Sí ìjọ Efesu
1“Sí angẹli ìjọ ní Efesu kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ní ẹni tí ó mú ìràwọ̀ méje náà ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ wí, ẹni tí ń rìn ní àárín ọ̀pá wúrà fìtílà méje:
2Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti làálàá rẹ, àti ìfaradà rẹ, àti bí ara rẹ kò ti gba àwọn ẹni búburú: àti bí ìwọ sì ti dán àwọn tí ń pe ara wọn ní aposteli, tí wọ́n kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ wo, tí ìwọ sì rí pé èké ni wọ́n; 3Tí ìwọ sì faradà ìyà, àti nítorí orúkọ mi tí ó sì rọ́jú, tí àárẹ̀ kò sì mú ọ.
4Síbẹ̀ èyí ni mo rí wí sí ọ, pé, ìwọ ti fi ìfẹ́ ìṣáájú rẹ sílẹ̀. 5Rántí ibi tí ìwọ ti gbé ṣubú! Ronúpìwàdà, kí ó sì ṣe iṣẹ́ ìṣáájú; bí kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó sì tọ̀ ọ́ wá, èmi ó sì ṣí ọ̀pá fìtílà rẹ̀ kúrò ní ipò rẹ̀, bí kò ṣe bí ìwọ bá ronúpìwàdà. 6Ṣùgbọ́n èyí ni ìwọ ní, pé ìwọ kórìíra ìṣe àwọn Nikolatani, èyí tí èmi pẹ̀lú sì kórìíra.
72.7: Gẹ 2.9.Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi èso igi ìyè nì fún jẹ, tí ń bẹ láàrín Paradise Ọlọ́run.
Sí Ìjọ ní Smirna
82.8: Isa 44.6.“Àti sí angẹli ìjọ ní Smirna kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ni ẹni tí í ṣe ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn wí, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè:
9Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti ìpọ́njú, àti àìní rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́, èmi sì mọ ọ̀rọ̀-òdì tí àwọn tí ń wí pé, Júù ni àwọn tìkára wọn, tí wọn kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ Sinagọgu ti Satani. 102.10: Da 1.12.Má ṣe bẹ̀rù ohunkóhun tí ìwọ ń bọ wá jìyà rẹ̀. Kíyèsi i, èṣù yóò gbé nínú yín jù sínú túbú, kí a lè dán yin wò; ẹ̀yin ó sì ní ìpọ́njú ní ọjọ́ mẹ́wàá: ìwọ ṣa ṣe olóòtítọ́ dé ojú ikú, èmi ó sì fi adé ìyè fún ọ.
11Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun kì yóò fi ara pa nínú ikú kejì.
Sí ìjọ ní Pargamu
12“Àti sì angẹli ìjọ ni Pargamu kọ̀wé:
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ní idà mímú olójú méjì.
13Èmí mọ̀ ibi tí ìwọ ń gbé, àní ibi tí ìtẹ́ Satani wà. Síbẹ̀ ìwọ di orúkọ mi mú ṣinṣin. Ìwọ kò sì sẹ́ ìgbàgbọ́ nínú mi, pàápàá jùlọ ni ọjọ́ Antipa ẹlẹ́rìí mi, olóòtítọ́ ènìyàn, ẹni tí wọn pa láàrín yín, níbi tí Satani ń gbé.
142.14: Nu 31.16; 25.1-2.Ṣùgbọ́n mo ni nǹkan díẹ̀ wí sí ọ; nítorí tí ìwọ ní àwọn kan tí ó di ẹ̀kọ́ Balaamu mú síbẹ̀, ẹni tí ó kọ́ Balaki láti mú ohun ìkọ̀sẹ̀ wá síwájú àwọn ọmọ Israẹli, láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sí òrìṣà, àti láti máa ṣe àgbèrè. 15Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ní àwọn tí ó gbá ẹ̀kọ́ àwọn Nikolatani pẹ̀lú, ohun tí mo kórìíra. 16Nítorí náà, ronúpìwàdà; bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó tọ̀ ọ́ wá nísinsin yìí, èmí o sì fi idà ẹnu mi bá wọn jà.
