Sí ìjọ Efesu
1“Sí angẹli ìjọ ní Efesu kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ní ẹni tí ó mú ìràwọ̀ méje náà ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ wí, ẹni tí ń rìn ní àárín ọ̀pá wúrà fìtílà méje:
2Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti làálàá rẹ, àti ìfaradà rẹ, àti bí ara rẹ kò ti gba àwọn ẹni búburú: àti bí ìwọ sì ti dán àwọn tí ń pe ara wọn ní aposteli, tí wọ́n kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ wo, tí ìwọ sì rí pé èké ni wọ́n; 3Tí ìwọ sì faradà ìyà, àti nítorí orúkọ mi tí ó sì rọ́jú, tí àárẹ̀ kò sì mú ọ.
4Síbẹ̀ èyí ni mo rí wí sí ọ, pé, ìwọ ti fi ìfẹ́ ìṣáájú rẹ sílẹ̀. 5Rántí ibi tí ìwọ ti gbé ṣubú! Ronúpìwàdà, kí ó sì ṣe iṣẹ́ ìṣáájú; bí kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó sì tọ̀ ọ́ wá, èmi ó sì ṣí ọ̀pá fìtílà rẹ̀ kúrò ní ipò rẹ̀, bí kò ṣe bí ìwọ bá ronúpìwàdà. 6Ṣùgbọ́n èyí ni ìwọ ní, pé ìwọ kórìíra ìṣe àwọn Nikolatani, èyí tí èmi pẹ̀lú sì kórìíra.
72.7: Gẹ 2.9.Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi èso igi ìyè nì fún jẹ, tí ń bẹ láàrín Paradise Ọlọ́run.
Sí Ìjọ ní Smirna
82.8: Isa 44.6.“Àti sí angẹli ìjọ ní Smirna kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ni ẹni tí í ṣe ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn wí, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè:
9Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti ìpọ́njú, àti àìní rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́, èmi sì mọ ọ̀rọ̀-òdì tí àwọn tí ń wí pé, Júù ni àwọn tìkára wọn, tí wọn kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ Sinagọgu ti Satani. 102.10: Da 1.12.Má ṣe bẹ̀rù ohunkóhun tí ìwọ ń bọ wá jìyà rẹ̀. Kíyèsi i, èṣù yóò gbé nínú yín jù sínú túbú, kí a lè dán yin wò; ẹ̀yin ó sì ní ìpọ́njú ní ọjọ́ mẹ́wàá: ìwọ ṣa ṣe olóòtítọ́ dé ojú ikú, èmi ó sì fi adé ìyè fún ọ.
11Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun kì yóò fi ara pa nínú ikú kejì.
Sí ìjọ ní Pargamu
12“Àti sì angẹli ìjọ ni Pargamu kọ̀wé:
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ní idà mímú olójú méjì.
13Èmí mọ̀ ibi tí ìwọ ń gbé, àní ibi tí ìtẹ́ Satani wà. Síbẹ̀ ìwọ di orúkọ mi mú ṣinṣin. Ìwọ kò sì sẹ́ ìgbàgbọ́ nínú mi, pàápàá jùlọ ni ọjọ́ Antipa ẹlẹ́rìí mi, olóòtítọ́ ènìyàn, ẹni tí wọn pa láàrín yín, níbi tí Satani ń gbé.
142.14: Nu 31.16; 25.1-2.Ṣùgbọ́n mo ni nǹkan díẹ̀ wí sí ọ; nítorí tí ìwọ ní àwọn kan tí ó di ẹ̀kọ́ Balaamu mú síbẹ̀, ẹni tí ó kọ́ Balaki láti mú ohun ìkọ̀sẹ̀ wá síwájú àwọn ọmọ Israẹli, láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sí òrìṣà, àti láti máa ṣe àgbèrè. 15Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ní àwọn tí ó gbá ẹ̀kọ́ àwọn Nikolatani pẹ̀lú, ohun tí mo kórìíra. 16Nítorí náà, ronúpìwàdà; bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó tọ̀ ọ́ wá nísinsin yìí, èmí o sì fi idà ẹnu mi bá wọn jà.
172.17: Sm 78.24; Isa 62.2.Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ; Ẹni tí o bá ṣẹ́gun ni èmi o fi manna tí ó pamọ́ fún, èmi ó sì fún un ni òkúta funfun kan, àti sára òkúta náà ni a kọ orúkọ tuntun kan, tí ẹnìkan kò mọ̀ bí kò ṣe ẹni tí ó gbà á.
