Mlima Wa Bwana
(Mika 4:1-3)
12:1 Isa 1:1Hili ndilo aliloliona Isaya mwana wa Amozi kuhusu Yuda na Yerusalemu:
22:2 Dan 2:35; 11:45; Yoe 3:17; Mdo 2:17; Isa 11:9; 65:9; Zek 14:10; Yer 16:19Katika siku za mwisho
mlima wa Hekalu la Bwana utaimarishwa
kama mlima mkuu miongoni mwa milima yote,
utainuliwa juu ya vilima,
na mataifa yote yatamiminika huko.
32:3 Zek 8:21; Lk 24:47; Yn 4:22; Isa 33:22; 45:23; Yer 3:17; Kum 33:19Mataifa mengi yatakuja na kusema,
“Njooni, twendeni mlimani mwa Bwana,
kwenye nyumba ya Mungu wa Yakobo.
Atatufundisha njia zake,
ili tuweze kuenenda katika mapito yake.”
Sheria itatoka Sayuni,
neno la Bwana litatoka Yerusalemu.
42:4 Hos 2:18; Yer 30:11; Za 96:13; 51:4; 46:9; Yoe 3:10; Mwa 49:10; Zek 9:10Atahukumu kati ya mataifa
na ataamua migogoro ya mataifa mengi.
Watafua panga zao ziwe majembe,
na mikuki yao kuwa miundu ya kukata matawi.
Taifa halitainua upanga dhidi ya taifa jingine,
wala hawatajifunza vita tena.
52:5 Isa 60:19-20; 1Yn 1:5-7; Isa 58:1; 60:1Njooni, enyi nyumba ya Yakobo,
tutembeeni katika nuru ya Bwana.
Siku Ya Bwana
62:6 Kum 18:10, 14; 31:17; Yer 12:7; 2Nya 16:7; Isa 44:25; 2Fal 16:7; Kum 31:17Umewatelekeza watu wako,
nyumba ya Yakobo.
Wamejaa ushirikina utokao Mashariki,
wanapiga ramli kama Wafilisti
na wanashikana mikono na wapagani.
72:7 Mwa 41:43; Kum 17:16; Mik 5:10; Za 17:14; Isa 31:1; Kum 17:17Nchi yao imejaa fedha na dhahabu,
hakuna mwisho wa hazina zao.
Nchi yao imejaa farasi,
hakuna mwisho wa magari yao.
82:8 Isa 10:9-11; 17:8; 44:17; Ufu 9:20; 2Nya 32:19; Mik 5:13; Isa 44:17; Za 135:15Nchi yao imejaa sanamu,
wanasujudia kazi za mikono yao,
vitu vile vidole vyao vimevitengeneza.
92:9 Za 62:9; Isa 13:11; 5:15; 2:11, 17; Hes 4:5; Neh 4:5Kwa hiyo mwanadamu atashushwa
na binadamu atanyenyekezwa:
usiwasamehe.
102:10 Ufu 6:15-16; Nah 3:11; Za 145:12; Isa 2:19; 2The 1:9Ingieni kwenye miamba,
jificheni ardhini
kutokana na utisho wa Bwana
na utukufu wa enzi yake!
112:11 Isa 24:21-23; 37:23; 10:12; 5:15; Eze 31:10; Oba 1:8; Neh 9:29; Ay 40:11; Za 46:10; Hab 2:5Macho ya mtu mwenye majivuno yatanyenyekezwa
na kiburi cha wanadamu kitashushwa,
Bwana peke yake ndiye atakayetukuzwa siku hiyo.