172.17: Sm 78.24; Isa 62.2.Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ; Ẹni tí o bá ṣẹ́gun ni èmi o fi manna tí ó pamọ́ fún, èmi ó sì fún un ni òkúta funfun kan, àti sára òkúta náà ni a kọ orúkọ tuntun kan, tí ẹnìkan kò mọ̀ bí kò ṣe ẹni tí ó gbà á.
Sí ìjọ ni Tiatira
182.18: Da 10.6.“Àti sí angẹli ìjọ ní Tiatira kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ni Ọmọ Ọlọ́run wí, ẹni tí ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, tí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára:
19Èmi mọ̀ iṣẹ́, ìfẹ́, àti ìgbàgbọ́ àti ìsìn àti sùúrù rẹ̀; àti pé iṣẹ́ rẹ̀ ìkẹyìn ju tí ìṣáájú lọ.
202.20: 1Ọb 16.31; 2Ọb 9.22,30; Nu 25.1.Ṣùgbọ́n èyí ni mo rí wí sí ọ: nítorí tí ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún obìnrin Jesebeli tí ó ń pe ara rẹ̀ ní wòlíì. Nípasẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó sì ń kọ́ àwọn ìránṣẹ́ mi, ó sì ń tàn wọ́n láti máa ṣe àgbèrè, àti láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sì òrìṣà. 21Èmi fi àkókò fún un, láti ronúpìwàdà; ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ ronúpìwàdà àgbèrè rẹ̀. 22Nítorí náà, èmi ó gbé e sọ sí orí àkéte ìpọ́njú, àti àwọn tí ń bá a ṣe panṣágà ni èmi ó fi sínú ìpọ́njú ńlá, bí kò ṣe bí wọ́n bá ronúpìwàdà iṣẹ́ wọn. 232.23: Jr 17.10; Sm 62.12.Èmi o pa àwọn ọmọ rẹ̀ run; gbogbo ìjọ ni yóò sì mọ̀ pé, èmi ni ẹni tí ń wádìí inú àti ọkàn: èmi ó sì fi fún olúkúlùkù yín gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
24Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni mò ń sọ fún, ẹ̀yin ìyókù tí ń bẹ ní Tiatira, gbogbo ẹ̀yin tí kò ni ẹ̀kọ́ yìí, ti kò ì tí ì mọ̀ ohun tí wọn pè ni ohun ìjìnlẹ̀ Satani, èmi kò di ẹrù mìíràn rù yín: 25Ṣùgbọ́n èyí tí ẹ̀yin ní, ẹ di mú ṣinṣin títí èmi ó fi dé.
262.26: Sm 2.8-9.Ẹni tí ó bá sì ṣẹ́gun, àti tí ó sì ṣe ìfẹ́ mi títí dé òpin, èmi ó fún un láṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè: 27‘Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn; gẹ́gẹ́ bí a ti ń fọ́ ohun èlò amọ̀kòkò ni a ó fọ́ wọn túútúú,’ gẹ́gẹ́ bí èmi pẹ̀lú tí gbà àṣẹ láti ọ̀dọ̀ Baba mi. 28Èmi yóò sì fi ìràwọ̀ òwúrọ̀ fún un. 29Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
Do Efezu: Chybí vám to nejdůležitější – láska
1Představiteli efezského sboru napiš:
Hovoří k vám ten, který je ve vašich sborech neustále činně přítomen a na němž jsou jejich představitelé plně závislí. 2-3Vím o tom, co jste už vykonali a také o vaší usilovné práci. Jste vytrvalí, stateční a trpěliví, snášíte pro mne mnoho a neochabujete. Cením si toho, že jste se nenechali svést falešnými apoštoly, ale vyzkoušeli jste je a odhalili jejich lži. Dobře děláte, že jste ostře vystoupili proti zastáncům nevázaného života, který já také odsuzuji.
