Ọ̀rọ̀ ìṣáájú
1Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀, 2ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi. 3Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
Ọ̀rọ̀ ìkíni àti ìyìn
41.4: Ek 3.14.Johanu,
Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia:
Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀; 51.5: Sm 89.27.àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé.
Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, 61.6: Ek 19.6; Isa 61.6.tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín.
71.7: Da 7.13; Mt 24.30; Mk 14.62; Sk 12.10.“Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀,
gbogbo ojú ni yóò sì rí i,
àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”;
àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni
“yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
Bẹ́ẹ̀ náà ni! Àmín.
81.8: Ek 3.14. “Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
Ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí Ọmọ Ènìyàn
9Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi. 10Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè, 11Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
12Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje, 131.13: Da 7.13; 10.5.àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́. 14Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná. 151.15: El 1.24.Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀. 161.16: Ek 34.29.Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
171.17: Isa 44.2,6.Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn. 18Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́.
19“Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí; 20ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.
The Revelation Is Given
1This is the revelation from Jesus Christ. God gave it to him to show those who serve God what will happen soon. God made it known by sending his angel to his servant John. 2John is a witness to everything he saw. What he saw is God’s word and what Jesus Christ has said. 3Blessed is the one who reads out loud the words of this prophecy. Blessed are those who hear it and think everything it says is important. The time when these things will come true is near.
Greetings and Praise to God
4I, John, am writing this letter.
I am sending it to the seven churches in Asia Minor.
May grace and peace come to you from God. He is the one who is, and who was, and who will come. May grace and peace come to you from the seven spirits. These spirits are in front of God’s throne. 5May grace and peace come to you from Jesus Christ. He is the faithful witness, so what he has shown can be trusted. He was the first to rise from the dead. He rules over the kings of the earth.
Glory and power belong to Jesus Christ who loves us! He has set us free from our sins by pouring out his blood for us. 6He has made us members of his royal family. He has made us priests who serve his God and Father. Glory and power belong to Jesus Christ for ever and ever! Amen.
7“Look! He is coming with the clouds!” (Daniel 7:13)
“Every eye will see him.
Even those who pierced him will see him.”
All the nations of the earth “will mourn because of him.” (Zechariah 12:10)
This will really happen! Amen.
8“I am the Alpha and the Omega, the Beginning and the End,” says the Lord God. “I am the God who is, and who was, and who will come. I am the Mighty One.”
John’s Vision of Christ
9I, John, am a believer like you. I am a friend who suffers like you. As members of Jesus’ royal family, we can put up with anything that happens to us. I was on the island of Patmos because I taught God’s word and what Jesus said. 10The Holy Spirit gave me a vision on the Lord’s Day. I heard a loud voice behind me that sounded like a trumpet. 11The voice said, “Write on a scroll what you see. Send it to the seven churches in Asia Minor. They are Ephesus, Smyrna, Pergamum, Thyatira, Sardis, Philadelphia and Laodicea.”
12I turned around to see who was speaking to me. When I turned, I saw seven golden lampstands. 13In the middle of them was someone who looked “like a son of man.” (Daniel 7:13) He was dressed in a long robe with a gold strip of cloth around his chest. 14The hair on his head was white like wool, as white as snow. His eyes were like a blazing fire. 15His feet were like bronze metal glowing in a furnace. His voice sounded like rushing waters. 16He held seven stars in his right hand. Coming out of his mouth was a sharp sword with two edges. His face was like the sun shining in all its brightness.
17When I saw him, I fell at his feet as if I were dead. Then he put his right hand on me and said, “Do not be afraid. I am the First and the Last. 18I am the Living One. I was dead. But now look! I am alive for ever and ever! And I hold the keys to Death and Hell.
19“So write down what you have seen. Write about what is happening now and what will happen later. 20Here is the meaning of the mystery of the seven stars you saw in my right hand. They are the angels of the seven churches. And the seven golden lampstands you saw stand for the seven churches.