuertes para el trabajo.
Tet
18Se complace en la prosperidad de sus negocios;
no se apaga su lámpara en la noche.
Yod
19Con sus manos sostiene el telar
y con sus dedos maneja el hilo.
Caf
20Tiende la mano al pobre
y con ella sostiene al necesitado.
Lámed
21Si nieva, no tiene que preocuparse de su familia,
pues todos están bien abrigados.
Mem
22Prepara las mantas para su cama;
se viste de lana color púrpura y tela de lino fino.
Nun
23Su esposo es respetado en las puertas de la ciudad;
ocupa un puesto entre las autoridades del lugar.
Sámej
24Confecciona ropa de lino y la vende;
provee cinturones a los comerciantes.
Ayin
25Se reviste de fuerza y dignidad
y afronta segura el porvenir.
Pe
26Cuando habla, lo hace con sabiduría;
cuando instruye, lo hace con amor.
Tsade
27Está atenta a la marcha de su hogar
y el pan que come no es fruto del ocio.
Qof
28Sus hijos se levantan y la felicitan;
también su esposo la alaba:
Resh
29«Muchas mujeres han realizado proezas,
pero tú las superas a todas».
Shin
30Engañoso es el encanto y pasajera la belleza;
la mujer que teme al Señor es digna de alabanza.
Tav
31¡Sean reconocidos31:31 Sean reconocidos. Alt. Denle. sus logros
y en las puertas de la ciudad sean alabadas sus obras!