4Musím vám však vytknout, že jste polevili v lásce; není už tak vřelá jako na počátku. 5-6Vzpomeňte si, jak to s vámi bylo, jděte do sebe a navraťte se k činorodé lásce. Nebudete-li činit pokání, hrozí vašemu sboru zánik.
7Slyšte, co vám říká Bůh: Kdo zvítězí, okusí ovoce stromu věčného života, který je v Božím ráji.
Do Smyrny: Věrnost osvědčíte v utrpení
8Představiteli smyrenského sboru napiš:
Hovoří k vám První a Poslední, ten, který zemřel a ožil. 9Znám vaše činy, těžkosti a chudobu – ale přesto jste bohatí! Vím, jak vás lživě obviňují ti, kteří se pyšní svou pravověrností, ale pracují vlastně pro satana. 10Nebojte se utrpení, které ještě přijde. Ďábel dostane některé z vás i do vězení a bude zkoušet vaši věrnost po deset dnů. Buďte věrní až do smrti a dám vám věčný život – cenu vítězů.
11Slyšte, co vám říká Bůh: Kdo zvítězí, nepodlehne věčné smrti.
Do Pergamu: Zbavte se tolerance k hříchu
12Představiteli pergamského sboru napiš:
Hovoří k vám ten, jehož slovo platí. 13Vím, na jak nebezpečném místě působíte. Hlásíte se k mému jménu přímo v satanově sídelním městě, ve stínu jeho trůnu. Nezapřeli jste víru ve mne ani tehdy, když byl umučen můj věrný svědek Antipas.
14-15Jednu věc vám však přece musím vytknout: klidně ponecháváte mezi sebou ty, kteří se pod rouškou křesťanské svobody účastní nestydatých orgií, a to já nenávidím. 16Dejte tu záležitost rychle do pořádku, nebo přijdu a vynesu nad nimi spravedlivý rozsudek.
17Slyšte, co vám říká Bůh: Toho, kdo zvítězí, dokonale nasytím. Vtisknu mu nový charakter a poctím ho svým osobním přátelstvím.
Do Tyatiry: Žádné kompromisy s hříchem
18Představiteli tyatirského sboru napiš:
Hovoří k vám Boží Syn, jehož oči září jako oheň a nohy žhnou jako rozpálená mosaz.
19Znám vaše činy lásky, víry, trpělivé naděje a vím, že v tom všem rostete. 20Avšak to vám musím vytknout, že mezi sebou trpíte tu ženu, která se vydává za prorokyni, ale svádí moje věrné k sexuálním zvrácenostem a modlářským hostinám. 21Dal jsem jí lhůtu k nápravě, ale ona provádí své nečisté rejdy dál. 22-23Dopustím těžkou nemoc na ni i na ty, které svedla, pokud nebudou činit pokání z toho, co páchali; nezůstane po ní ani památka. Tak bude jasné všem sborům, že každému vidím do svědomí a každého budu soudit podle jeho činů.
24Vám, kteří odmítáte její učení a nejste zvědavi na to, čemu pyšně říká „satanova nejhlubší tajemství“, vám, věrní Tyatirští, slibuji: víc už na vás nenaložím. 25Musíte se však pevně držet toho, čemu jste uvěřili, dokud nepřijdu.
26Tomu, kdo zvítězí a splní mou vůli, dám mocné poslání ke všem lidem. 27Bude mít mezi nimi takovou autoritu, jakou dal Otec mně, a to, na čem si zakládají, rozbije jako hliněné hrnce. 28Vítězům vyjdu vstříc jako jitřní hvězda, která ohlašuje den. 29Slyšte, to vám říká Bůh.