Sí ìjọ ni Tiatira
182.18: Da 10.6.“Àti sí angẹli ìjọ ní Tiatira kọ̀wé:
Nǹkan wọ̀nyí ni Ọmọ Ọlọ́run wí, ẹni tí ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, tí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára:
19Èmi mọ̀ iṣẹ́, ìfẹ́, àti ìgbàgbọ́ àti ìsìn àti sùúrù rẹ̀; àti pé iṣẹ́ rẹ̀ ìkẹyìn ju tí ìṣáájú lọ.
202.20: 1Ọb 16.31; 2Ọb 9.22,30; Nu 25.1.Ṣùgbọ́n èyí ni mo rí wí sí ọ: nítorí tí ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún obìnrin Jesebeli tí ó ń pe ara rẹ̀ ní wòlíì. Nípasẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó sì ń kọ́ àwọn ìránṣẹ́ mi, ó sì ń tàn wọ́n láti máa ṣe àgbèrè, àti láti máa jẹ ohun tí a pa rú ẹbọ sì òrìṣà. 21Èmi fi àkókò fún un, láti ronúpìwàdà; ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ ronúpìwàdà àgbèrè rẹ̀. 22Nítorí náà, èmi ó gbé e sọ sí orí àkéte ìpọ́njú, àti àwọn tí ń bá a ṣe panṣágà ni èmi ó fi sínú ìpọ́njú ńlá, bí kò ṣe bí wọ́n bá ronúpìwàdà iṣẹ́ wọn. 232.23: Jr 17.10; Sm 62.12.Èmi o pa àwọn ọmọ rẹ̀ run; gbogbo ìjọ ni yóò sì mọ̀ pé, èmi ni ẹni tí ń wádìí inú àti ọkàn: èmi ó sì fi fún olúkúlùkù yín gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
24Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni mò ń sọ fún, ẹ̀yin ìyókù tí ń bẹ ní Tiatira, gbogbo ẹ̀yin tí kò ni ẹ̀kọ́ yìí, ti kò ì tí ì mọ̀ ohun tí wọn pè ni ohun ìjìnlẹ̀ Satani, èmi kò di ẹrù mìíràn rù yín: 25Ṣùgbọ́n èyí tí ẹ̀yin ní, ẹ di mú ṣinṣin títí èmi ó fi dé.
262.26: Sm 2.8-9.Ẹni tí ó bá sì ṣẹ́gun, àti tí ó sì ṣe ìfẹ́ mi títí dé òpin, èmi ó fún un láṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè: 27‘Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn; gẹ́gẹ́ bí a ti ń fọ́ ohun èlò amọ̀kòkò ni a ó fọ́ wọn túútúú,’ gẹ́gẹ́ bí èmi pẹ̀lú tí gbà àṣẹ láti ọ̀dọ̀ Baba mi. 28Èmi yóò sì fi ìràwọ̀ òwúrọ̀ fún un. 29Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ.
Brevet till församlingen i Efesos
1Skriv till budbäraren2:1 Eller ängeln, som ses som en representant för församlingen. Brevet, liksom de följande breven, är alltså riktat till församlingen. för församlingen i Efesos:
’Så säger han som håller de sju stjärnorna i sin högra hand och går omkring bland de sju lampställen av guld:
2Jag känner dina gärningar, dina ansträngningar och din uthållighet. Jag vet att du inte kan tåla onda människor och att du noga har prövat dem som kallar sig apostlar2:2 Eller sändebud., men inte är det. Du har funnit att de ljuger. 3Du har hållit ut och stått ut med mycket för mitt namns skull, utan att ge upp.
4Men en sak måste jag anmärka mot dig: du har övergett din första kärlek. 5Tänk på vad det är du har fallit ifrån, och vänd om och gör samma gärningar som då. För om du inte vänder om, ska jag komma till dig och flytta ditt lampställ från sin plats. 6Men något berömvärt har du också: du hatar nikolaiternas2:6 Nikolaiterna var gnostiker. De trodde att den andliga och den materiella verkligheten var skilda åt, och att man därför kunde leva omoraliskt utan att det påverkade det andliga livet. handlingar, precis som jag gör.
7Den som har öron ska höra vad Anden säger till församlingarna. Åt den som segrar ska jag ge rätt att äta av livets träd, som är i Guds paradis.’
