Ẹ̀mí Mímọ́ wá ní Pentikosti
1Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan. 2Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó. 3Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn. 4Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
5Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu. 6Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀. 7Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́? 8Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀? 9Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia. 10Frigia, àti pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù 11(àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.” 12Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
13Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
Peteru wàásù sí ọ̀pọ̀ ènìyàn
14Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi. 15Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí. 16Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joeli wá pé:
172.17-21: Jl 2.28-32.“Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́,
Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo,
àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran,
àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá;
18Àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin,
ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì:
wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀;
19Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run,
àti àwọn ààmì nísàlẹ̀ ilẹ̀;
ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
20A ó sọ oòrùn di òkùnkùn,
àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,
kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
21Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe
orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
22“Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti ààmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú. 23Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú kàn mọ́ àgbélébùú, tí a sì pa á. 24Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú: nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú. 252.25-28: Sm 16.8-11.Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé:
“ ‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí,
nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi,
a kì ó ṣí mi ní ipò.
26Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀:
pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
27Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú,
bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.
28Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè,
ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
29“Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí. 302.30: Sm 132.11.Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. 312.31: Sm 16.10.Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. 32Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí. 33A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta. 342.34-35: Sm 110.1.Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé,
“ ‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé:
“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
35títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ
dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.” ’
36“Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé: Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
37Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
38Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ 392.39: Isa 57.19; Jl 2.32.Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
40Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.” 41Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
Ìsọ̀kan àwọn ará tí o gbàgbọ́
42Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà. 43Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ ààmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe. 442.44-45: Ap 4.32-35.Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn; 45Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí. 46Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn. 47Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.
نزول روحالقدس
1هنگامی که روز پِنتیکاست فرا رسید، همه با هم در یک جا جمع بودند. 2ناگهان صدایی شبیه صدای وزش باد شدید از آسمان آمد و خانهای را که در آن جمع بودند، پر کرد. 3سپس چیزی شبیه زبانههای آتش ظاهر شده، تقسیم شد و بر سر هر یک از ایشان قرار گرفت. 4آنگاه همه از روحالقدس پر شدند و برای اولین بار شروع به سخن گفتن به زبانهایی کردند که با آنها آشنایی نداشتند، زیرا روح خدا این قدرت را به ایشان بخشیده بود.
5آن روزها، یهودیان دیندار برای مراسم عید از تمام سرزمینها به اورشلیم آمده بودند. 6پس وقتی صدا از آن خانه به گوش رسید، گروهی با سرعت آمدند تا ببینند چه شده است. وقتی شنیدند شاگردان عیسی به زبان ایشان سخن میگویند، مات و مبهوت ماندند!
7آنان با تعجب به یکدیگر میگفتند: «این چگونه ممکن است؟ با اینکه این اشخاص از اهالی جلیل هستند، 8ولی به زبانهای محلی ما سخن میگویند، به زبان همان سرزمینهایی که ما در آنجا به دنیا آمدهایم! 9ما که از پارتها، مادها، ایلامیها، اهالی بینالنهرین، یهودیه، کپدوکیه، پونتوس، آسیا، 10فریجیه و پمفلیه، مصر، قسمت قیروانی زبان لیبی، 11کریت و عربستان هستیم، و حتی کسانی که از روم آمدهاند هم یهودی و هم آنانی که یهودی شدهاند، همگی میشنویم که این اشخاص به زبان خود ما از اعمال عجیب خدا سخن میگویند!»
12همه در حالی که مبهوت بودند، از یکدیگر میپرسیدند: «این چه واقعهای است؟»
13بعضی نیز مسخره کرده، میگفتند: «اینها مست هستند!»
موعظهٔ پطرس رسول
14آنگاه پطرس با یازده رسول دیگر از جا برخاست و با صدای بلند به ایشان گفت: «ای اهالی اورشلیم، ای زائرینی که در این شهر به سر میبرید، گوش کنید! 15اینها برخلاف آنچه شما فکر میکنید مست نیستند. چون اکنون ساعت نه صبح است و هنگام شرابخواری و مستی نیست! 16آنچه امروز صبح شاهد آن هستید، یوئیل نبی چنین پیشگویی کرده بود:
17«”خدا میفرماید: در روزهای آخر، روح خود را بر همۀ مردم خواهم ریخت. پسران و دختران شما نبوّت خواهند کرد، جوانان شما رؤیاها و پیران شما خوابها خواهند دید. 18در آن روزها روح خود را حتی بر غلامان و کنیزانم خواهم ریخت و ایشان نبوّت خواهند کرد. 19بالا، در آسمان، عجایب، و پایین، بر زمین، آیات به ظهور خواهم آورد، از خون و آتش و بخار. 20پیش از فرا رسیدن روز بزرگ و پرشکوه خداوند، آفتاب تاریک و ماه مانند خون سرخ خواهد شد 21اما هر که نام خداوند را بخواند نجات خواهد یافت.“2:21 یوئیل ۲:۲۸-۳۲.
