ምሳሌ 10 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 10:1-32

የሰሎሞን ምሳሌዎች

1የሰሎሞን ምሳሌዎች፤

ጠቢብ ልጅ አባቱን ደስ ያሰኛል፤

ተላላ ልጅ ግን ለእናቱ ሐዘንን ያተርፋል።

2ያላግባብ የተገኘ ሀብት አይጠቅምም፤

ጽድቅ ግን ከሞት ይታደጋል።

3እግዚአብሔር ጻድቁ እንዲራብ አያደርግም፤

የክፉዎችን ምኞት ግን ያጨናግፋል።

4ሰነፍ እጆች ሰውን ያደኸያሉ፤

ትጉህ እጆች ግን ብልጽግናን ያመጣሉ።

5ሰብሉን በበጋ የሚሰበስብ ጠቢብ ልጅ ነው፤

በመከር ጊዜ የሚተኛ ግን ውርደት ይከተለዋል።

6በረከት በጻድቃን ራስ ላይ ነው፤

መዓት ግን የክፉዎችን አፍ ይዘጋል።10፥6 ወይም የክፉዎች አፍ ግን መዓትን ይሰውራል፤ እንዲሁም 11 ይመ።

7የጻድቃን መታሰቢያቸው በረከት ነው፤

የክፉዎች ስም ግን እንደ ጠፋ ይቀራል።

8በልቡ ጠቢብ የሆነ ትእዛዝ ይቀበላል፤

ለፍላፊ ተላላ ግን ወደ ጥፋት ያመራል።

9ሐቀኛ ሰው ያለ ሥጋት ይራመዳል፤

በጠማማ ጐዳና የሚሄድ ግን ይጋለጣል።

10በተንኰለኛ ዐይን የሚጠቅስ ሐዘን ያስከትላል፤

ለፍላፊ ተላላም ወደ ጥፋት ያመራል።

11የጻድቅ አንደበት የሕይወት ምንጭ ናት፤

መዓት ግን የክፉዎችን አፍ ይዘጋል።

12ጥላቻ ጠብን ያነሣሣል፤

ፍቅር ግን ስሕተትን ሁሉ ይሸፍናል።

13ጥበብ በአስተዋይ ሰው ከንፈር ትገኛለች፤

በትር ግን ማመዛዘን ለጐደለው ሰው ጀርባ ነው።

14ጠቢባን ዕውቀት ያከማቻሉ፤

የተላላ አንደበት ግን ጥፋትን ይጋብዛል።

15የባለጠጎች ሀብት የተመሸገ ከተማቸው ነው፤

ድኽነት ግን የድኾች መጥፊያ ናት።

16የጻድቃን ደመወዝ ሕይወት ታስገኝላቸዋለች፤

የክፉዎች ትርፍ ግን ቅጣትን ታመጣባቸዋለች።

17ተግሣጽን ነቅቶ የሚጠብቅ የሕይወትን መንገድ ያሳያል፤

ዕርምትን የማይቀበል ግን ሌሎችን ወደ ስሕተት ይመራል።

18ጥላቻውን የሚሸሽግ ሐሰተኛ አንደበት ያለው ነው፤

ሐሜትን የሚዘራ ሁሉ ተላላ ነው።

19ከቃላት ብዛት ኀጢአት አይታጣም፤

አንደበቱን የሚገታ ግን ጠቢብ ነው።

20የጻድቅ አንደበት የነጠረ ብር ነው፤

የክፉ ሰው ልብ ግን ርባና የለውም።

21የጻድቃን ከንፈሮች ብዙዎችን ያንጻሉ፤

ተላሎች ግን ከማመዛዘን ጕድለት ይሞታሉ።

22የእግዚአብሔር በረከት ብልጽግናን ታመጣለች፤

መከራንም አያክልባትም።

23ተላላ ሰው በክፉ ተግባር ይደሰታል፤

አስተዋይ ሰው ግን በጥበብ ደስ ይለዋል።

24ክፉ ሰው የፈራው ይደርስበታል፤

ጻድቅ የሚመኘው ይፈጸምለታል።

25ዐውሎ ነፋስ ሲነሣ ክፉዎች ተጠራርገው ይወሰዳሉ፤

ጻድቃን ግን ለዘላለም ጸንተው ይኖራሉ።

26ሆምጣጤ ጥርስን፣ ጢስ ዐይንን እንደሚጐዳ፣

ሰነፍም ለሚልኩት እንዲሁ ነው።

27እግዚአብሔርን መፍራት ዕድሜን ያረዝማል፤

የክፉዎች ዕድሜ ግን በዐጭር ይቀጫል።

28የጻድቃን አለኝታ ደስታ ነው፤

የክፉዎች ተስፋ ግን ከንቱ ሆኖ ይቀራል።

29የእግዚአብሔር መንገድ ለጻድቃን መጠጊያ፣

ክፉ ለሚያደርጉ ግን መጥፊያቸው ነው።

30ጻድቃን ፈጽሞ አይነቀሉም፤

ክፉዎች ግን በምድር አይኖሩም።

31የጻድቃን አንደበት ጥበብን ያፈልቃል፤

ጠማማ ምላስ ግን ትቈረጣለች።

32የጻድቃን ከንፈሮች ተገቢውን ነገር ያውቃሉ፤

የክፉዎች አንደበት ግን የሚያውቀው ጠማማውን ብቻ ነው።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 10:1-32

Àwọn òwe Solomoni

1Àwọn òwe Solomoni.

Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn,

ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.

2Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè,

ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.

3Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo,

ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.

4Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,

ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.

5Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.

6Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo,

ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.

7Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún,

ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.

8Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,

ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.

9Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu,

ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.

10Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn,

aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.

11Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè,

ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.

12Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,

ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.

13Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye,

ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.

14Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ,

ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.

15Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,

ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.

16Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn,

ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.

17Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.

18Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́

ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.

19Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù

ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

20Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà,

ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.

21Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.

22Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,

kì í sì í fi ìdààmú sí i.

23Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú,

ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.

24Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;

olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.

25Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,

ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.

26Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú,

bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.

27Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,

ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.

28Ìrètí olódodo ni ayọ̀,

ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.

29Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo,

ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.

30A kì yóò fa olódodo tu láéláé,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

31Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,

ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.

32Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,

ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.