Brevet till församlingen i Smyrna
8Skriv till budbäraren2:8 Se not till 2:1. för församlingen i Smyrna:
’Så säger han som är den förste och den siste, han som var död men nu lever igen:
9Jag vet hur mycket du får lida och hur fattig du är. Men du är rik. Jag vet att du blir hånad av dem som kallar sig judar men inte är det, utan är en Satans synagoga. 10Var inte rädd för det lidande som väntar dig. Se, djävulen kommer att kasta några av er i fängelse för att pröva er, och ni ska lida under tio dagar. Men var trogen intill döden, så ska jag ge dig livets segerkrans.
11Den som har öron ska höra vad Anden säger till församlingarna. Den som segrar ska inte skadas av den andra döden.2:11 Den andra döden. Förklaringen finns i 20:14-15 och 21:8.’
Brevet till församlingen i Pergamon
12Skriv till budbäraren2:12 Se not till 2:1. för församlingen i Pergamon:
’Så säger han som har det skarpa, dubbeleggade svärdet:
13Jag vet var du bor: där Satan har sin tron2:13 Pergamon var centrum i provinsen Asien för tillbedjan av den romerska kejsaren., men trots det håller du fast vid mig. Du har inte förnekat din tro på mig, inte ens när Antipas, mitt trogna vittne, blev dödad hos er, där Satan bor.
14Men en sak måste jag anmärka mot dig: du har några hos dig som är anhängare av Bileams lära, han som visade Balak att man kunde få Israels folk på fall genom att locka dem att äta sådant som offrats till avgudar och leda dem in i sexuell omoral.2:14 Jfr 4 Mos 22-24. 15Vidare har du också sådana som håller sig till nikolaiternas2:15 Se not till 2:6. lära. 16Vänd om! Annars ska jag snart komma till dig och strida mot dem med min muns svärd.
17Den som har öron ska höra vad Anden säger till församlingarna. Åt den som segrar ska jag ge av dolt manna.2:17 En bild på andlig ”mat”. Jfr Ps 78:24 och Joh 6:30-33, där Jesus säger att han är brödet från himlen. Och jag ska ge honom en vit sten, och på den stenen ska det stå ett nytt namn, som bara den känner till som får det.2:17 Stenar kan ha använts som inträdesbiljetter till fester. Namnet kan vara antingen den troendes nya namn eller identitet, eller Jesus namn. Jfr Jes 62:2.’
Brevet till församlingen i Thyatira
18Skriv till budbäraren2:18 Se not till 2:1. för församlingen i Thyatira:
’Så säger Guds Son, han som har ögon som eldslågor och fötter som liknar polerad koppar:
19Jag känner dina gärningar, din kärlek och tro, ditt tjänande och din uthållighet. Jag vet att du gör mer idag än du gjorde under den första tiden.
20Men det måste jag anmärka mot dig att du tolererar kvinnan Isebel, som säger sig vara en profetissa och som lär och förleder mina tjänare till sexuell omoral och till att äta sådant som offrats till avgudar. 21Jag gav henne tid att ångra sig och vända om, men hon ville inte sluta med sina sexuella utsvävningar. 22Därför ska jag låta henne bli sängliggande,2:22 Ordagrant: Jag placerar henne på en säng. och alla som bedriver otukt med henne, ska drabbas av svåra lidanden, om de inte vänder om från hennes gärningar. 23Och hennes efterföljare ska drabbas av döden. Alla församlingar ska då förstå att jag är den som rannsakar hjärtan och njurar, och att jag ger var och en av er den lön han förtjänar.
24När det gäller er andra i Thyatira, ni som inte har följt denna lära och inte lärt känna dessa Satans djup, som man kallar det, så tänker jag inte kräva något mer av er. 25Håll bara fast vid det ni har, tills jag kommer.
26Den som segrar och fortsätter att göra min vilja ända till slutet, honom ska jag ge makt över folken. 27Han ska härska över dem med en spira av järn och krossa dem som lerkrukor,2:27 Jfr Ps 2:9. 28liksom jag har fått den makten av min Fader, och jag ska ge honom morgonstjärnan.2:28 Morgonstjärnan var en symbol för seger och makt. Jesus kallas för morgonstjärnan i 22:16. 29Den som har öron ska höra vad Anden säger till församlingarna.’