Ìfihàn 22 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 22:1-21

Omi iyè

1Ó sì fi odò omi ìyè kan hàn mi, tí ó mọ́ bí Kirisitali, tí ń tí ibi ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn jáde wá, 222.2: Gẹ 2.9.Ní àárín ìgboro rẹ̀, àti níhà èkínní kejì odò náà, ni igi ìyè gbé wà, tí o máa ń so onírúurú èso méjìlá, a sì máa so èso rẹ̀ ni oṣooṣù ewé igi náà sí wà fún mímú àwọn orílẹ̀-èdè láradà. 322.3: Sk 14.11.Ègún kì yóò sì ṣí mọ: ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-àgùntàn ni yóò sì máa wà níbẹ̀; àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò sì máa sìn ín: 422.4: Sm 17.15.Wọ́n ó si máa rí ojú rẹ̀; orúkọ rẹ̀ yóò si máa wà ni iwájú orí wọn. 5Òru kì yóò sí mọ́; wọn kò sì ní wa ìmọ́lẹ̀ fìtílà, tàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn; nítorí pé Olúwa Ọlọ́run ni yóò tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn: wọn ó sì máa jẹ ọba láé àti láéláé.

6Ó sì wí fún mi pé, “Òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: Olúwa Ọlọ́run ẹ̀mí àwọn wòlíì ni ó sì ran angẹli rẹ̀ láti fi ohun tí ó ní láti ṣẹlẹ̀ láìpẹ́ yìí hàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.”

7“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán! Ìbùkún ni fún ẹni tí ń pa ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí mọ́!”

8Èmi, Johanu, ni ẹni tí ó gbọ́ tí ó sì ri nǹkan wọ̀nyí. Nígbà tí mo sì gbọ́ tí mo sì rí, mo wólẹ̀ láti foríbalẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ angẹli náà, tí o fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi, 9Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Wó ò, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ wòlíì, àti ti àwọn tí ń pa ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí mọ́: foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run!”

10Ó sì wí fún mi pé, “má ṣe fi èdìdì di ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí inú ìwé yìí: nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀. 1122.11: Da 12.10.Ẹni tí ń ṣe aláìṣòótọ́, kí ó máa ṣe aláìṣòótọ́ nì só: àti ẹni tí ń ṣe ẹlẹ́gbin, kí ó máa ṣe ẹ̀gbin nì só: àti ẹni tí ń ṣe olódodo, kí ó máa ṣe òdodo nì só: Àti ẹni tí ń ṣe mímọ́, kí ó máa ṣe mímọ́ nì só.”

1222.12: Isa 40.10; Jr 17.10.“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán; èrè mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, láti sán fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ yóò tí rí. 1322.13: Isa 44.6; 48.12.Èmi ni Alfa àti Omega, ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin.

14“Ìbùkún ni fún àwọn ti ń fọ aṣọ wọn, kí wọ́n lè ni ẹ̀tọ́ láti wá sí ibi igi ìyè náà, àti kí wọ́n lè gbà àwọn ẹnu ibodè wọ inú ìlú náà. 15Nítorí ni òde ni àwọn ajá gbé wà, àti àwọn oṣó, àti àwọn àgbèrè, àti àwọn apànìyàn, àti àwọn abọ̀rìṣà, àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn èké tí ó sì ń hùwà èké.

16“Èmi, Jesu, ni ó rán angẹli mi láti jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí fún yin ní tí àwọn ìjọ. Èmi ni gbòǹgbò àti irú-ọmọ Dafidi, àti ìràwọ̀ òwúrọ̀ tí ń tàn.”

1722.17: Isa 55.1.Ẹ̀mí àti ìyàwó wí pé, “Máa bọ!” Àti ẹni tí ó ń gbọ́ kí ó wí pé, “Máa bọ̀!” Àti ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ kí ó wá, àti ẹni tí o bá sì fẹ́, kí ó gba omi ìyè náà lọ́fẹ̀ẹ́.

