Nahumu 3 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Nahumu 3:1-19

Ole Wa Ninawi

13:1 Eze 22:2; Mik 3:10; Za 12:2Ole wa mji umwagao damu,

uliojaa uongo,

umejaa nyara,

usiokosa kuwa na vitu vya kuteka nyara.

23:2 Isa 34:3; Yer 47:3Kelele za mijeledi,

vishindo vya magurudumu,

farasi waendao mbio

na mshtuo wa magari ya vita!

3Wapanda farasi wanaenda mbio,

panga zinameremeta,

na mikuki inangʼaa!

Majeruhi wengi,

malundo ya maiti,

idadi kubwa ya miili isiyohesabika,

watu wanajikwaa juu ya mizoga:

43:4 Isa 47:9; 23:17; 2The 2:9, 10; Dan 2:2; Ufu 9:20, 21; Eze 16:25-29yote haya kwa sababu ya wingi wa tamaa za kahaba,

anayeshawishi, bibi wa mambo ya uchawi,

anayewatia utumwani mataifa kwa ukahaba wake

na pia jamaa za watu kwa ulozi wake.

53:5 Nah 2:13; Isa 47:2-3; 20:4; Yer 13:22Bwana Mwenye Nguvu Zote anasema,

“Mimi ni kinyume na ninyi.

Nitafunika uso wako kwa gauni lako.

Nitaonyesha mataifa uchi wako

na falme aibu yako.

63:6 Kut 29:14; Ay 9:31; 1Sam 2:30; Yer 51:37; Isa 14:16Nitakutupia uchafu,

nitakufanyia dharau

na kukufanya kioja.

73:7 Isa 13:14; 31:9; Nah 1:1; Ay 3:14; Yer 51:37Wote wanaokuona watakukimbia na kusema,

‘Ninawi ipo katika kuangamia:

ni nani atakayeomboleza kwa ajili yake?’

Nitampata wapi yeyote wa kukufariji?”

83:8 Amo 6:2; Yer 46:25; Isa 19:6-9Je, wewe ni bora kuliko No-Amoni,

uliopo katika Mto Naili,

uliozungukwa na maji?

Mto ulikuwa kinga yake,

nayo maji yalikuwa ukuta wake.

93:9 Mwa 10:6; 2Nya 12:3; Eze 27:10; 30:5Kushi3:9 Kushi ni Ethiopia. na Misri walikuwa nguvu zake zisizo na mpaka;

Putu na Libia walikuwa miongoni mwa wale walioungana naye.

103:10 Isa 20:4; 2Fal 8:12; Isa 13:16; Hos 13:16; Ay 6:26-27; Eze 24:6; Yer 40:1; Yoe 3:3; Oba 1:11Hata hivyo alichukuliwa mateka

na kwenda uhamishoni.

Watoto wake wachanga walivunjwa vunjwa vipande

kwenye mwanzo wa kila barabara.

Kura zilipigwa kwa watu wake wenye heshima,

na watu wake wote wakuu walifungwa kwa minyororo.

113:11 Isa 49:26; 2:10Wewe pia utalewa;

utakwenda mafichoni

na kutafuta kimbilio kutoka kwa adui.

123:12 Wim 2:13; Ufu 6:13; Isa 28:4Ngome zako zote ni kama mitini

yenye matunda yake ya kwanza yaliyoiva;

wakati inapotikiswa,

tini huanguka kwenye kinywa chake alaye.

133:13 Isa 19:16; 45:2; Yer 50:37; Nah 2:6Tazama vikosi vyako:

wote ni wanawake!

Malango ya nchi yako

yamekuwa wazi kwa adui zako;

moto umeteketeza mapingo yake.

143:14 2Nya 32:4; Nah 2:1Teka maji kwa ajili ya kuzingirwa kwako,

imarisha ulinzi wako,

Ufanyie udongo wa mfinyanzi kazi,

yakanyage matope,

karabati tanuru la kuchomea matofali!

153:15 Isa 27:1; 2Sam 2:26; Yer 51:14; Yoe 1:4Huko moto utakuteketeza,

huko upanga utakuangusha chini

na kama vile panzi, watakumaliza.

Ongezeka kama panzi,

ongezeka kama nzige!

163:16 Kut 10:13Umeongeza idadi ya wafanyabiashara wako

mpaka wamekuwa wengi kuliko nyota za angani,

lakini kama nzige wanaacha nchi tupu

kisha huruka na kwenda zake.

173:17 Ufu 9:7; Yer 51:17Walinzi wako ni kama nzige,

maafisa wako ni kama makundi ya nzige

watuao kwenye kuta wakati wa siku ya baridi:

lakini wakati jua linapotokea wanaruka kwenda zao,

na hakuna ajuaye waendako.

183:18 Za 76:5-6; Yer 25:27; 50:18; Eze 31:3; Isa 56:10; 1Fal 22:17Ee mfalme wa Ashuru, wachungaji wako wanasinzia;

wakuu wako wanalala chini mavumbini kupumzika.

Watu wako wametawanyika juu ya milima

bila kuwa na mtu yeyote wa kuwakusanya.

193:19 Yer 30:13; Mik 1:9; Ay 27:23; Mao 2:15; Sef 2:15; Isa 14:8; 37:18Hakuna kitu kinachoweza kuponya jeraha lako;

jeraha lako ni la kukuua.

Kila anayesikia habari zako,

hupiga makofi kwa kuanguka kwako,

kwa kuwa ni nani ambaye hajaguswa

na ukatili wako usio na mwisho?

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nahumu 3:1-19

A fi Ninefe bú

1Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,

gbogbo rẹ̀ kún fún èké,

ó kún fún olè,

ìjẹ kò kúrò!

2Ariwo pàṣán àti ariwo

kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun

àti jíjó ẹṣin

àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!

3Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára

ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná

ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;

òkú kò sì ni òpin;

àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.

4Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà

àgbèrè tí ó rójú rere gbà,

ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn Orílẹ̀-èdè di ẹrú

nípa àgbèrè rẹ̀

àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.

5“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ.

Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè

àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.

6Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,

èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́,

èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.

7Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,

‘Ninefe ṣòfò, ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’

Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

8Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ,

èyí tí ó wà ní ibi odò Naili,

tí omi sì yí káàkiri?

Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,

omi si jẹ́ odi rẹ̀.

9Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;

Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.

10Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn

o sì lọ sí oko ẹrú.

Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀

ní orí ìta gbogbo ìgboro.

Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,

gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè.

11Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;

a ó sì fi ọ́ pamọ́

ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

12Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́

pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;

nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,

ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.

13Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun!

Obìnrin ni gbogbo wọn.

Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada,

fún àwọn ọ̀tá rẹ;

iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.

14Pọn omi nítorí ìhámọ́,

mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i

wọ inú amọ̀

kí o sì tẹ erùpẹ̀,

kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.

15Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;

idà yóò sì ké ọ kúrò,

yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,

yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,

àní, di púpọ̀ bí eṣú!

16Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀

títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ,

ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.

17Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,

àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,

èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù,

ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ,

ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

18Ìwọ ọba Asiria,

àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;

àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi.

Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,

tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.

19Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn;

ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora,

Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ

yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,

nítorí ta ni kò ní pín nínú

ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.