1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,
ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.
2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!
Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,
okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli
kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì
kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle
5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí
kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n
6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé
wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;
7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn
kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn
fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun
9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè
jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?
Ó níye lórí ju iyùn lọ
11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀
kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi
ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀
Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;
ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn
15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;
ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀
àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;
nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀
17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára
apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́
18Ó rí i pé òwò òun pé
fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru
19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú
20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀
nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;
ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀
23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú
níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú
24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n
ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò
25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ
ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n
ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀
kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́
28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún
ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un
29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá
ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”
30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán
nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn
31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i
kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
Приче цара Лемуила
1Поруке цара Лемуила, пророштва којим га је поучила његова мајка:
2„Чуј, сине мој! Чуј, сине утробе моје!
Чуј, сине завета мојих!
3Не дај своју снагу женама,
ни путеве своје онима што руше цареве.
4Није за цареве, Лемуило,
није за цареве да пију вино
и за владаре склоност жестоком пићу.
5Да не би уз пиће заборавили шта су одредбе,
па онда ускратили право свим ојађенима.
6Жестоко пиће остави за умирућег
и вино за унесрећену душу.
7Нека такав пије, нека заборави своју беду
и свог јада нека се не сећа.
8Говори уместо безгласног
и заступај све људе који умиру.
9Говори и суди праведно,
одбрани право сиромаха и убогог.“
Честита жена
10Ко да нађе честиту жену?
Таква вреди много више од драгуља.
11У њу се поуздаје срце њеног мужа
и неће остати без добитка.
12Добро, а не зло она му чини
кроз све дане живота свога.
13Прихвата се вуне и лана
па ужива у раду руку својих.
14Она је попут трговачких галија,
јер издалека доноси себи хлеба.
15Диже се док је још мркло,
храну дели укућанима
и послове слушкињама својим.
16Разгледа њиву па је купи,
од зараде својих руку сади виноград.
17Одважно се прихвата посла
и мишице своје јача.
18Увиђа да добро зарађује
и светиљка јој се по ноћи не гаси.
19Рукама се преслице дохвата,
длановима прихвата вретено.
20Сиромаху отвара шаку,
руке пружа убогоме.
21Не страхује за укућане када је снег,
јер сви у дому носе двоструку одећу31,21 Ово је превод према Септуагинти, а према јеврејском тексту реч је о гримизној одећи..
22Покриваче себи шије
и одећу од танкога платна и скерлета.
23Познаје се њен муж на вратима
када седи са старешинама земље.
24Она шије ланене кошуље и продаје их,
појасевима снабдева трговце.
25Облачи се у част и у дику
и смеје се дану што долази.
26Мудро отвара уста своја,
а на језику су јој поуке истине.
27Надгледа како јој укућани живе
и не једе хлеб у доколици.
28Синови њени се дижу и благосиљају је,
а њен је муж хвали:
29„Честите су многе жене
али ти их све надмашујеш!“
30Допадљивост је заводљива и лепота је пролазна,
али ће хваљена бити жена која се Господа боји.
31Подајте јој нешто од плода њених руку
и нека је на вратима града хвале дела њена!