18Èmi kìlọ̀ fún olúkúlùkù ẹni tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí pé, bí ẹnikẹ́ni ba fi kún wọn, Ọlọ́run yóò fi kún àwọn ìyọnu tí a kọ sínú ìwé yìí fún un. 19Bí ẹnikẹ́ni bá sì mú kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìwé ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, Ọlọ́run yóò sì mú ipa tirẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, àti kúrò nínú ìlú mímọ́ náà, àti kúrò nínú àwọn ohun tí a kọ sínú ìwé yìí.

20Ẹni tí ó jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí wí pé, “Nítòótọ́ èmi ń bọ̀ kánkán.”

Àmín, Máa bọ̀, Jesu Olúwa!

2122.21: 2Tẹ 3.18.Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àmín.

Slovo na cestu

Zjevení 22:1-21

Navždy v Boží přítomnosti

1Ještě mi ukázal řeku života, čistou jako křišťál. Vyvěrala z trůnu Boha a Beránka a protékala na náměstí toho města. 2Po obou jejích březích rostl strom života nesoucí dvanáct druhů ovoce, na každý měsíc jeden. A listy toho stromu sloužily všem ke zdraví. 3Tam nebude vůbec nic škodlivého. Vládě Boha a Beránka se všichni ochotně podřídí. 4Budou ho vidět tváří v tvář a na čele ponesou jeho jméno. 5Už se tam nikdy nesetmí, takže nebudou rozsvěcet lampy ani čekat na východ slunce. Bůh bude jejich stálé světlo a s ním budou kralovat na věky věků.

Zaslíbení Ježíšova návratu

6Anděl mi řekl: „Tato slova jsou spolehlivá a pravdivá. Pán Bůh, který dával svého Ducha prorokům, mě poslal, abych oznámil jeho služebníkům, co se zanedlouho stane.

7Vzkazuje vám: Pozor, přijdu náhle! Dobře dělá, kdo bere vážně proroctví této knihy.“

8Když jsem to všechno já, Jan, slyšel a viděl, padl jsem před svým průvodcem na kolena. 9On mi však řekl: „Nech toho, vždyť jsem jen spoluslužebník tvůj i tvých bratří, proroků a těch, kdo budou dbát slov této knihy. Před Bohem klekej!“ 10Pak dodal: „Nic z toho nezatajuj, ale zveřejni to. Doba těch událostí se nezadržitelně blíží. 11Kdo činíš bezpráví, pokračuj, kdo máš rád špínu, válej se v ní. Kdo jsi však přijal Kristovu bezúhonnost, jednej podle toho, kdo zápasíš o čistý život, nepolevuj!

12Čekejte, přijdu už brzo a odplatím každému podle jeho činů. 13Já jsem první i poslední, začátek i konec. 14Šťasten, kdo má očištěné srdce: před ním se otevírá věčný život a brány nebeského města, 15venku zůstanou pohlavně nevázaní, zvrhlíci, šarlatáni, vrazi a všichni, kdo dávají čemukoliv přednost před Bohem a libují si v podvodech.

16Já, Ježíš, jsem pověřil svého posla, aby tuto zvěst vyřídil církvi. Já, potomek velkého krále Davida, Jitřenka nového svítání.“

Boží nabídka – uchop život!

17Duch i církev volají: „Přijď!“

A všichni, kdo je slyší, ať se připojí svým: „Přijď!“

Kdo žízníš, pojď sem a čerpej zdarma vodu života.

18Upozorňuji každého čtenáře této knihy; kdo k ní něco přidá, dostane přidáno Božích ran tady popsaných. 19Kdo z ní něco ubere, tomu Bůh odepře přístup ke stromu života i do svatého města, o kterých jste tu četli. 20Ten, kdo stojí za slovy této knihy, praví:

„Jistě, přijdu brzy.“

Ano, přijď, Pane Ježíši!

21Vám všem, milí čtenáři, platí dosud nabídka Kristovy milosti!