122:12 Za 76:12; 59:12; Eze 7:7; Ay 40:11; Isa 13:6-9; 34:8; Yer 30:7; Mao 1:12; 2Sam 22:28; Yoe 1:15; Amo 5:18Bwana Mwenye Nguvu Zote anayo siku aliyoiweka akiba
kwa wote wenye kujivuna na wenye kiburi,
kwa wote wanaojikweza
(nao watanyenyekezwa),
132:13 Amu 9:15; Isa 10:33, 34; 29:17; Eze 27:5; Za 22:12; Zek 11:2kwa mierezi yote ya Lebanoni iliyo mirefu sana,
na mialoni yote ya Bashani,
142:14 Isa 30:25; 40:4kwa milima yote mirefu
na vilima vyote vilivyoinuka,
152:15 Isa 25:2, 12; 30:25; 32:14; 33:18; Sef 1:16kwa kila mnara ulio mrefu sana
na kila ukuta wenye ngome,
162:16 Mwa 10:4; 1Fal 10:22; 9:26kwa kila meli ya biashara,2:16 Au: ya Tarshishi (ona pia 1Fal 10:22; 22:48; 2Nya 9:21; 20:36; Isa 60:9.)
na kila chombo cha baharini cha fahari.
172:17 2Sam 22:28; Ay 40:112:17 Nah 3:13; Ebr 10:31; Kum 2:25; Isa 11:10, 15Majivuno ya mwanadamu yatashushwa,
na kiburi cha wanadamu kitanyenyekezwa,
Bwana peke yake ndiye atatukuzwa siku hiyo,
182:18 Kum 9:21; Mik 5:13; Eze 36:25; Isa 21:9; Yer 10:11; 1Sam 5:2nazo sanamu zitatoweka kabisa.
192:19 Hos 10:8; Nah 1:3-6; Ay 9:6; 30:9; Ebr 12:26; Hab 3:6; Amu 6:2; Isa 7:19; 14:16; Ay 30:6; Lk 23:30; Ufu 6:15Watu watakimbilia kwenye mapango ndani ya miamba,
na kwenye mahandaki ardhini
kutokana na utisho wa Bwana
na utukufu wa enzi yake,
ainukapo kuitikisa dunia.
202:20 Law 11:19; Eze 36:25; 7:19-20; 14:6; Ufu 9:20; Isa 2:11; Ay 22:24Siku ile, watu watawatupia
panya na popo
sanamu zao za fedha na za dhahabu,
walizozitengeneza ili waziabudu.
212:21 Kut 33:22; Za 145:12; Isa 33:10; 2:19Watakimbilia kwenye mapango miambani
na kwenye nyufa za miamba
kutokana na utisho wa Bwana
na utukufu wa enzi yake,
ainukapo kuitikisa dunia.
222:22 Mit 23:4; Yer 17:5; Yak 4:14; Ay 12:19; Za 119:8-9; Isa 51:12; 40:15; Za 18:42; 118:6, 8; 146:3Acheni kumtumainia mwanadamu,
ambaye hana kitu ila pumzi katika pua zake.
Yeye ana thamani gani?
Òkè Olúwa
1Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu:
22.2-4: Mt 4.1-3.Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́
òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀
gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè,
a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
3Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé,
“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu.
Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
4Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn.
Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀,
wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé.
Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́,
bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
5Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu,
ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Ọjọ́ Olúwa
6Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
ìwọ ilé Jakọbu.
Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá,
wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini,
wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
7Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà,
ìṣúra wọn kò sì ní òpin.
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin,
kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
8Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère,
wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn,
èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
9Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀
ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀,
má ṣe dáríjì wọ́n.
10Wọ inú àpáta lọ,
fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀
kúrò nínú ìpayà Olúwa,
àti ògo ọláńlá rẹ̀!
11Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀
a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba,
Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
12Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́
fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga
nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
13nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó
àti gbogbo óákù Baṣani,
14nítorí gbogbo òkè gíga ńláńlá
àti àwọn òkè kéékèèkéé,
15fún ilé ìṣọ́ gíga gíga
àti àwọn odi ìdáàbòbò,
16fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò
àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
17Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba
a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀,
Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
18gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
19Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta
àti sínú ihò ilẹ̀
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
àti ògo ọláńlá rẹ̀,
nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ
àwọn ère fàdákà àti ère wúrà
tí wọ́n ti yá fún bíbọ
sí èkúté àti àwọn àdán,
21Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta
àti sínú ihò pàlàpálá àpáta
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
àti ògo ọláńlá rẹ̀,
nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
22Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́,
èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀.
Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?