22«حال، ای مردان اسرائیلی به من گوش دهید! همانطور که خود نیز میدانید، خدا بهوسیلۀ عیسای ناصری معجزات عجیب ظاهر کرد تا به همه ثابت کند که عیسی از جانب او آمده است. 23از سوی دیگر، خدا مطابق اراده و نقشهای که از پیش تعیین فرموده بود، به شما اجازه داد تا به دست اجنبیهای بیدین، عیسی را بر صلیب کشیده، بکُشید. 24ولی خدا او را دوباره زنده ساخت و از قدرت مرگ رهانید، زیرا مرگ نمیتوانست چنین کسی را در چنگ خود اسیر نگه دارد.
25«زیرا داوود نبی میفرماید: ”خداوند را همیشه پیش روی خود دیدهام. او در کنار من است و هیچ چیز نمیتواند مرا بلرزاند. 26پس دلم شاد است و زبانم در وجد؛ بدنم نیز در امید ساکن است. 27زیرا تو جان مرا در چنگال مرگ رها نخواهی کرد و نخواهی گذاشت قُدّوسِ تو در قبر بپوسد. 28تو راه حیات را به من نشان خواهی داد. حضور تو مرا از شادی لبریز میکند.“2:28 مزمور ۱۶:۸-۱۱.
29«برادران عزیز، کمی فکر کنید! این سخنان را جدّ ما داوود دربارهٔ خودش نگفت زیرا او مرد، دفن شد و قبرش نیز هنوز همینجا در میان ماست. 30ولی چون نبی بود، میدانست خدا قول داده و قسم خورده است که از نسل او، مسیح را بر تخت سلطنت او بنشاند. 31داوود به آیندهٔ دور نگاه میکرد و زنده شدن مسیح را میدید و میگفت که خدا جان او را در چنگال مرگ رها نخواهد کرد و نخواهد گذاشت بدنش در قبر بپوسد. 32داوود در واقع دربارهٔ عیسی پیشگویی میکرد و همهٔ ما با چشمان خود دیدیم که خدا عیسی را زنده ساخت.
33«او اکنون در آسمان، بر عالیترین جایگاه افتخار در کنار خدا نشسته است و روحالقدس موعود را از پدر دریافت کرده و او را به پیروان خود عطا فرموده است، که امروز شما نتیجهاش را میبینید و میشنوید.
34«زیرا داوود خودش هرگز به آسمان بالا نرفت. با این حال، گفت: ”خداوند به خداوند من گفت: به دست راست من بنشین 35تا دشمنانت را به زیر پایت بیفکنم.“2:35 مزمور ۱۱۰:۱.
36«از این جهت، من امروز به وضوح و روشنی به همهٔ شما هموطنان اسرائیلیام میگویم که خدا همین عیسی را که شما بر روی صلیب کشتید، بهعنوان خداوند و مسیح2:36 منظور از «مسیح»، پادشاه و نجاتدهندۀ موعود اسرائیل است. تعیین فرموده است!»
37سخنان پطرس مردم را سخت تحت تأثیر قرار داد. بنابراین، به او و به سایر رسولان گفتند: «برادران، اکنون باید چه کنیم؟»
38پطرس جواب داد: «هر یک از شما باید از گناهانتان دست کشیده، به سوی خدا بازگردید و به نام عیسی مسیح تعمید بگیرید تا خدا گناهانتان را ببخشد. آنگاه خدا به شما نیز این هدیه، یعنی روحالقدس را عطا خواهد فرمود. 39زیرا مسیح به شما که از سوی خداوند، خدای ما دعوت شدهاید، و نیز به فرزندان شما و همچنین به کسانی که در سرزمینهای دور هستند، وعده داده که روحالقدس را عطا فرماید.»
40سپس پطرس به تفصیل دربارهٔ عیسی سخن گفت و تمام شنوندگان را تشویق نمود که خود را از گناهان مردم شرور آن زمانه آزاد سازند. 41از کسانی که پیام او را پذیرفتند، تقریباً سه هزار نفر تعمید گرفتند و به جمع ایشان پیوستند. 42ایشان خود را وقف تعالیمی ساختند که رسولان میدادند، و با سایر ایمانداران رفاقت و مشارکت میکردند، و با هم خوراک خورده، رسم شام خداوند را برگزار میکردند، و مرتب با یکدیگر به دعا میپرداختند.
مردم گروهگروه به عیسی ایمان میآورند
43در ضمن، در اثر معجزات زیادی که توسط رسولان به عمل میآمد، در دل همه ترسی توأم با احترام نسبت به خدا ایجاد شده بود.
44به این ترتیب، تمام ایمانداران با هم بودند و هر چه را که داشتند، با هم قسمت میکردند. 45ایشان دارایی خود را نیز میفروختند و بین فقرا تقسیم مینمودند؛ 46و هر روز مرتب در معبد با هم عبادت میکردند، در خانهها برای شام خداوند جمع میشدند، و با خوشحالی و شکرگزاری هر چه داشتند با هم میخوردند، 47و خدا را سپاس میگفتند. اهالی شهر نیز به ایشان احترام میگذاشتند و خدا هر روز عدهای را نجات میبخشید و به جمع ایشان میافزود.